< Proverbs 7 >

1 Ọmọ mi, pa ọ̀rọ̀ mi mọ́, sì fi àwọn òfin mi pamọ́ sínú ọkàn rẹ.
My son, observe my sayings, and my commandments must thou treasure up with thee.
2 Pa òfin mi mọ́, ìwọ yóò sì yè tọ́jú ẹ̀kọ́ mi bí ẹyinlójú rẹ.
Observe my commandments, and live: and my teaching as the apple of thy eyes.
3 Kọ wọ́n sí ọwọ́ òsì rẹ, má ṣe fi jẹun kọ wọ́n sí inú wàláà àyà rẹ.
Bind them around thy fingers, write them upon the table of thy heart.
4 Wí fún ọgbọ́n pé, “Ìwọ ni arábìnrin mi,” sì pe òye ní ìbátan rẹ.
Say unto wisdom, Thou art my sister; and call understanding thy kinswoman:
5 Wọn yóò pa ó mọ́ kúrò lọ́wọ́ obìnrin alágbèrè, kúrò lọ́wọ́ àjèjì obìnrin àti ọ̀rọ̀ ìtànjẹ rẹ̀.
That they may keep thee from an adulterous woman, from an alien that useth flattering speeches.
6 Ní ojú fèrèsé ilé è mi mo wo ìta láti ojú fèrèsé.
For through the window of my house, through my lattice did I [once] look out,
7 Mo rí i láàrín àwọn aláìmọ̀kan mo sì kíyèsi láàrín àwọn ọ̀dọ́kùnrin, ọ̀dọ́ kan tí ó ṣe aláìgbọ́n.
And I beheld among the simple ones, I discerned among the youths, a lad void of sense;
8 Ó ń lọ ní pópónà ní tòsí i ilé alágbèrè obìnrin náà, ó ń rìn lọ sí ọ̀nà ilé e rẹ̀.
He was passing through the market-place near her corner; and he stepped along on the way to her house,
9 Ní ìrọ̀lẹ́ bí oòrùn ṣe ń wọ̀, bí òkùnkùn ṣe ń bo ni lára.
In the twilight, in the evening of the day, in the depth of the night and when it was dark:
10 Bẹ́ẹ̀ ni obìnrin kan jáde wá láti pàdé rẹ̀, ó múra bí panṣágà pẹ̀lú ètè búburú.
And, behold, a woman came to meet him with the attire of a harlot, and obdurate of heart.
11 (Ó jẹ́ aláriwo àti alágídí, ìdí rẹ̀ kì í jókòó nílé;
(She is noisy and ungovernable; in her house her feet never rest;
12 bí ó ti ń já níhìn-ín ní ó ń já lọ́hùn ún gbogbo orígun ni ó ti ń ba ní ibùba.)
At one time she is in the street, at another in the open places, and near every corner doth she lurk, )
13 Ó dìímú, ó sì fẹnukò ó ní ẹnu pẹ̀lú ojú díndín ó wí pé,
And she caught hold of him, and kissed him, and with an impudent face she said to him,
14 “Mo ní ọrẹ àlàáfíà ní ilé; lónìí ni mo san ẹ̀jẹ́ mi.
“I had bound myself to bring peace-offerings; this day have I paid my vows:
15 Nítorí náà ni n o ṣe jáde wá pàdé è rẹ; mo wá ọ káàkiri mo sì ti rí ọ!
Therefore am I come forth to meet thee, to seek thy presence diligently, and I have found thee.
16 Mo ti tẹ́ ibùsùn mi pẹ̀lú aṣọ aláràbarà láti ilẹ̀ Ejibiti.
With tapestry coverings have I decked my bed, with embroidered coverlids of the fine linen of Egypt.
17 Mo ti fi nǹkan olóòórùn dídùn sí ibùsùn mi bí i òjìá, aloe àti kinamoni.
I have sprinkled my couch with myrrh, aloes, and cinnamon.
18 Wá, jẹ́ kí a lo ìfẹ́ papọ̀ ní kíkún títí di àárọ̀; jẹ́ kí a gbádùn ara wa pẹ̀lú ìfẹ́!
Come, let us indulge in love until the morning: let us delight ourselves with dalliances.
19 Ọkọ ọ̀ mi ò sí nílé; ó ti lọ sí ìrìnàjò jíjìn.
For the man is not in his house, he is gone on a journey a great way off:
20 Ó mú owó púpọ̀ lọ́wọ́ kò sì ní darí dé kí ó tó di ọ̀sán.”
The bag of money hath he taken with him, by the day of the new-moon festival only will he come home.”
21 Pẹ̀lú ọ̀rọ̀ dídùn ó sì í lọ́nà; ó tàn án jẹ pẹ̀lú ẹnu dídùn.
She seduced him by the abundance of her reasoning: by the flattery of her lips she misguided him.
22 Òun sì tọ̀ ọ́ lọ lẹsẹ̀ kan náà, bí i màlúù tí ń lọ sí ibi pípa, tàbí bí àgbọ̀nrín tí ń lọ sí ibi okùn ìso.
He followed after her suddenly, as an ox goeth to the slaughter, and as in fetters to his correction, the fool:
23 Títí tí ọ̀kọ̀ fi gún un ní ẹ̀dọ̀, bí ẹyẹ ṣe ń fẹ́ wọ inú okùn, láìmọ̀ pé yóò gba ẹ̀mí òun.
Till an arrow cleaveth through his liver; as a bird hasteneth into the snare, and knoweth not that it is done to take his life.
24 Nítorí náà báyìí ẹ̀yin ọmọ mi, tẹ́tí sí mi fọkàn sí nǹkan tí mo sọ.
And now, O children, hearken unto me, and listen to the sayings of my mouth.
25 Má ṣe jẹ́ kí ọkàn rẹ kí ó yà sí ọ̀nà rẹ̀, tàbí kí ó rìn lọ sí ipa ọ̀nà rẹ̀.
Let not thy heart turn aside to her ways, do not go astray on her paths.
26 Ọ̀pọ̀lọpọ̀ ni àwọn tí ó ti fà lulẹ̀. Ogunlọ́gọ̀ àwọn alágbára ni ó ti pa.
For many deadly wounded hath she caused to fall: yea, very numerous are all those slain by her.
27 Ilé e rẹ̀ ni ọ̀nà tààrà sí isà òkú, tí ó lọ tààrà sí àgbàlá ikú. (Sheol h7585)
The ways to the nether world is her house leading down to the chambers of death. (Sheol h7585)

< Proverbs 7 >