< Proverbs 6 >

1 Ọmọ mi, bí ìwọ bá ṣe onídùúró fún aládùúgbò rẹ, bí ìwọ bá jẹ́ ẹ̀jẹ́ fún àjèjì ènìyàn,
Fiam! ha kezes lettél a te barátodért, és kezedet adván, kötelezted magadat másért:
2 bí a bá ti fi ọ̀rọ̀ tí ó sọ dẹkùn mú ọ, tí ọ̀rọ̀ ẹnu rẹ ti kó ọ sí pàkúté.
Szádnak beszédei által estél tőrbe, megfogattattál a te szádnak beszédivel.
3 Nígbà náà, ṣe èyí, ìwọ ọmọ mi, láti gba ara rẹ níwọ̀n bí o ti kó ṣọ́wọ́ aládùúgbò rẹ: lọ kí o sì rẹ ara rẹ sílẹ̀; bẹ aládùúgbò rẹ dáradára.
Ezt míveld azért fiam, és mentsd ki magadat, mert a te felebarátodnak kezébe jutottál; eredj, alázd meg magadat, és kényszerítsd felebarátodat.
4 Má ṣe jẹ́ kí oorun kí ó kùn ọ́, tàbí kí o tilẹ̀ tòògbé rárá.
Még álmot se engedj szemeidnek, se szunnyadást szemöldökidnek,
5 Gba ara rẹ sílẹ̀, bí abo èsúró kúrò lọ́wọ́ ọdẹ, bí ẹyẹ kúrò nínú okùn àwọn pẹyẹpẹyẹ.
Szabadítsd ki magadat, mint a zerge a vadász kezéből, és mint a madár a madarásznak kezéből.
6 Tọ èèrà lọ, ìwọ ọ̀lẹ; kíyèsi ìṣe rẹ̀, kí o sì gbọ́n!
Eredj a hangyához, te rest, nézd meg az ő útait, és légy bölcs!
7 Kò ní olùdarí, kò sí alábojútó tàbí ọba,
A kinek nincs vezére, igazgatója, vagy ura,
8 síbẹ̀, a kó ìpèsè rẹ̀ jọ ní àsìkò òjò yóò sì kó oúnjẹ rẹ̀ jọ ní àsìkò ìkórè.
Nyárban szerzi meg az ő kenyerét, aratáskor gyűjti eledelét.
9 Yóò ti pẹ́ tó tí ìwọ yóò dùbúlẹ̀, ìwọ ọ̀lẹ? Nígbà wo ni ìwọ yóò jí kúrò lójú oorun rẹ?
Oh te rest, meddig fekszel? mikor kelsz fel a te álmodból?
10 Oorun díẹ̀, òògbé díẹ̀, ìkáwọ́gbera láti sinmi díẹ̀.
Még egy kis álom, még egy kis szunnyadás, még egy kis kéz-összefonás, hogy pihenjek;
11 Òsì yóò sì wá sórí rẹ bí ìgárá ọlọ́ṣà àti àìní bí adigunjalè.
Így jő el, mint az útonjáró, a te szegénységed, és a te szűkölködésed, mint a paizsos férfiú!
12 Ènìyànkénìyàn àti ènìyàn búburú, tí ń ru ẹnu àrékérekè káàkiri,
Haszontalan ember, hamis férfiú, a ki álnok szájjal jár,
13 tí ó ń ṣẹ́jú pàkòpàkò, ó ń fi ẹsẹ̀ rẹ̀ sọ̀rọ̀ ó sì ń fi ìka ọwọ́ rẹ̀ júwe,
A ki hunyorgat szemeivel; lábaival is szól, és ujjaival jelt ád.
14 tí ó ń pète búburú pẹ̀lú ẹ̀tàn nínú ọkàn rẹ̀ ìgbà gbogbo ni ó máa ń dá ìjà sílẹ̀.
Álnokság van az ő szívében, gonoszt forral minden időben, háborúságot indít.
15 Nítorí náà ìdààmú yóò dé bá a ní ìṣẹ́jú akàn; yóò parun lójijì láìsí àtúnṣe.
Annakokáért hirtelen eljő az ő nyomorúsága, gyorsan megrontatik, s nem lesz gyógyulása.
