< Proverbs 6 >

1 Ọmọ mi, bí ìwọ bá ṣe onídùúró fún aládùúgbò rẹ, bí ìwọ bá jẹ́ ẹ̀jẹ́ fún àjèjì ènìyàn,
Сыне, аще поручишися за твоего друга, предаси твою руку врагу.
2 bí a bá ti fi ọ̀rọ̀ tí ó sọ dẹkùn mú ọ, tí ọ̀rọ̀ ẹnu rẹ ti kó ọ sí pàkúté.
Сеть бо крепка мужу свои устне, и пленяется устнами своих уст.
3 Nígbà náà, ṣe èyí, ìwọ ọmọ mi, láti gba ara rẹ níwọ̀n bí o ti kó ṣọ́wọ́ aládùúgbò rẹ: lọ kí o sì rẹ ara rẹ sílẹ̀; bẹ aládùúgbò rẹ dáradára.
Твори, сыне, яже аз заповедую ти, и спасайся: идеши бо в руце злых за твоего друга: буди не ослабевая, поощряй же и твоего друга, егоже испоручил еси.
4 Má ṣe jẹ́ kí oorun kí ó kùn ọ́, tàbí kí o tilẹ̀ tòògbé rárá.
Не даждь сна твоима очима, ниже да воздремлеши твоима веждома,
5 Gba ara rẹ sílẹ̀, bí abo èsúró kúrò lọ́wọ́ ọdẹ, bí ẹyẹ kúrò nínú okùn àwọn pẹyẹpẹyẹ.
да спасешися аки серна от тенет и яко птица от сети.
6 Tọ èèrà lọ, ìwọ ọ̀lẹ; kíyèsi ìṣe rẹ̀, kí o sì gbọ́n!
Иди ко мравию, о, лениве, и поревнуй видев пути его, и буди онаго мудрейший:
7 Kò ní olùdarí, kò sí alábojútó tàbí ọba,
он бо, не сущу ему земледелцу, ниже нудящаго его имеяй, ниже под владыкою сый,
8 síbẹ̀, a kó ìpèsè rẹ̀ jọ ní àsìkò òjò yóò sì kó oúnjẹ rẹ̀ jọ ní àsìkò ìkórè.
готовит в жатву пищу и многое в лето творит уготование. Или иди ко пчеле и увеждь, коль делателница есть, делание же коль честное творит: еяже трудов царие и простии во здравие употребляют, любима же есть всеми и славна: аще силою и немощна сущи, (но) премудростию почтена произведеся.
9 Yóò ti pẹ́ tó tí ìwọ yóò dùbúlẹ̀, ìwọ ọ̀lẹ? Nígbà wo ni ìwọ yóò jí kúrò lójú oorun rẹ?
Доколе, о, лениве, лежиши? Когда же от сна востанеши?
10 Oorun díẹ̀, òògbé díẹ̀, ìkáwọ́gbera láti sinmi díẹ̀.
Мало убо спиши, мало же седиши, мало же дремлеши, мало же объемлеши перси рукама:
11 Òsì yóò sì wá sórí rẹ bí ìgárá ọlọ́ṣà àti àìní bí adigunjalè.
потом же найдет тебе аки зол путник убожество: скудость же аки благий течец. Аще же не ленив будеши, приидет яко источник жатва твоя, скудость же аки злый течец (от тебе) отбежит.
12 Ènìyànkénìyàn àti ènìyàn búburú, tí ń ru ẹnu àrékérekè káàkiri,
Муж безумен и законопреступный ходит в пути не благи:
13 tí ó ń ṣẹ́jú pàkòpàkò, ó ń fi ẹsẹ̀ rẹ̀ sọ̀rọ̀ ó sì ń fi ìka ọwọ́ rẹ̀ júwe,
той же намизает оком и знамение дает ногою, учит же помаванием перстов.
14 tí ó ń pète búburú pẹ̀lú ẹ̀tàn nínú ọkàn rẹ̀ ìgbà gbogbo ni ó máa ń dá ìjà sílẹ̀.
Развращенно же сердце кует злая: на всякое время таковый мятежы составляет граду.
15 Nítorí náà ìdààmú yóò dé bá a ní ìṣẹ́jú akàn; yóò parun lójijì láìsí àtúnṣe.
Сего ради внезапу приходит ему погибель, разсечение и сокрушение неизцельное.
16 Àwọn ohun mẹ́fà wà tí Olúwa kórìíra, ohun méje ní ó jẹ́ ìríra sí i,
Яко радуется о всех, ихже ненавидит Бог, сокрушается же за нечистоту души:
17 Ojú ìgbéraga, ahọ́n tó ń parọ́ ọwọ́ tí ń ta ẹ̀jẹ̀ aláìṣẹ̀ sílẹ̀,
око досадителя, язык неправедный, руце проливающя кровь праведнаго,
18 ọkàn tí ń pète ohun búburú, ẹsẹ̀ tí ó yára láti sáré sínú ìwà ìkà,
и сердце кующее мысли злы, и нозе тщащыяся зло творити потребятся.
