< Proverbs 8 >

1 Ǹjẹ́ ọgbọ́n kò ha ń kígbe síta? Òye kò ha ń gbé ohùn rẹ sókè?
Zdaliž moudrost nevolá, a rozumnost nevydává hlasu svého?
2 Ní ibi gíga ní ẹ̀gbẹ́ ọ̀nà, ní ìkóríta, ní ó dúró;
Na vrchu vysokých míst, u cesty, na rozcestí stojí,
3 ní ẹgbẹ́ ibodè tí ó wọ ìlú, ní ẹnu ibodè ni ó ń kígbe sókè:
U bran, kudy se chodí do města, a kudy se chodí dveřmi, volá, řkuci:
4 “Sí i yín ẹ̀yin ènìyàn, ní mo ń kígbe pè; mo gbé ohun mi sókè sí gbogbo ènìyàn.
Na vásť, ó muži, volám, a hlas můj jest k synům lidským.
5 Ẹ̀yin aláìmọ̀kan, ẹ kọ́gbọ́n; ẹ̀yin aṣiwèrè, ẹ gba òye.
Poučte se hloupí opatrnosti, a blázni srozumějte srdcem.
6 Ẹ gbọ́, nítorí tí èmi ó sọ̀rọ̀ ohun iyebíye; Èmí ṣí ètè mi láti sọ ohun tí ó tọ́,
Poslouchejtež, nebo znamenité věci mluviti budu, a otevření rtů mých pouhou pravdu.
7 ẹnu mi ń sọ ohun tí í ṣe òtítọ́, nítorí ètè mi kórìíra ibi.
Jistě žeť pravdu zvěstují ústa má, a ohavností jest rtům mým bezbožnost.
8 Gbogbo ọ̀rọ̀ ẹnu mi ni ó tọ́, kò sí èyí tí ó jẹ́ ẹ̀tàn tàbí àyídáyidà níbẹ̀.
Spravedlivé jsou všecky řeči úst mých, není v nich nic křivého ani převráceného.
9 Fún olóye gbogbo rẹ̀ ni ó tọ̀nà; wọ́n jẹ́ aláìlẹ́gàn fún gbogbo ẹni tí ó ní ìmọ̀.
Všecky pravé jsou rozumějícímu, a přímé těm, kteříž nalézají umění.
10 Yan ẹ̀kọ́ mi dípò fàdákà, ìmọ̀ dípò o wúrà àṣàyàn,
Přijmětež cvičení mé raději než stříbro, a umění raději než zlato nejvýbornější.
11 nítorí ọgbọ́n ṣe iyebíye jù iyùn lọ, kò sí ohun tí ọkàn rẹ̀ fẹ́ tí a sì le fiwé e.
Nebo lepší jest moudrost než drahé kamení, tak že jakékoli věci žádostivé vrovnati se jí nemohou.
12 “Èmi, ọgbọ́n ń gbé pẹ̀lú òye; mo ní ìmọ̀ àti ọgbọ́n-inú.
Já moudrost bydlím s opatrností, a umění pravé prozřetelnosti přítomné mám.
13 Ìbẹ̀rù Olúwa ni ìkórìíra ibi mo kórìíra ìgbéraga àti agídí, ìwà ibi àti ọ̀rọ̀ ẹ̀tàn.
Bázeň Hospodinova jest v nenávisti míti zlé, pýchy a vysokomyslnosti, i cesty zlé a úst převrácených nenávidím.
14 Ìmọ̀ràn àti ọgbọ́n tí ó yè kooro jẹ́ tèmi mo ní òye àti agbára.
Má jest rada i šťastný prospěch, jáť jsem rozumnost, a má jest síla.
15 Nípasẹ̀ mi ni ọba ń ṣàkóso tí àwọn aláṣẹ sì ń ṣe òfin tí ó dára.
Skrze mne králové kralují, a knížata ustanovují věci spravedlivé.
16 Nípasẹ̀ mi àwọn ọmọ-aládé ń ṣàkóso, àti gbogbo ọlọ́lá tí ń ṣàkóso ilẹ̀ ayé.
Skrze mne knížata panují, páni i všickni soudcové zemští.
17 Mo fẹ́ràn àwọn tí ó fẹ́ràn mi, àwọn tí ó sì wá mi rí mi.
Já milující mne miluji, a kteříž mne pilně hledají, nalézají mne.
18 Lọ́dọ̀ mi ni ọrọ̀ àti ọlá wà, ọrọ̀ tí í tọ́jọ́ àti ìgbéga rere.
Bohatství a sláva při mně jest, zboží trvánlivé i spravedlnost.
19 Èso mi dára ju wúrà dáradára lọ; ohun tí mò ń mú wá ju àṣàyàn fàdákà lọ.
