< Proverbs 8 >

1 Ǹjẹ́ ọgbọ́n kò ha ń kígbe síta? Òye kò ha ń gbé ohùn rẹ sókè?
Does wisdom not call? And understanding give forth her voice?
2 Ní ibi gíga ní ẹ̀gbẹ́ ọ̀nà, ní ìkóríta, ní ó dúró;
At the head of high places by the way, She has stood between the paths,
3 ní ẹgbẹ́ ibodè tí ó wọ ìlú, ní ẹnu ibodè ni ó ń kígbe sókè:
At the side of the gates, at the mouth of the city, The entrance of the openings, she cries aloud,
4 “Sí i yín ẹ̀yin ènìyàn, ní mo ń kígbe pè; mo gbé ohun mi sókè sí gbogbo ènìyàn.
“To you, O men, I call, And my voice [is] to the sons of men.
5 Ẹ̀yin aláìmọ̀kan, ẹ kọ́gbọ́n; ẹ̀yin aṣiwèrè, ẹ gba òye.
Understand, you simple ones, prudence, And you fools, understand the heart,
6 Ẹ gbọ́, nítorí tí èmi ó sọ̀rọ̀ ohun iyebíye; Èmí ṣí ètè mi láti sọ ohun tí ó tọ́,
Listen, for I speak noble things, And the opening of my lips [is] uprightness.
7 ẹnu mi ń sọ ohun tí í ṣe òtítọ́, nítorí ètè mi kórìíra ibi.
For my mouth utters truth, And wickedness [is] an abomination to my lips.
8 Gbogbo ọ̀rọ̀ ẹnu mi ni ó tọ́, kò sí èyí tí ó jẹ́ ẹ̀tàn tàbí àyídáyidà níbẹ̀.
All the sayings of my mouth [are] in righteousness, Nothing in them is contrary and perverse.
9 Fún olóye gbogbo rẹ̀ ni ó tọ̀nà; wọ́n jẹ́ aláìlẹ́gàn fún gbogbo ẹni tí ó ní ìmọ̀.
All of them [are] plain to the intelligent, And upright to those finding knowledge.
10 Yan ẹ̀kọ́ mi dípò fàdákà, ìmọ̀ dípò o wúrà àṣàyàn,
Receive my instruction, and not silver, And knowledge rather than choice gold.
11 nítorí ọgbọ́n ṣe iyebíye jù iyùn lọ, kò sí ohun tí ọkàn rẹ̀ fẹ́ tí a sì le fiwé e.
For wisdom [is] better than rubies, Indeed, all delights are not comparable with it.
12 “Èmi, ọgbọ́n ń gbé pẹ̀lú òye; mo ní ìmọ̀ àti ọgbọ́n-inú.
I, wisdom, have dwelt with prudence, And I find out a knowledge of purposes.
13 Ìbẹ̀rù Olúwa ni ìkórìíra ibi mo kórìíra ìgbéraga àti agídí, ìwà ibi àti ọ̀rọ̀ ẹ̀tàn.
The fear of YHWH [is] to hate evil; Pride, and arrogance, and an evil way, And a contrary mouth, I have hated.
14 Ìmọ̀ràn àti ọgbọ́n tí ó yè kooro jẹ́ tèmi mo ní òye àti agbára.
Counsel and substance [are] mine, I [am] understanding, I have might.
15 Nípasẹ̀ mi ni ọba ń ṣàkóso tí àwọn aláṣẹ sì ń ṣe òfin tí ó dára.
By me kings reign, and princes decree righteousness,
16 Nípasẹ̀ mi àwọn ọmọ-aládé ń ṣàkóso, àti gbogbo ọlọ́lá tí ń ṣàkóso ilẹ̀ ayé.
By me chiefs rule, and nobles, All judges of earth.
17 Mo fẹ́ràn àwọn tí ó fẹ́ràn mi, àwọn tí ó sì wá mi rí mi.
I love those loving me, And those seeking me earnestly find me.
18 Lọ́dọ̀ mi ni ọrọ̀ àti ọlá wà, ọrọ̀ tí í tọ́jọ́ àti ìgbéga rere.
Wealth and honor [are] with me, Lasting substance and righteousness.
19 Èso mi dára ju wúrà dáradára lọ; ohun tí mò ń mú wá ju àṣàyàn fàdákà lọ.
