< Proverbs 7 >
1 Ọmọ mi, pa ọ̀rọ̀ mi mọ́, sì fi àwọn òfin mi pamọ́ sínú ọkàn rẹ.
Hijo mío, guarda mis razones, y encierra contigo mis mandamientos.
2 Pa òfin mi mọ́, ìwọ yóò sì yè tọ́jú ẹ̀kọ́ mi bí ẹyinlójú rẹ.
Guarda mis mandamientos, y vivirás; y mi ley como las niñas de tus ojos.
3 Kọ wọ́n sí ọwọ́ òsì rẹ, má ṣe fi jẹun kọ wọ́n sí inú wàláà àyà rẹ.
Lígalos a tus dedos: escríbelos en la tabla de tu corazón.
4 Wí fún ọgbọ́n pé, “Ìwọ ni arábìnrin mi,” sì pe òye ní ìbátan rẹ.
Di a la sabiduría: Tú eres mi hermana; y a la inteligencia llama parienta:
5 Wọn yóò pa ó mọ́ kúrò lọ́wọ́ obìnrin alágbèrè, kúrò lọ́wọ́ àjèjì obìnrin àti ọ̀rọ̀ ìtànjẹ rẹ̀.
Para que te guarden de la mujer ajena, y de la extraña, que ablanda sus palabras.
6 Ní ojú fèrèsé ilé è mi mo wo ìta láti ojú fèrèsé.
Porque mirando yo por la ventana de mi casa, por mi ventana,
7 Mo rí i láàrín àwọn aláìmọ̀kan mo sì kíyèsi láàrín àwọn ọ̀dọ́kùnrin, ọ̀dọ́ kan tí ó ṣe aláìgbọ́n.
Miré entre los simples, consideré entre los mancebos un mancebo falto de entendimiento,
8 Ó ń lọ ní pópónà ní tòsí i ilé alágbèrè obìnrin náà, ó ń rìn lọ sí ọ̀nà ilé e rẹ̀.
El cual pasaba por la calle, junto a su esquina; e iba camino de su casa,
9 Ní ìrọ̀lẹ́ bí oòrùn ṣe ń wọ̀, bí òkùnkùn ṣe ń bo ni lára.
A la tarde del día, ya que oscurecía, en la oscuridad y tiniebla de la noche:
10 Bẹ́ẹ̀ ni obìnrin kan jáde wá láti pàdé rẹ̀, ó múra bí panṣágà pẹ̀lú ètè búburú.
Y veis aquí una mujer, que le sale al encuentro con atavío de ramera, astuta de corazón,
11 (Ó jẹ́ aláriwo àti alágídí, ìdí rẹ̀ kì í jókòó nílé;
Alborotadora y rencillosa: sus pies no pueden estar en casa:
12 bí ó ti ń já níhìn-ín ní ó ń já lọ́hùn ún gbogbo orígun ni ó ti ń ba ní ibùba.)
Ahora de fuera, ahora por las plazas: asechando por todas las encrucijadas.
13 Ó dìímú, ó sì fẹnukò ó ní ẹnu pẹ̀lú ojú díndín ó wí pé,
Y traba de él, y bésale; desvergonzó su rostro; y díjole:
14 “Mo ní ọrẹ àlàáfíà ní ilé; lónìí ni mo san ẹ̀jẹ́ mi.
Sacrificios de paz he prometido, hoy he pagado mis votos:
15 Nítorí náà ni n o ṣe jáde wá pàdé è rẹ; mo wá ọ káàkiri mo sì ti rí ọ!
Por tanto he salido a encontrarte, buscando diligentemente tu faz; y héte hallado.
16 Mo ti tẹ́ ibùsùn mi pẹ̀lú aṣọ aláràbarà láti ilẹ̀ Ejibiti.
Con paramentos he emparamentado mi cama, alzados con cuerdas de Egipto.
17 Mo ti fi nǹkan olóòórùn dídùn sí ibùsùn mi bí i òjìá, aloe àti kinamoni.
He sahumado mi cámara con mirra, áloes, y canela.
18 Wá, jẹ́ kí a lo ìfẹ́ papọ̀ ní kíkún títí di àárọ̀; jẹ́ kí a gbádùn ara wa pẹ̀lú ìfẹ́!
Ven, embriaguémosnos de amores hasta la mañana: alegrémosnos en amores.
19 Ọkọ ọ̀ mi ò sí nílé; ó ti lọ sí ìrìnàjò jíjìn.
Porque el marido no está en su casa, ha ido a un viaje muy largo:
20 Ó mú owó púpọ̀ lọ́wọ́ kò sì ní darí dé kí ó tó di ọ̀sán.”
El saco del dinero llevó en su mano, el día de la fiesta volverá a su casa.
21 Pẹ̀lú ọ̀rọ̀ dídùn ó sì í lọ́nà; ó tàn án jẹ pẹ̀lú ẹnu dídùn.
Derribóle con la multitud de la suavidad de sus palabras: con la blandura de sus labios le compelió.
22 Òun sì tọ̀ ọ́ lọ lẹsẹ̀ kan náà, bí i màlúù tí ń lọ sí ibi pípa, tàbí bí àgbọ̀nrín tí ń lọ sí ibi okùn ìso.
Váse en pos de ella luego, como va el buey al degolladero, y como el insensato a las prisiones para ser castigado:
23 Títí tí ọ̀kọ̀ fi gún un ní ẹ̀dọ̀, bí ẹyẹ ṣe ń fẹ́ wọ inú okùn, láìmọ̀ pé yóò gba ẹ̀mí òun.
De tal manera que la saeta traspasó su hígado: como el ave que se apresura al lazo, y no sabe que es contra su vida.
24 Nítorí náà báyìí ẹ̀yin ọmọ mi, tẹ́tí sí mi fọkàn sí nǹkan tí mo sọ.
Ahora pues hijos, oídme, y estád atentos a las razones de mi boca.
25 Má ṣe jẹ́ kí ọkàn rẹ kí ó yà sí ọ̀nà rẹ̀, tàbí kí ó rìn lọ sí ipa ọ̀nà rẹ̀.
No se aparte a sus caminos tu corazón; y no yerres en sus veredas.
26 Ọ̀pọ̀lọpọ̀ ni àwọn tí ó ti fà lulẹ̀. Ogunlọ́gọ̀ àwọn alágbára ni ó ti pa.
Porque a muchos ha hecho caer muertos; y todos los fuertes han sido muertos por ella.
27 Ilé e rẹ̀ ni ọ̀nà tààrà sí isà òkú, tí ó lọ tààrà sí àgbàlá ikú. (Sheol )
Caminos del sepulcro son su casa, que descienden a las cámaras de la muerte. (Sheol )