< Proverbs 6 >

1 Ọmọ mi, bí ìwọ bá ṣe onídùúró fún aládùúgbò rẹ, bí ìwọ bá jẹ́ ẹ̀jẹ́ fún àjèjì ènìyàn,
Synu mój, jeśli poręczyłeś za swego bliźniego i dałeś porękę za obcego;
2 bí a bá ti fi ọ̀rọ̀ tí ó sọ dẹkùn mú ọ, tí ọ̀rọ̀ ẹnu rẹ ti kó ọ sí pàkúté.
Związałeś się słowami ust twoich, schwytany jesteś mową twoich ust.
3 Nígbà náà, ṣe èyí, ìwọ ọmọ mi, láti gba ara rẹ níwọ̀n bí o ti kó ṣọ́wọ́ aládùúgbò rẹ: lọ kí o sì rẹ ara rẹ sílẹ̀; bẹ aládùúgbò rẹ dáradára.
Uczyń więc tak, synu mój, uwolnij się, gdy wpadłeś w ręce swego bliźniego; idź, upokórz się i nalegaj na twego bliźniego.
4 Má ṣe jẹ́ kí oorun kí ó kùn ọ́, tàbí kí o tilẹ̀ tòògbé rárá.
Nie daj snu swoim oczom i nie pozwól powiekom drzemać.
5 Gba ara rẹ sílẹ̀, bí abo èsúró kúrò lọ́wọ́ ọdẹ, bí ẹyẹ kúrò nínú okùn àwọn pẹyẹpẹyẹ.
Uwolnij się jak sarna z rąk [myśliwego] i jak ptak z ręki ptasznika.
6 Tọ èèrà lọ, ìwọ ọ̀lẹ; kíyèsi ìṣe rẹ̀, kí o sì gbọ́n!
Idź do mrówki, leniwcze, przypatrz się jej drogom i bądź mądry;
7 Kò ní olùdarí, kò sí alábojútó tàbí ọba,
Chociaż nie ma ona wodza ani przełożonego, ani pana;
8 síbẹ̀, a kó ìpèsè rẹ̀ jọ ní àsìkò òjò yóò sì kó oúnjẹ rẹ̀ jọ ní àsìkò ìkórè.
To w lecie przygotowuje swój pokarm i gromadzi w żniwa swą żywność.
9 Yóò ti pẹ́ tó tí ìwọ yóò dùbúlẹ̀, ìwọ ọ̀lẹ? Nígbà wo ni ìwọ yóò jí kúrò lójú oorun rẹ?
Jak długo będziesz leżał, leniwcze? Kiedy wstaniesz ze swego snu?
10 Oorun díẹ̀, òògbé díẹ̀, ìkáwọ́gbera láti sinmi díẹ̀.
Jeszcze trochę snu, trochę drzemania, trochę założenia rąk, aby zasnąć;
11 Òsì yóò sì wá sórí rẹ bí ìgárá ọlọ́ṣà àti àìní bí adigunjalè.
A twoje ubóstwo przyjdzie jak podróżny i twój niedostatek jak mąż uzbrojony.
12 Ènìyànkénìyàn àti ènìyàn búburú, tí ń ru ẹnu àrékérekè káàkiri,
Człowiek nikczemny i niegodziwy chodzi z przewrotnością na ustach;
13 tí ó ń ṣẹ́jú pàkòpàkò, ó ń fi ẹsẹ̀ rẹ̀ sọ̀rọ̀ ó sì ń fi ìka ọwọ́ rẹ̀ júwe,
Mruga swymi oczyma, mówi swymi nogami, wskazuje swymi palcami;
14 tí ó ń pète búburú pẹ̀lú ẹ̀tàn nínú ọkàn rẹ̀ ìgbà gbogbo ni ó máa ń dá ìjà sílẹ̀.
Przewrotność [jest] w jego sercu, stale knuje zło [i] sieje niezgodę.
15 Nítorí náà ìdààmú yóò dé bá a ní ìṣẹ́jú akàn; yóò parun lójijì láìsí àtúnṣe.
Dlatego nagle spadnie na niego nieszczęście; nagle zostanie złamany i pozbawiony ratunku.
16 Àwọn ohun mẹ́fà wà tí Olúwa kórìíra, ohun méje ní ó jẹ́ ìríra sí i,
Jest sześć rzeczy, których nienawidzi PAN, siedem budzi w nim odrazę:
17 Ojú ìgbéraga, ahọ́n tó ń parọ́ ọwọ́ tí ń ta ẹ̀jẹ̀ aláìṣẹ̀ sílẹ̀,
Wyniosłe oczy, kłamliwy język i ręce, które przelewają krew niewinną;
18 ọkàn tí ń pète ohun búburú, ẹsẹ̀ tí ó yára láti sáré sínú ìwà ìkà,
Serce, które knuje złe myśli; nogi, które spiesznie biegną do zła;
19 ajẹ́rìí èké tí ń tú irọ́ jáde lẹ́nu àti ènìyàn tí ń dá ìjà sílẹ̀ láàrín àwọn ọmọ ìyá kan.