My fruit [is] better than gold, even fine gold, And my increase than choice silver.
20 Mò ń rìn ní ọ̀nà òdodo, ní ojú ọ̀nà òtítọ́,
I cause to walk in a path of righteousness, In midst of paths of judgment,
21 mò ń fi ọrọ̀ fún gbogbo àwọn tí ó fẹ́ràn mi mo sì ń mú kí ilé ìṣúra wọn kún.
To cause my lovers to inherit substance, Indeed, I fill their treasures.
22 “Èmi ni Olúwa kọ́kọ́ dá nínú iṣẹ́ rẹ̀. Ṣáájú àwọn iṣẹ́ rẹ̀ àtijọ́;
YHWH possessed me—the beginning of His way, Before His works since then.
23 a ti yàn mí láti ayérayé, láti ìbẹ̀rẹ̀ pẹ̀pẹ̀, kí ayé tó bẹ̀rẹ̀.
I was anointed from the age, from the first, From former states of the earth.
24 Nígbà tí kò tí ì sí Òkun, ni a ti bí mi, nígbà tí kò tí ì sí ìsun tí ó ní omi nínú;
In there being no depths, I was brought forth, In there being no fountains heavy [with] waters,
25 kí a tó fi àwọn òkè sí ipò wọn, ṣáájú àwọn òkè ni a ti bí mi,
Before mountains were sunk, Before heights, I was brought forth.
26 kí ó tó dá ilẹ̀ ayé tàbí àwọn oko rẹ̀ tàbí èyíkéyìí nínú eruku ayé.
While He had not made the earth, and out-places, And the top of the dusts of the world.
27 Mo wà níbẹ̀ nígbà tí ó fi àwọn ọ̀run sí ipò wọn, nígbà tí ó fi òsùwọ̀n àyíká sórí ibú omi,
In His preparing the heavens I [am] there, In His decreeing a circle on the face of the deep,
28 nígbà tí ó ṣẹ̀dá òfúrufú lókè tí ó sì fi orísun ibú omi sí ipò rẹ̀ láì le è yẹsẹ̀,
In His strengthening clouds above, In His making strong fountains of the deep,
29 nígbà tí ó ṣe ààlà fún omi Òkun kí omi má ba à kọjá ààlà àṣẹ rẹ̀, àti nígbà tí ó pààlà ìpìlẹ̀ ayé.
In His setting for the sea its limit, And the waters do not transgress His command, In His decreeing the foundations of earth,
30 Nígbà náà èmi ni gbẹ́nàgbẹ́nà ẹ̀gbẹ́ rẹ̀ mo kún fún inú dídùn lójoojúmọ́, mo ń yọ̀ nígbà gbogbo níwájú rẹ̀.
Then I am near Him, a workman, And I am a delight—day by day. Rejoicing before Him at all times,
31 Mo ń yọ̀ nínú gbogbo àgbáyé tí ó dá mo sì ní inú dídùn sí àwọn ọmọ ènìyàn.
Rejoicing in the habitable part of His earth, And my delights [are] with the sons of men.
32 “Nítorí náà báyìí, ẹ̀yin ọmọ mi, ìbùkún ni fún àwọn tí ó pa ọ̀nà mi mọ́.
And now, you sons, listen to me, Indeed, blessed are they who keep my ways.
33 Fetí sí ìtọ́sọ́nà mi kí o sì gbọ́n; má ṣe pa á tì sápá kan.
Hear instruction, and be wise, and do not slight.
34 Ìbùkún ni fún ẹni tí ó fetísílẹ̀ sí mi, tí ń ṣọ́nà ní ẹnu-ọ̀nà mi lójoojúmọ́, tí ń dúró ní ẹnu-ọ̀nà mi.
O the blessedness of the man listening to me, To watch at my doors day by day, To watch at the doorposts of my entrance.
35 Nítorí ẹnikẹ́ni tí ó bá rí mi rí ìyè ó sì rí ojúrere gbà lọ́dọ̀ Olúwa.
For whoever is finding me, has found life, And brings out goodwill from YHWH.
36 Ṣùgbọ́n ẹnikẹ́ni tí ó bá kọ̀ láti rí ń pa ara rẹ̀ lára gbogbo ẹni tí ó kórìíra mi fẹ́ ikú.”
And whoever is missing me, is wronging his soul, All hating me have loved death!”

< Proverbs 8 >