< Proverbs 9 >
1 Ọgbọ́n ti kọ́ ilé rẹ̀, ó ti gbẹ́ òpó o rẹ̀ méjèèjì,
Wisdom has built her house, She has hewn out her pillars—seven.
2 ó ti fi ilé pọn tí, ó ti fọ̀nà rokà. Ó sì ti ṣètò o tábìlì oúnjẹ rẹ̀
She has slaughtered her slaughter, She has mingled her wine, Indeed, she has arranged her table.
3 ó ti rán àwọn ìránṣẹ́bìnrin rẹ̀ jáde, ó sì ń pè, láti ibi tí ó ga jù láàrín ìlú.
She has sent forth her girls, She cries on the tops of the high places of the city:
4 “Jẹ́ kí gbogbo àwọn aláìgbọ́n wọ ibí wá!” Ó ń wí fún àwọn tí kò lọ́gbọ́n pé,
“Who [is] simple? Let him turn aside here.” Whoever lacks heart: she has said to him,
5 “Wá, ẹ wá jẹ́ oúnjẹ mi sì mu wáìnì tí mo ti pò.
“Come, eat of my bread, And drink of the wine I have mingled.
6 Fi ìwà àìmọ̀kan rẹ sílẹ̀ ìwọ yóò sì yè; rìn ní ọ̀nà òye.
Forsake the simple and live, And be blessed in the way of understanding.”
7 “Ẹnikẹ́ni tí ó bá bá ẹlẹ́gàn wí, kọ lẹ́tà sí àbùkù ẹnikẹ́ni tí ó bá bá ẹni búburú wí kọ lẹ́tà sí èébú.
The instructor of a scorner Is receiving for it—shame, And a reprover of the wicked—his blemish.
8 Má ṣe bá ẹlẹ́gàn wí, àìṣe bẹ́ẹ̀ yóò kórìíra rẹ. Bá ọlọ́gbọ́n wí yóò sì fẹ́ràn rẹ;
Do not reprove a scorner, lest he hate you, Give reproof to the wise, and he loves you.
9 kọ́ ọlọ́gbọ́n ènìyàn lẹ́kọ̀ọ́, yóò sì gbọ́n sí i kọ́ olódodo ènìyàn lẹ́kọ̀ọ́, yóò sì fi kún ìmọ̀ rẹ̀.
Give to the wise, and he is wiser still, Make known to the righteous, And he increases learning.
10 “Ìbẹ̀rù Olúwa ni ìbẹ̀rẹ̀ ọgbọ́n, ìmọ̀ nípa Ẹni Mímọ́ ni òye.
The commencement of wisdom [is] the fear of YHWH, And a knowledge of the Holy Ones [is] understanding.
11 Nítorí nípasẹ̀ mi ọjọ́ rẹ yóò gùn ọ̀pọ̀lọpọ̀ ọdún yóò sì kún ọjọ́ ayé rẹ.
For by me your days multiply, And years of life are added to you.
12 Bí ìwọ bá gbọ́n, ọgbọ́n rẹ yóò fún ọ ní èrè: bí ìwọ bá jẹ́ ẹlẹ́gàn, ìwọ nìkan ni yóò jìyà.”
If you have been wise, you have been wise for yourself, And you have scorned—you bear [it] alone.
13 Òmùgọ̀ obìnrin jẹ́ aláriwo; ó jẹ́ aláìlẹ́kọ̀ọ́ àti aláìní ìmọ̀.
A foolish woman [is] noisy, Simple, and has not known what.
14 Ó jókòó ní ẹnu-ọ̀nà ilé rẹ̀ lórí ìjókòó níbi tí ó ga jù láàrín ìlú,
And she has sat at the opening of her house, On a throne—the high places of the city,
15 ó ń pe àwọn tí ó ń kọjá lọ, tí wọn ń lọ tààrà ní ọ̀nà wọn.
To call to those passing by the way, Who are going straight [on] their paths.
16 “Jẹ́ kí gbogbo ẹni tí ó jẹ́ aláìlóye súnmọ́ bí!” Ni ó wí fún ẹni tí òye kù díẹ̀ ká à tó fún.
“Who [is] simple? Let him turn aside here.” And whoever lacks heart—she said to him,
17 “Omi tí a jí mu dùn oúnjẹ tí a jẹ ní ìkọ̀kọ̀ a máa ládùn!”
“Stolen waters are sweet, And hidden bread is pleasant.”
18 Ṣùgbọ́n wọn ò funra pé àwọn òkú wà níbẹ̀, pé àwọn àlejò rẹ̀ wà ní ìsàlẹ̀ ilẹ̀ isà òkú. (Sheol )
And he has not known that Rephaim [are] there, Her invited ones in deep places of Sheol! (Sheol )