Fałszywy świadek, który mówi kłamstwa, i ten, który sieje niezgodę między braćmi.
20 Ọmọ mi, pa àṣẹ baba rẹ mọ́ má sì ṣe kọ ẹ̀kọ́ ìyá rẹ sílẹ̀.
Synu mój, strzeż przykazania twego ojca i nie odrzucaj prawa twojej matki.
21 Jẹ́ kí wọn wà nínú ọkàn rẹ láéláé so wọ́n mọ́ ọrùn rẹ.
Przywiąż je na zawsze do serca twego i zawieś je sobie na szyi.
22 Nígbà tí ìwọ bá ń rìn, wọn yóò ṣe amọ̀nà rẹ; nígbà tí ìwọ bá sùn, wọn yóò máa ṣe olùṣọ́ rẹ; nígbà tí o bá jí, wọn yóò bá ọ sọ̀rọ̀.
Gdy będziesz chodził, poprowadzi cię; gdy zaśniesz, strzec cię będzie, a gdy się obudzisz, będzie mówić do ciebie;
23 Nítorí àwọn àṣẹ yìí jẹ́ fìtílà, ẹ̀kọ́ yìí jẹ́ ìmọ́lẹ̀, àti ìtọ́nisọ́nà ti ìbáwí ni ọ̀nà sí ìyè.
Bo przykazanie [jest] pochodnią, prawo światłością, a upomnienia do karności są drogą życia;
24 Yóò pa ọ́ mọ́ kúrò lọ́wọ́ obìnrin búburú, kúrò lọ́wọ́ ẹnu dídùn obìnrin àjèjì.
Aby cię strzegły przed złą kobietą [i] przed gładkim językiem obcej kobiety.
25 Má ṣe ṣe ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́ si nínú ọkàn rẹ nítorí ẹwà rẹ tàbí kí o jẹ́ kí ó fi ojú rẹ̀ fà ọ́ mọ́ra.
Nie pożądaj w twoim sercu jej piękności i niech cię nie łowi swymi powiekami.
26 Nítorí pé nípasẹ̀ àgbèrè obìnrin ni ènìyàn fi ń di oníṣù-àkàrà kan, ṣùgbọ́n àyà ènìyàn a máa wá ìyè rẹ̀ dáradára.
Bo dla kobiety nierządnej [zubożeje człowiek] o kawałek chleba, a żona cudzołożna czyha na cenne życie.
27 Ǹjẹ́ ọkùnrin ha le è gbé iná lé orí itan kí aṣọ rẹ̀ má sì jóná?
Czy może ktoś wziąć ogień w zanadrze, a jego szaty się nie spalą?
28 Ǹjẹ́ ènìyàn le è máa rìn lórí iná? Kí ẹsẹ̀ rẹ̀ sì má jóná?
Czy może ktoś chodzić po rozżarzonych węglach, a jego nogi się nie poparzą?
29 Bẹ́ẹ̀ ni ẹni tí ń lọ sùn pẹ̀lú aya aláya; kò sí ẹni tí ó fọwọ́ kàn án tí yóò lọ láìjìyà.
Tak ten, kto wchodzi do żony swego bliźniego; ktokolwiek ją dotknie, nie będzie bez winy.
30 Àwọn ènìyàn kì í kẹ́gàn olè tí ó bá jalè nítorí àti jẹun nígbà tí ebi bá ń pa á.
Nie pogardza się złodziejem, jeśli kradnie, by nasycić swoją duszę, będąc głodnym;
31 Síbẹ̀ bí ọwọ́ bá tẹ̀ ẹ́, ó gbọdọ̀ san ìlọ́po méje bí ó tilẹ̀ kó gbogbo ohun tó ní nílé tà.
Ale [jeśli] go złapią, zwróci siedmiokrotnie [albo] odda cały dobytek swego domu.
32 Ṣùgbọ́n ẹni tí ń ṣe àgbèrè kò nírònú; ẹnikẹ́ni tí ó bá ń ṣe bẹ́ẹ̀ ó ń pa ara rẹ̀ run ni.
Lecz kto cudzołoży z kobietą, jest pozbawiony rozsądku; kto tak robi, gubi swoją duszę.
33 Ìfarapa àti ìtìjú ni tirẹ̀, ẹ̀gàn rẹ̀ kì yóò sì kúrò láéláé.
Znajdzie chłostę i wstyd, a jego hańba nie będzie zmazana.
34 Nítorí owú yóò ru ìbínú ọkọ sókè, kì yóò sì ṣàánú nígbà tí ó bá ń gbẹ̀san.
Bo zazdrość rozpala gniew mężczyzny i nie będzie pobłażał w dniu zemsty.
35 Kò nígbà nǹkan kan bí ohun ìtánràn; yóò kọ àbẹ̀tẹ́lẹ̀, bí ó ti wù kí ó pọ̀ tó.
Nie będzie miał względu na żaden okup i nie przyjmie darów, choćbyś najwięcej mu dawał.

< Proverbs 6 >