Lepší jest ovoce mé než nejlepší zlato, i než ryzí, a užitek můj než stříbro výborné.
20 Mò ń rìn ní ọ̀nà òdodo, ní ojú ọ̀nà òtítọ́,
Stezkou spravedlnosti vodím, prostředkem stezek soudu,
21 mò ń fi ọrọ̀ fún gbogbo àwọn tí ó fẹ́ràn mi mo sì ń mú kí ilé ìṣúra wọn kún.
Abych těm, kteříž mne milují, přidědila zboží věčné, a poklady jejich naplnila.
22 “Èmi ni Olúwa kọ́kọ́ dá nínú iṣẹ́ rẹ̀. Ṣáájú àwọn iṣẹ́ rẹ̀ àtijọ́;
Hospodin měl mne při počátku cesty své, před skutky svými, přede všemi časy.
23 a ti yàn mí láti ayérayé, láti ìbẹ̀rẹ̀ pẹ̀pẹ̀, kí ayé tó bẹ̀rẹ̀.
Před věky ustanovena jsem, před počátkem, prvé než byla země.
24 Nígbà tí kò tí ì sí Òkun, ni a ti bí mi, nígbà tí kò tí ì sí ìsun tí ó ní omi nínú;
Když ještě nebylo propasti, zplozena jsem, když ještě nebylo studnic oplývajících vodami.
25 kí a tó fi àwọn òkè sí ipò wọn, ṣáájú àwọn òkè ni a ti bí mi,
Prvé než hory založeny byly, než byli pahrbkové, zplozena jsem;
26 kí ó tó dá ilẹ̀ ayé tàbí àwọn oko rẹ̀ tàbí èyíkéyìí nínú eruku ayé.
Ještě byl neučinil země a rovin, ani začátku prachu okršlku zemského.
27 Mo wà níbẹ̀ nígbà tí ó fi àwọn ọ̀run sí ipò wọn, nígbà tí ó fi òsùwọ̀n àyíká sórí ibú omi,
Když připravoval nebesa, byla jsem tu, když vyměřoval okrouhlost nad propastí;
28 nígbà tí ó ṣẹ̀dá òfúrufú lókè tí ó sì fi orísun ibú omi sí ipò rẹ̀ láì le è yẹsẹ̀,
Když upevňoval oblaky u výsosti, když utvrzoval studnice propasti;
29 nígbà tí ó ṣe ààlà fún omi Òkun kí omi má ba à kọjá ààlà àṣẹ rẹ̀, àti nígbà tí ó pààlà ìpìlẹ̀ ayé.
Když ukládal moři cíl jeho, a vodám, aby nepřestupovaly rozkázaní jeho, když vyměřoval základy země:
30 Nígbà náà èmi ni gbẹ́nàgbẹ́nà ẹ̀gbẹ́ rẹ̀ mo kún fún inú dídùn lójoojúmọ́, mo ń yọ̀ nígbà gbogbo níwájú rẹ̀.
Tehdáž byla jsem od něho pěstována, a byla jsem jeho potěšení na každý den, anobrž hrám před ním každého času;
31 Mo ń yọ̀ nínú gbogbo àgbáyé tí ó dá mo sì ní inú dídùn sí àwọn ọmọ ènìyàn.
Hrám i na okršlku země jeho, a rozkoše mé s syny lidskými.
32 “Nítorí náà báyìí, ẹ̀yin ọmọ mi, ìbùkún ni fún àwọn tí ó pa ọ̀nà mi mọ́.
A tak tedy, synové, poslechněte mne, nebo blahoslavení jsou ostříhající cest mých.
33 Fetí sí ìtọ́sọ́nà mi kí o sì gbọ́n; má ṣe pa á tì sápá kan.
Poslouchejte cvičení, a nabuďte rozumu, a nerozpakujte se.
34 Ìbùkún ni fún ẹni tí ó fetísílẹ̀ sí mi, tí ń ṣọ́nà ní ẹnu-ọ̀nà mi lójoojúmọ́, tí ń dúró ní ẹnu-ọ̀nà mi.
Blahoslavený člověk, kterýž mne slýchá, bdě u dveří mých na každý den, šetře veřejí dveří mých.
35 Nítorí ẹnikẹ́ni tí ó bá rí mi rí ìyè ó sì rí ojúrere gbà lọ́dọ̀ Olúwa.
Nebo kdož mne nalézá, nalézá život, a dosahuje lásky od Hospodina.
36 Ṣùgbọ́n ẹnikẹ́ni tí ó bá kọ̀ láti rí ń pa ara rẹ̀ lára gbogbo ẹni tí ó kórìíra mi fẹ́ ikú.”
Ale kdož hřeší proti mně, ukrutenství provodí nad duší svou; všickni, kteříž mne nenávidí, milují smrt.

< Proverbs 8 >