< Proverbs 7 >
1 Ọmọ mi, pa ọ̀rọ̀ mi mọ́, sì fi àwọn òfin mi pamọ́ sínú ọkàn rẹ.
Filho meu, guarda as minhas palavras, e esconde dentro de ti os meus mandamentos.
2 Pa òfin mi mọ́, ìwọ yóò sì yè tọ́jú ẹ̀kọ́ mi bí ẹyinlójú rẹ.
Guarda os meus mandamentos, e vive; e a minha lei, como as meninas dos teus olhos.
3 Kọ wọ́n sí ọwọ́ òsì rẹ, má ṣe fi jẹun kọ wọ́n sí inú wàláà àyà rẹ.
Ata-os aos teus dedos, escreve-os na táboa do teu coração.
4 Wí fún ọgbọ́n pé, “Ìwọ ni arábìnrin mi,” sì pe òye ní ìbátan rẹ.
Dize à sabedoria, Tu és minha irmã; e à prudência chama parenta.
5 Wọn yóò pa ó mọ́ kúrò lọ́wọ́ obìnrin alágbèrè, kúrò lọ́wọ́ àjèjì obìnrin àti ọ̀rọ̀ ìtànjẹ rẹ̀.
Para te guardarem da mulher alheia, da estrangeira, que lisongeia com as suas palavras.
6 Ní ojú fèrèsé ilé è mi mo wo ìta láti ojú fèrèsé.
Porque da janela da minha casa, por minhas grades olhando eu,
7 Mo rí i láàrín àwọn aláìmọ̀kan mo sì kíyèsi láàrín àwọn ọ̀dọ́kùnrin, ọ̀dọ́ kan tí ó ṣe aláìgbọ́n.
Vi entre os símplices, descobri entre os moços, um mancebo falto de juízo,
8 Ó ń lọ ní pópónà ní tòsí i ilé alágbèrè obìnrin náà, ó ń rìn lọ sí ọ̀nà ilé e rẹ̀.
Que passava pela rua junto à sua esquina, e seguia o caminho da sua casa;
9 Ní ìrọ̀lẹ́ bí oòrùn ṣe ń wọ̀, bí òkùnkùn ṣe ń bo ni lára.
No crepúsculo, à tarde do dia, na tenebrosa noite e na escuridão;
10 Bẹ́ẹ̀ ni obìnrin kan jáde wá láti pàdé rẹ̀, ó múra bí panṣágà pẹ̀lú ètè búburú.
E eis que uma mulher lhe saiu ao encontro, com enfeites de prostituta, e astuta de coração:
11 (Ó jẹ́ aláriwo àti alágídí, ìdí rẹ̀ kì í jókòó nílé;
Esta era alvoroçadora, e contenciosa; não paravam em sua casa os seus pés;
12 bí ó ti ń já níhìn-ín ní ó ń já lọ́hùn ún gbogbo orígun ni ó ti ń ba ní ibùba.)
Agora por fora, depois pelas ruas, e espreitando por todos os cantos:
13 Ó dìímú, ó sì fẹnukò ó ní ẹnu pẹ̀lú ojú díndín ó wí pé,
E pegou dele, e o beijou; esforçou o seu rosto, e disse-lhe:
14 “Mo ní ọrẹ àlàáfíà ní ilé; lónìí ni mo san ẹ̀jẹ́ mi.
Sacrifícios pacíficos tenho comigo; hoje paguei os meus votos.
15 Nítorí náà ni n o ṣe jáde wá pàdé è rẹ; mo wá ọ káàkiri mo sì ti rí ọ!
Por isto saí ao encontro a buscar diligentemente a tua face, e te achei.
16 Mo ti tẹ́ ibùsùn mi pẹ̀lú aṣọ aláràbarà láti ilẹ̀ Ejibiti.
Já cobri a minha cama com cobertas de tapeçaria, com obras lavradas com linho fino do Egito.
17 Mo ti fi nǹkan olóòórùn dídùn sí ibùsùn mi bí i òjìá, aloe àti kinamoni.
Já perfumei o meu leito com mirra, aloes, e canela.
18 Wá, jẹ́ kí a lo ìfẹ́ papọ̀ ní kíkún títí di àárọ̀; jẹ́ kí a gbádùn ara wa pẹ̀lú ìfẹ́!
Vem, saciemo-nos de amores até pela manhã: alegremo-nos com amores.
19 Ọkọ ọ̀ mi ò sí nílé; ó ti lọ sí ìrìnàjò jíjìn.
Porque já o marido não está em sua casa: foi fazer uma jornada ao longe:
20 Ó mú owó púpọ̀ lọ́wọ́ kò sì ní darí dé kí ó tó di ọ̀sán.”
Um saquitel de dinheiro levou na sua mão: ao dia apontado virá a sua casa.
21 Pẹ̀lú ọ̀rọ̀ dídùn ó sì í lọ́nà; ó tàn án jẹ pẹ̀lú ẹnu dídùn.
Seduziu-o com a multidão das suas palavras, com as lisonjas dos seus lábios o persuadiu.
22 Òun sì tọ̀ ọ́ lọ lẹsẹ̀ kan náà, bí i màlúù tí ń lọ sí ibi pípa, tàbí bí àgbọ̀nrín tí ń lọ sí ibi okùn ìso.
Segue-a logo, como boi que vai ao matadouro, e como o louco ao castigo das prisões;
23 Títí tí ọ̀kọ̀ fi gún un ní ẹ̀dọ̀, bí ẹyẹ ṣe ń fẹ́ wọ inú okùn, láìmọ̀ pé yóò gba ẹ̀mí òun.
Até que a flecha lhe atravesse o fígado, como a ave que se apressa para o laço, e não sabe que está armado contra a sua vida.
24 Nítorí náà báyìí ẹ̀yin ọmọ mi, tẹ́tí sí mi fọkàn sí nǹkan tí mo sọ.
Agora pois, filhos, dai-me ouvidos, e estai atentos às palavras da minha boca.
25 Má ṣe jẹ́ kí ọkàn rẹ kí ó yà sí ọ̀nà rẹ̀, tàbí kí ó rìn lọ sí ipa ọ̀nà rẹ̀.
Não se desvie para os seus caminhos o teu coração, e não andes perdido nas suas veredas.
26 Ọ̀pọ̀lọpọ̀ ni àwọn tí ó ti fà lulẹ̀. Ogunlọ́gọ̀ àwọn alágbára ni ó ti pa.
Porque a muitos feridos derribou; e são muitíssimos os que por ela foram mortos.
27 Ilé e rẹ̀ ni ọ̀nà tààrà sí isà òkú, tí ó lọ tààrà sí àgbàlá ikú. (Sheol )
Caminhos da sepultura são a sua casa, que descem às câmaras da morte. (Sheol )