< Proverbs 8 >
1 Ǹjẹ́ ọgbọ́n kò ha ń kígbe síta? Òye kò ha ń gbé ohùn rẹ sókè?
Ne propovijeda li mudrost i ne diže li razboritost svoj glas?
2 Ní ibi gíga ní ẹ̀gbẹ́ ọ̀nà, ní ìkóríta, ní ó dúró;
Navrh brda, uza cestu, na raskršćima stoji,
3 ní ẹgbẹ́ ibodè tí ó wọ ìlú, ní ẹnu ibodè ni ó ń kígbe sókè:
kod izlaza iz grada, kraj ulaznih vrata, ona glasno viče:
4 “Sí i yín ẹ̀yin ènìyàn, ní mo ń kígbe pè; mo gbé ohun mi sókè sí gbogbo ènìyàn.
“Vama, o ljudi, propovijedam i upravljam svoj glas sinovima ljudskim.
5 Ẹ̀yin aláìmọ̀kan, ẹ kọ́gbọ́n; ẹ̀yin aṣiwèrè, ẹ gba òye.
Shvatite mudrost, vi neiskusni, a vi nerazumni, urazumite srce.
6 Ẹ gbọ́, nítorí tí èmi ó sọ̀rọ̀ ohun iyebíye; Èmí ṣí ètè mi láti sọ ohun tí ó tọ́,
Slušajte, jer ću zboriti o važnim stvarima, i moje će usne otkriti što je pravo.
7 ẹnu mi ń sọ ohun tí í ṣe òtítọ́, nítorí ètè mi kórìíra ibi.
Jer moje nepce zbori istinu i zloća je mojim usnama mrska.
8 Gbogbo ọ̀rọ̀ ẹnu mi ni ó tọ́, kò sí èyí tí ó jẹ́ ẹ̀tàn tàbí àyídáyidà níbẹ̀.
Sve su riječi mojih usta pravične, u njima nema ništa ni krivo ni prijetvorno.
9 Fún olóye gbogbo rẹ̀ ni ó tọ̀nà; wọ́n jẹ́ aláìlẹ́gàn fún gbogbo ẹni tí ó ní ìmọ̀.
Sve su one jasne razboritomu i pravedne onomu tko je stekao spoznaju.
10 Yan ẹ̀kọ́ mi dípò fàdákà, ìmọ̀ dípò o wúrà àṣàyàn,
Primajte radije moju pouku no srebro i znanje požudnije od zlata.
11 nítorí ọgbọ́n ṣe iyebíye jù iyùn lọ, kò sí ohun tí ọkàn rẹ̀ fẹ́ tí a sì le fiwé e.
Jer mudrost je vrednija od biserja i nikakve se dragocjenosti ne mogu porediti s njom.
12 “Èmi, ọgbọ́n ń gbé pẹ̀lú òye; mo ní ìmọ̀ àti ọgbọ́n-inú.
Ja, mudrost, boravim s razboritošću i posjedujem znanje umna djelovanja.
13 Ìbẹ̀rù Olúwa ni ìkórìíra ibi mo kórìíra ìgbéraga àti agídí, ìwà ibi àti ọ̀rọ̀ ẹ̀tàn.
Strah Gospodnji mržnja je na zlo. Oholost, samodostatnost, put zloće i usta puna laži - to ja mrzim.
14 Ìmọ̀ràn àti ọgbọ́n tí ó yè kooro jẹ́ tèmi mo ní òye àti agbára.
Moji su savjet i razboritost, ja sam razbor i moja je jakost.
15 Nípasẹ̀ mi ni ọba ń ṣàkóso tí àwọn aláṣẹ sì ń ṣe òfin tí ó dára.
Po meni kraljevi kraljuju i velikaši dijele pravdu.
16 Nípasẹ̀ mi àwọn ọmọ-aládé ń ṣàkóso, àti gbogbo ọlọ́lá tí ń ṣàkóso ilẹ̀ ayé.
Po meni knezuju knezovi i odličnici i svi suci zemaljski.
17 Mo fẹ́ràn àwọn tí ó fẹ́ràn mi, àwọn tí ó sì wá mi rí mi.
Ja ljubim one koji ljube mene i nalaze me koji me traže.
18 Lọ́dọ̀ mi ni ọrọ̀ àti ọlá wà, ọrọ̀ tí í tọ́jọ́ àti ìgbéga rere.
U mene je bogatstvo i slava, postojano dobro i pravednost.
19 Èso mi dára ju wúrà dáradára lọ; ohun tí mò ń mú wá ju àṣàyàn fàdákà lọ.
