< Proverbs 8 >

1 Ǹjẹ́ ọgbọ́n kò ha ń kígbe síta? Òye kò ha ń gbé ohùn rẹ sókè?
Is not wisdom crying out, and the voice of knowledge sounding?
2 Ní ibi gíga ní ẹ̀gbẹ́ ọ̀nà, ní ìkóríta, ní ó dúró;
At the top of the highways, at the meeting of the roads, she takes her place;
3 ní ẹgbẹ́ ibodè tí ó wọ ìlú, ní ẹnu ibodè ni ó ń kígbe sókè:
Where the roads go into the town her cry goes out, at the doorways her voice is loud:
4 “Sí i yín ẹ̀yin ènìyàn, ní mo ń kígbe pè; mo gbé ohun mi sókè sí gbogbo ènìyàn.
I am crying out to you, O men; my voice comes to the sons of men.
5 Ẹ̀yin aláìmọ̀kan, ẹ kọ́gbọ́n; ẹ̀yin aṣiwèrè, ẹ gba òye.
Become expert in reason, O you simple ones; you foolish ones, take training to heart.
6 Ẹ gbọ́, nítorí tí èmi ó sọ̀rọ̀ ohun iyebíye; Èmí ṣí ètè mi láti sọ ohun tí ó tọ́,
Give ear, for my words are true, and my lips are open to give out what is upright.
7 ẹnu mi ń sọ ohun tí í ṣe òtítọ́, nítorí ètè mi kórìíra ibi.
For good faith goes out of my mouth, and false lips are disgusting to me.
8 Gbogbo ọ̀rọ̀ ẹnu mi ni ó tọ́, kò sí èyí tí ó jẹ́ ẹ̀tàn tàbí àyídáyidà níbẹ̀.
All the words of my mouth are righteousness; there is nothing false or twisted in them.
9 Fún olóye gbogbo rẹ̀ ni ó tọ̀nà; wọ́n jẹ́ aláìlẹ́gàn fún gbogbo ẹni tí ó ní ìmọ̀.
They are all true to him whose mind is awake, and straightforward to those who get knowledge.
10 Yan ẹ̀kọ́ mi dípò fàdákà, ìmọ̀ dípò o wúrà àṣàyàn,
Take my teaching, and not silver; get knowledge in place of the best gold.
11 nítorí ọgbọ́n ṣe iyebíye jù iyùn lọ, kò sí ohun tí ọkàn rẹ̀ fẹ́ tí a sì le fiwé e.
For wisdom is better than jewels, and all things which may be desired are nothing in comparison with her.
12 “Èmi, ọgbọ́n ń gbé pẹ̀lú òye; mo ní ìmọ̀ àti ọgbọ́n-inú.
I, wisdom, have made wise behaviour my near relation; I am seen to be the special friend of wise purposes.
13 Ìbẹ̀rù Olúwa ni ìkórìíra ibi mo kórìíra ìgbéraga àti agídí, ìwà ibi àti ọ̀rọ̀ ẹ̀tàn.
The fear of the Lord is seen in hating evil: pride, a high opinion of oneself, the evil way, and the false tongue, are unpleasing to me.
14 Ìmọ̀ràn àti ọgbọ́n tí ó yè kooro jẹ́ tèmi mo ní òye àti agbára.
Wise design and good sense are mine; reason and strength are mine.
15 Nípasẹ̀ mi ni ọba ń ṣàkóso tí àwọn aláṣẹ sì ń ṣe òfin tí ó dára.
Through me kings have their power, and rulers give right decisions.
16 Nípasẹ̀ mi àwọn ọmọ-aládé ń ṣàkóso, àti gbogbo ọlọ́lá tí ń ṣàkóso ilẹ̀ ayé.
Through me chiefs have authority, and the noble ones are judging in righteousness.
17 Mo fẹ́ràn àwọn tí ó fẹ́ràn mi, àwọn tí ó sì wá mi rí mi.
Those who have given me their love are loved by me, and those who make search for me with care will get me.
18 Lọ́dọ̀ mi ni ọrọ̀ àti ọlá wà, ọrọ̀ tí í tọ́jọ́ àti ìgbéga rere.
Wealth and honour are in my hands, even wealth without equal and righteousness.
19 Èso mi dára ju wúrà dáradára lọ; ohun tí mò ń mú wá ju àṣàyàn fàdákà lọ.