19 ajẹ́rìí èké tí ń tú irọ́ jáde lẹ́nu àti ènìyàn tí ń dá ìjà sílẹ̀ láàrín àwọn ọmọ ìyá kan.
Разжизает лжы свидетель неправеден и насылает суды посреде братий.
20 Ọmọ mi, pa àṣẹ baba rẹ mọ́ má sì ṣe kọ ẹ̀kọ́ ìyá rẹ sílẹ̀.
Сыне, храни законы отца твоего и не отрини наказания матере твоея:
21 Jẹ́ kí wọn wà nínú ọkàn rẹ láéláé so wọ́n mọ́ ọrùn rẹ.
навяжи же я на твою душу присно и обяжи их о твоей выи.
22 Nígbà tí ìwọ bá ń rìn, wọn yóò ṣe amọ̀nà rẹ; nígbà tí ìwọ bá sùn, wọn yóò máa ṣe olùṣọ́ rẹ; nígbà tí o bá jí, wọn yóò bá ọ sọ̀rọ̀.
Егда ходиши, води ю, и с тобою да будет: егда же спиши, да хранит тя, да востающу ти глаголет с тобою.
23 Nítorí àwọn àṣẹ yìí jẹ́ fìtílà, ẹ̀kọ́ yìí jẹ́ ìmọ́lẹ̀, àti ìtọ́nisọ́nà ti ìbáwí ni ọ̀nà sí ìyè.
Зане светилник заповедь закона и свет, и путь жизни, и обличение, и наказание,
24 Yóò pa ọ́ mọ́ kúrò lọ́wọ́ obìnrin búburú, kúrò lọ́wọ́ ẹnu dídùn obìnrin àjèjì.
еже сохранити тя от жены мужаты и от наваждения языка чуждаго.
25 Má ṣe ṣe ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́ si nínú ọkàn rẹ nítorí ẹwà rẹ tàbí kí o jẹ́ kí ó fi ojú rẹ̀ fà ọ́ mọ́ra.
Сыне, да не победит тя доброты похоть, ниже уловлен буди твоима очима, ниже да совосхитишися веждами ея.
26 Nítorí pé nípasẹ̀ àgbèrè obìnrin ni ènìyàn fi ń di oníṣù-àkàrà kan, ṣùgbọ́n àyà ènìyàn a máa wá ìyè rẹ̀ dáradára.
Цена бо блудницы, елика единаго хлеба: жена же мужей честныя душы уловляет.
27 Ǹjẹ́ ọkùnrin ha le è gbé iná lé orí itan kí aṣọ rẹ̀ má sì jóná?
Ввяжет ли кто огнь в недра, риз же (своих) не сожжет ли?
28 Ǹjẹ́ ènìyàn le è máa rìn lórí iná? Kí ẹsẹ̀ rẹ̀ sì má jóná?
Или ходити кто будет на углиех огненных, ног же не сожжет ли?
29 Bẹ́ẹ̀ ni ẹni tí ń lọ sùn pẹ̀lú aya aláya; kò sí ẹni tí ó fọwọ́ kàn án tí yóò lọ láìjìyà.
Тако вшедый к жене мужатей не без вины будет, ниже всяк прикасайся ей.
30 Àwọn ènìyàn kì í kẹ́gàn olè tí ó bá jalè nítorí àti jẹun nígbà tí ebi bá ń pa á.
Не дивно, аще кто ят будет крадый: крадет бо, да насытит душу свою алчущую:
31 Síbẹ̀ bí ọwọ́ bá tẹ̀ ẹ́, ó gbọdọ̀ san ìlọ́po méje bí ó tilẹ̀ kó gbogbo ohun tó ní nílé tà.
аще же ят будет, воздаст седмерицею, и вся имения своя дав, избавит себе.
32 Ṣùgbọ́n ẹni tí ń ṣe àgbèrè kò nírònú; ẹnikẹ́ni tí ó bá ń ṣe bẹ́ẹ̀ ó ń pa ara rẹ̀ run ni.
Прелюбодей же за скудость ума погибель души своей содевает,
33 Ìfarapa àti ìtìjú ni tirẹ̀, ẹ̀gàn rẹ̀ kì yóò sì kúrò láéláé.
болезни же и безчестие понесет: поношение же его не загладится во век:
34 Nítorí owú yóò ru ìbínú ọkọ sókè, kì yóò sì ṣàánú nígbà tí ó bá ń gbẹ̀san.
исполнена бо ревности ярость мужа ея: не пощадит в день суда,
35 Kò nígbà nǹkan kan bí ohun ìtánràn; yóò kọ àbẹ̀tẹ́lẹ̀, bí ó ti wù kí ó pọ̀ tó.
не изменит ни единою ценою вражды, ниже разрешится многими дарми.

< Proverbs 6 >