Moj je plod bolji od čista i žežena zlata i moj je prihod bolji od čistoga srebra.
20 Mò ń rìn ní ọ̀nà òdodo, ní ojú ọ̀nà òtítọ́,
Ja kročim putem pravde, sred pravičnih staza,
21 mò ń fi ọrọ̀ fún gbogbo àwọn tí ó fẹ́ràn mi mo sì ń mú kí ilé ìṣúra wọn kún.
da dadem dobra onima koji me ljube i napunim njihove riznice.
22 “Èmi ni Olúwa kọ́kọ́ dá nínú iṣẹ́ rẹ̀. Ṣáájú àwọn iṣẹ́ rẹ̀ àtijọ́;
Jahve me stvori kao počelo svoga djela, kao najraniji od svojih čina, u pradoba;
23 a ti yàn mí láti ayérayé, láti ìbẹ̀rẹ̀ pẹ̀pẹ̀, kí ayé tó bẹ̀rẹ̀.
oblikovana sam još od vječnosti, odiskona, prije nastanka zemlje.
24 Nígbà tí kò tí ì sí Òkun, ni a ti bí mi, nígbà tí kò tí ì sí ìsun tí ó ní omi nínú;
Rodih se kad još nije bilo pradubina, dok nije bilo izvora obilnih voda.
25 kí a tó fi àwọn òkè sí ipò wọn, ṣáájú àwọn òkè ni a ti bí mi,
Rodih se prije nego su utemeljene gore, prije brežuljaka.
26 kí ó tó dá ilẹ̀ ayé tàbí àwọn oko rẹ̀ tàbí èyíkéyìí nínú eruku ayé.
Kad još ne bijaše načinio zemlje, ni poljana, ni početka zemaljskom prahu;
27 Mo wà níbẹ̀ nígbà tí ó fi àwọn ọ̀run sí ipò wọn, nígbà tí ó fi òsùwọ̀n àyíká sórí ibú omi,
kad je stvarao nebesa, bila sam nazočna, kad je povlačio krug na licu bezdana.
28 nígbà tí ó ṣẹ̀dá òfúrufú lókè tí ó sì fi orísun ibú omi sí ipò rẹ̀ láì le è yẹsẹ̀,
Kad je u visini utvrđivao oblake i kad je odredio snagu izvoru pradubina;
29 nígbà tí ó ṣe ààlà fún omi Òkun kí omi má ba à kọjá ààlà àṣẹ rẹ̀, àti nígbà tí ó pààlà ìpìlẹ̀ ayé.
kad je postavljao moru njegove granice da mu se vode ne preliju preko obala, kad je polagao temelje zemlji,
30 Nígbà náà èmi ni gbẹ́nàgbẹ́nà ẹ̀gbẹ́ rẹ̀ mo kún fún inú dídùn lójoojúmọ́, mo ń yọ̀ nígbà gbogbo níwájú rẹ̀.
bila sam kraj njega, kao graditeljica, bila u radosti, iz dana u dan, igrajući pred njim sve vrijeme:
31 Mo ń yọ̀ nínú gbogbo àgbáyé tí ó dá mo sì ní inú dídùn sí àwọn ọmọ ènìyàn.
igrala sam po tlu njegove zemlje, i moja su radost djeca čovjekova.
32 “Nítorí náà báyìí, ẹ̀yin ọmọ mi, ìbùkún ni fún àwọn tí ó pa ọ̀nà mi mọ́.
Tako, djeco, poslušajte me, blago onima koji čuvaju moje putove.
33 Fetí sí ìtọ́sọ́nà mi kí o sì gbọ́n; má ṣe pa á tì sápá kan.
Poslušajte pouku - da stečete mudrost i nemojte je odbaciti.
34 Ìbùkún ni fún ẹni tí ó fetísílẹ̀ sí mi, tí ń ṣọ́nà ní ẹnu-ọ̀nà mi lójoojúmọ́, tí ń dúró ní ẹnu-ọ̀nà mi.
Blago čovjeku koji me sluša i bdi na mojim vratima svaki dan i koji čuva dovratnike moje.
35 Nítorí ẹnikẹ́ni tí ó bá rí mi rí ìyè ó sì rí ojúrere gbà lọ́dọ̀ Olúwa.
Jer tko nalazi mene, nalazi život i stječe milost od Jahve.
36 Ṣùgbọ́n ẹnikẹ́ni tí ó bá kọ̀ láti rí ń pa ara rẹ̀ lára gbogbo ẹni tí ó kórìíra mi fẹ́ ikú.”
A ako se ogriješi o mene, udi svojoj duši: svi koji mene mrze ljube smrt.”