< Proverbs 7 >

1 Ọmọ mi, pa ọ̀rọ̀ mi mọ́, sì fi àwọn òfin mi pamọ́ sínú ọkàn rẹ.
Hijo mío, guarda mis palabras. Guarda mis mandamientos dentro de ti.
2 Pa òfin mi mọ́, ìwọ yóò sì yè tọ́jú ẹ̀kọ́ mi bí ẹyinlójú rẹ.
¡Guarda mis mandamientos y vive! Guarda mi enseñanza como la niña de tus ojos.
3 Kọ wọ́n sí ọwọ́ òsì rẹ, má ṣe fi jẹun kọ wọ́n sí inú wàláà àyà rẹ.
Átalos en los dedos. Escríbelos en la tabla de tu corazón.
4 Wí fún ọgbọ́n pé, “Ìwọ ni arábìnrin mi,” sì pe òye ní ìbátan rẹ.
Dile a la sabiduría: “Eres mi hermana”. Llama a la comprensión de tu pariente,
5 Wọn yóò pa ó mọ́ kúrò lọ́wọ́ obìnrin alágbèrè, kúrò lọ́wọ́ àjèjì obìnrin àti ọ̀rọ̀ ìtànjẹ rẹ̀.
para que te alejen de la mujer extraña, de la extranjera que halaga con sus palabras.
6 Ní ojú fèrèsé ilé è mi mo wo ìta láti ojú fèrèsé.
Pues en la ventana de mi casa, Miré a través de mi celosía.
7 Mo rí i láàrín àwọn aláìmọ̀kan mo sì kíyèsi láàrín àwọn ọ̀dọ́kùnrin, ọ̀dọ́ kan tí ó ṣe aláìgbọ́n.
Vi entre los simples. Distinguí entre los jóvenes a un joven vacío de entendimiento,
8 Ó ń lọ ní pópónà ní tòsí i ilé alágbèrè obìnrin náà, ó ń rìn lọ sí ọ̀nà ilé e rẹ̀.
pasando por la calle cerca de su esquina, se dirigió a su casa,
9 Ní ìrọ̀lẹ́ bí oòrùn ṣe ń wọ̀, bí òkùnkùn ṣe ń bo ni lára.
en el crepúsculo, en la tarde del día, en medio de la noche y en la oscuridad.
10 Bẹ́ẹ̀ ni obìnrin kan jáde wá láti pàdé rẹ̀, ó múra bí panṣágà pẹ̀lú ètè búburú.
He aquí que le salió al encuentro una mujer con atuendo de prostituta, y con astucia.
11 (Ó jẹ́ aláriwo àti alágídí, ìdí rẹ̀ kì í jókòó nílé;
Es ruidosa y desafiante. Sus pies no se quedan en su casa.
12 bí ó ti ń já níhìn-ín ní ó ń já lọ́hùn ún gbogbo orígun ni ó ti ń ba ní ibùba.)
Ahora está en las calles, ahora en las plazas, y acechando en cada esquina.
13 Ó dìímú, ó sì fẹnukò ó ní ẹnu pẹ̀lú ojú díndín ó wí pé,
Entonces ella lo agarró y lo besó. Con una cara impúdica le dijo:
14 “Mo ní ọrẹ àlàáfíà ní ilé; lónìí ni mo san ẹ̀jẹ́ mi.
“Los sacrificios de ofrendas de paz están conmigo. Hoy he pagado mis votos.
15 Nítorí náà ni n o ṣe jáde wá pàdé è rẹ; mo wá ọ káàkiri mo sì ti rí ọ!
Por eso salí a tu encuentro, para buscar diligentemente tu rostro, y te he encontrado.
16 Mo ti tẹ́ ibùsùn mi pẹ̀lú aṣọ aláràbarà láti ilẹ̀ Ejibiti.
He extendido mi sofá con alfombras de tapiz, con telas rayadas del hilo de Egipto.
17 Mo ti fi nǹkan olóòórùn dídùn sí ibùsùn mi bí i òjìá, aloe àti kinamoni.
He perfumado mi cama con mirra, áloe y canela.
18 Wá, jẹ́ kí a lo ìfẹ́ papọ̀ ní kíkún títí di àárọ̀; jẹ́ kí a gbádùn ara wa pẹ̀lú ìfẹ́!
Ven, vamos a saciarnos de amor hasta la mañana. Consolémonos con el amor.
19 Ọkọ ọ̀ mi ò sí nílé; ó ti lọ sí ìrìnàjò jíjìn.
Porque mi marido no está en casa. Ha hecho un largo viaje.
20 Ó mú owó púpọ̀ lọ́wọ́ kò sì ní darí dé kí ó tó di ọ̀sán.”
Se ha llevado una bolsa de dinero. Volverá a casa con la luna llena”.
21 Pẹ̀lú ọ̀rọ̀ dídùn ó sì í lọ́nà; ó tàn án jẹ pẹ̀lú ẹnu dídùn.
Con palabras persuasivas, ella lo desvió. Con el halago de sus labios, lo sedujo.
22 Òun sì tọ̀ ọ́ lọ lẹsẹ̀ kan náà, bí i màlúù tí ń lọ sí ibi pípa, tàbí bí àgbọ̀nrín tí ń lọ sí ibi okùn ìso.
La siguió inmediatamente, como un buey va al matadero, como un tonto que se mete en un lazo.
23 Títí tí ọ̀kọ̀ fi gún un ní ẹ̀dọ̀, bí ẹyẹ ṣe ń fẹ́ wọ inú okùn, láìmọ̀ pé yóò gba ẹ̀mí òun.
Hasta que una flecha le atraviese el hígado, como un pájaro se apresura a la trampa, y no sabe que le costará la vida.
24 Nítorí náà báyìí ẹ̀yin ọmọ mi, tẹ́tí sí mi fọkàn sí nǹkan tí mo sọ.
Ahora, pues, hijos, escuchadme. Presta atención a las palabras de mi boca.
25 Má ṣe jẹ́ kí ọkàn rẹ kí ó yà sí ọ̀nà rẹ̀, tàbí kí ó rìn lọ sí ipa ọ̀nà rẹ̀.
No dejes que tu corazón se vuelva hacia sus caminos. No te desvíes de sus caminos,
26 Ọ̀pọ̀lọpọ̀ ni àwọn tí ó ti fà lulẹ̀. Ogunlọ́gọ̀ àwọn alágbára ni ó ti pa.
porque ha arrojado muchos heridos. Sí, todos sus muertos son un poderoso ejército.
27 Ilé e rẹ̀ ni ọ̀nà tààrà sí isà òkú, tí ó lọ tààrà sí àgbàlá ikú. (Sheol h7585)
Su casa es el camino al Seol, bajando a las habitaciones de la muerte. (Sheol h7585)

< Proverbs 7 >