< Proverbs 7 >
1 Ọmọ mi, pa ọ̀rọ̀ mi mọ́, sì fi àwọn òfin mi pamọ́ sínú ọkàn rẹ.
Mon fils, retiens mes paroles et pénètre-toi de mes recommandations;
2 Pa òfin mi mọ́, ìwọ yóò sì yè tọ́jú ẹ̀kọ́ mi bí ẹyinlójú rẹ.
garde mes préceptes pour que tu vives, et mon enseignement, comme la prunelle de tes yeux.
3 Kọ wọ́n sí ọwọ́ òsì rẹ, má ṣe fi jẹun kọ wọ́n sí inú wàláà àyà rẹ.
Attache-les à tes doigts, inscris-les sur les tablettes de ton cœur.
4 Wí fún ọgbọ́n pé, “Ìwọ ni arábìnrin mi,” sì pe òye ní ìbátan rẹ.
Dis à la sagesse: "Tu es ma sœur," et appelle la raison" Mon amie!"
5 Wọn yóò pa ó mọ́ kúrò lọ́wọ́ obìnrin alágbèrè, kúrò lọ́wọ́ àjèjì obìnrin àti ọ̀rọ̀ ìtànjẹ rẹ̀.
Ainsi tu seras mis en garde contre la femme d’autrui, contre l’étrangère au parler doucereux.
6 Ní ojú fèrèsé ilé è mi mo wo ìta láti ojú fèrèsé.
Aussi bien, il m’arriva de regarder par la fenêtre de ma chambre, à travers mon treillis.
7 Mo rí i láàrín àwọn aláìmọ̀kan mo sì kíyèsi láàrín àwọn ọ̀dọ́kùnrin, ọ̀dọ́ kan tí ó ṣe aláìgbọ́n.
J’Observai les jeunes étourdis, je distinguai, parmi eux, un adolescent dépourvu d’intelligence.
8 Ó ń lọ ní pópónà ní tòsí i ilé alágbèrè obìnrin náà, ó ń rìn lọ sí ọ̀nà ilé e rẹ̀.
Il passait dans la rue, près du logis de cette femme, et dirigeait ses pas vers sa maison.
9 Ní ìrọ̀lẹ́ bí oòrùn ṣe ń wọ̀, bí òkùnkùn ṣe ń bo ni lára.
C’Était à l’heure du crépuscule, quand le soir tombait et que la nuit se faisait sombre et obscure.
10 Bẹ́ẹ̀ ni obìnrin kan jáde wá láti pàdé rẹ̀, ó múra bí panṣágà pẹ̀lú ètè búburú.
Or, voici qu’une femme l’aborde, à la mise de courtisane et au cœur artificieux.
11 (Ó jẹ́ aláriwo àti alágídí, ìdí rẹ̀ kì í jókòó nílé;
Bruyante et désordonnée, ses pieds ne tiennent pas en place à la maison;
12 bí ó ti ń já níhìn-ín ní ó ń já lọ́hùn ún gbogbo orígun ni ó ti ń ba ní ibùba.)
tantôt dans la rue, tantôt sur les places, à chaque coin elle se met aux aguets.
13 Ó dìímú, ó sì fẹnukò ó ní ẹnu pẹ̀lú ojú díndín ó wí pé,
Cette femme s’empare de lui, le couvre de baisers et, prenant un air effronté, lui dit:
14 “Mo ní ọrẹ àlàáfíà ní ilé; lónìí ni mo san ẹ̀jẹ́ mi.
"J’Avais à faire un sacrifice de reconnaissance, et aujourd’hui même je me suis acquittée de mes vœux.
15 Nítorí náà ni n o ṣe jáde wá pàdé è rẹ; mo wá ọ káàkiri mo sì ti rí ọ!
C’Est pourquoi je suis sortie à ta rencontre, voulant me trouver face à face avec toi, et te voilà!
16 Mo ti tẹ́ ibùsùn mi pẹ̀lú aṣọ aláràbarà láti ilẹ̀ Ejibiti.
J’Ai paré ma couche de riches broderies, de draps en lin d’Egypte.
17 Mo ti fi nǹkan olóòórùn dídùn sí ibùsùn mi bí i òjìá, aloe àti kinamoni.
J’Ai parfumé mon lit de repos de myrrhe, d’aloès et de cinnamone.
18 Wá, jẹ́ kí a lo ìfẹ́ papọ̀ ní kíkún títí di àárọ̀; jẹ́ kí a gbádùn ara wa pẹ̀lú ìfẹ́!
Viens donc, enivrons-nous d’amour jusqu’au matin, épuisons les délices des caresses.
19 Ọkọ ọ̀ mi ò sí nílé; ó ti lọ sí ìrìnàjò jíjìn.
Mon mari n’est pas à la maison, il est parti pour un voyage lointain.
20 Ó mú owó púpọ̀ lọ́wọ́ kò sì ní darí dé kí ó tó di ọ̀sán.”
Il a emporté sa sacoche avec lui et ne rentrera qu’au jour convenu."
21 Pẹ̀lú ọ̀rọ̀ dídùn ó sì í lọ́nà; ó tàn án jẹ pẹ̀lú ẹnu dídùn.
Elle l’ébranle par ce flux de paroles, et achève sa défaite par sa faconde insinuante.
22 Òun sì tọ̀ ọ́ lọ lẹsẹ̀ kan náà, bí i màlúù tí ń lọ sí ibi pípa, tàbí bí àgbọ̀nrín tí ń lọ sí ibi okùn ìso.
Soudain il la suit, comme le bœuf va à l’abattoir, comme un fou qu’on entraîne pour le châtier,
23 Títí tí ọ̀kọ̀ fi gún un ní ẹ̀dọ̀, bí ẹyẹ ṣe ń fẹ́ wọ inú okùn, láìmọ̀ pé yóò gba ẹ̀mí òun.
comme le passereau se lance dans le piège, jusqu’à ce qu’une flèche lui perce le foie: il ne se doute pas qu’il y va de sa vie.
24 Nítorí náà báyìí ẹ̀yin ọmọ mi, tẹ́tí sí mi fọkàn sí nǹkan tí mo sọ.
Et maintenant, mes fils, écoutez-moi, soyez attentifs aux paroles de ma bouche.
25 Má ṣe jẹ́ kí ọkàn rẹ kí ó yà sí ọ̀nà rẹ̀, tàbí kí ó rìn lọ sí ipa ọ̀nà rẹ̀.
Que votre cœur ne se détourne pas vers les voies d’une telle femme, ne vous égarez pas dans ses sentiers;
26 Ọ̀pọ̀lọpọ̀ ni àwọn tí ó ti fà lulẹ̀. Ogunlọ́gọ̀ àwọn alágbára ni ó ti pa.
car nombreuses sont les victimes dont elle a causé la chute, et ceux qu’elle a fait périr sont foule.
27 Ilé e rẹ̀ ni ọ̀nà tààrà sí isà òkú, tí ó lọ tààrà sí àgbàlá ikú. (Sheol )
Sa maison est comme les avenues du Cheol, qui aboutissent aux demeures souterraines de la mort. (Sheol )