My fruit is better than gold, even than the best gold; and my increase is more to be desired than silver.
20 Mò ń rìn ní ọ̀nà òdodo, ní ojú ọ̀nà òtítọ́,
I go in the road of righteousness, in the way of right judging:
21 mò ń fi ọrọ̀ fún gbogbo àwọn tí ó fẹ́ràn mi mo sì ń mú kí ilé ìṣúra wọn kún.
So that I may give my lovers wealth for their heritage, making their store-houses full.
22 “Èmi ni Olúwa kọ́kọ́ dá nínú iṣẹ́ rẹ̀. Ṣáájú àwọn iṣẹ́ rẹ̀ àtijọ́;
The Lord made me as the start of his way, the first of his works in the past.
23 a ti yàn mí láti ayérayé, láti ìbẹ̀rẹ̀ pẹ̀pẹ̀, kí ayé tó bẹ̀rẹ̀.
From eternal days I was given my place, from the birth of time, before the earth was.
24 Nígbà tí kò tí ì sí Òkun, ni a ti bí mi, nígbà tí kò tí ì sí ìsun tí ó ní omi nínú;
When there was no deep I was given birth, when there were no fountains flowing with water.
25 kí a tó fi àwọn òkè sí ipò wọn, ṣáájú àwọn òkè ni a ti bí mi,
Before the mountains were put in their places, before the hills was my birth:
26 kí ó tó dá ilẹ̀ ayé tàbí àwọn oko rẹ̀ tàbí èyíkéyìí nínú eruku ayé.
When he had not made the earth or the fields or the dust of the world.
27 Mo wà níbẹ̀ nígbà tí ó fi àwọn ọ̀run sí ipò wọn, nígbà tí ó fi òsùwọ̀n àyíká sórí ibú omi,
When he made ready the heavens I was there: when he put an arch over the face of the deep:
28 nígbà tí ó ṣẹ̀dá òfúrufú lókè tí ó sì fi orísun ibú omi sí ipò rẹ̀ láì le è yẹsẹ̀,
When he made strong the skies overhead: when the fountains of the deep were fixed:
29 nígbà tí ó ṣe ààlà fún omi Òkun kí omi má ba à kọjá ààlà àṣẹ rẹ̀, àti nígbà tí ó pààlà ìpìlẹ̀ ayé.
When he put a limit to the sea, so that the waters might not go against his word: when he put in position the bases of the earth:
30 Nígbà náà èmi ni gbẹ́nàgbẹ́nà ẹ̀gbẹ́ rẹ̀ mo kún fún inú dídùn lójoojúmọ́, mo ń yọ̀ nígbà gbogbo níwájú rẹ̀.
Then I was by his side, as a master workman: and I was his delight from day to day, playing before him at all times;
31 Mo ń yọ̀ nínú gbogbo àgbáyé tí ó dá mo sì ní inú dídùn sí àwọn ọmọ ènìyàn.
Playing in his earth; and my delight was with the sons of men.
32 “Nítorí náà báyìí, ẹ̀yin ọmọ mi, ìbùkún ni fún àwọn tí ó pa ọ̀nà mi mọ́.
Give ear to me then, my sons: for happy are those who keep my ways.
33 Fetí sí ìtọ́sọ́nà mi kí o sì gbọ́n; má ṣe pa á tì sápá kan.
Take my teaching and be wise; do not let it go.
34 Ìbùkún ni fún ẹni tí ó fetísílẹ̀ sí mi, tí ń ṣọ́nà ní ẹnu-ọ̀nà mi lójoojúmọ́, tí ń dúró ní ẹnu-ọ̀nà mi.
Happy is the man who gives ear to me, watching at my doors day by day, keeping his place by the pillars of my house.
35 Nítorí ẹnikẹ́ni tí ó bá rí mi rí ìyè ó sì rí ojúrere gbà lọ́dọ̀ Olúwa.
For whoever gets me gets life, and grace from the Lord will come to him.
36 Ṣùgbọ́n ẹnikẹ́ni tí ó bá kọ̀ láti rí ń pa ara rẹ̀ lára gbogbo ẹni tí ó kórìíra mi fẹ́ ikú.”
But he who does evil to me, does wrong to his soul: all my haters are in love with death.

< Proverbs 8 >