16 Àwọn ohun mẹ́fà wà tí Olúwa kórìíra, ohun méje ní ó jẹ́ ìríra sí i,
E hat dolgot gyűlöli az Úr, és hét dolog útálat az ő lelkének:
17 Ojú ìgbéraga, ahọ́n tó ń parọ́ ọwọ́ tí ń ta ẹ̀jẹ̀ aláìṣẹ̀ sílẹ̀,
A kevély szemek, a hazug nyelv, és az ártatlan vért ontó kezek,
18 ọkàn tí ń pète ohun búburú, ẹsẹ̀ tí ó yára láti sáré sínú ìwà ìkà,
Az álnok gondolatokat forraló elme, a gonoszra sietséggel futó lábak,
19 ajẹ́rìí èké tí ń tú irọ́ jáde lẹ́nu àti ènìyàn tí ń dá ìjà sílẹ̀ láàrín àwọn ọmọ ìyá kan.
A hazugságlehelő hamis tanú, és a ki szerez háborúságokat az atyafiak között!
20 Ọmọ mi, pa àṣẹ baba rẹ mọ́ má sì ṣe kọ ẹ̀kọ́ ìyá rẹ sílẹ̀.
Őrizd meg, fiam, atyád parancsolatját, és anyád tanítását el ne hagyd.
21 Jẹ́ kí wọn wà nínú ọkàn rẹ láéláé so wọ́n mọ́ ọrùn rẹ.
Kösd azokat szívedre mindenkor, fűzd a nyakadba.
22 Nígbà tí ìwọ bá ń rìn, wọn yóò ṣe amọ̀nà rẹ; nígbà tí ìwọ bá sùn, wọn yóò máa ṣe olùṣọ́ rẹ; nígbà tí o bá jí, wọn yóò bá ọ sọ̀rọ̀.
Valahová mégysz, vezérel téged, mikor aluszol, őriz téged, mikor felserkensz, beszélget te veled.
23 Nítorí àwọn àṣẹ yìí jẹ́ fìtílà, ẹ̀kọ́ yìí jẹ́ ìmọ́lẹ̀, àti ìtọ́nisọ́nà ti ìbáwí ni ọ̀nà sí ìyè.
Mert szövétnek a parancsolat, és a tudomány világosság, és életnek úta a tanító-feddések.
24 Yóò pa ọ́ mọ́ kúrò lọ́wọ́ obìnrin búburú, kúrò lọ́wọ́ ẹnu dídùn obìnrin àjèjì.
Hogy a gonosz asszonytól téged megőrizzenek, az idegen asszony nyelvének hizelkedésétől.
25 Má ṣe ṣe ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́ si nínú ọkàn rẹ nítorí ẹwà rẹ tàbí kí o jẹ́ kí ó fi ojú rẹ̀ fà ọ́ mọ́ra.
Ne kivánd az ő szépségét szivedben, és meg ne fogjon téged szemöldökeivel;
26 Nítorí pé nípasẹ̀ àgbèrè obìnrin ni ènìyàn fi ń di oníṣù-àkàrà kan, ṣùgbọ́n àyà ènìyàn a máa wá ìyè rẹ̀ dáradára.
Mert a parázna asszony miatt jut az ember egy darab kenyérre, és más férfi felesége drága életet vadász!
27 Ǹjẹ́ ọkùnrin ha le è gbé iná lé orí itan kí aṣọ rẹ̀ má sì jóná?
Vehet-é valaki tüzet az ő kebelébe, hogy ruhái meg ne égnének?
28 Ǹjẹ́ ènìyàn le è máa rìn lórí iná? Kí ẹsẹ̀ rẹ̀ sì má jóná?
Vagy járhat-é valaki elevenszénen, hogy lábai meg ne égnének?
29 Bẹ́ẹ̀ ni ẹni tí ń lọ sùn pẹ̀lú aya aláya; kò sí ẹni tí ó fọwọ́ kàn án tí yóò lọ láìjìyà.
Így van, valaki bemegy felebarátjának feleségéhez, nem marad büntetlen, valaki illeti azt!
30 Àwọn ènìyàn kì í kẹ́gàn olè tí ó bá jalè nítorí àti jẹun nígbà tí ebi bá ń pa á.
Nem útálják meg a lopót, ha lop az ő kivánságának betöltésére, mikor éhezik;
31 Síbẹ̀ bí ọwọ́ bá tẹ̀ ẹ́, ó gbọdọ̀ san ìlọ́po méje bí ó tilẹ̀ kó gbogbo ohun tó ní nílé tà.
És ha rajta kapatik, hétannyit kell adnia, az ő házának minden marháját érette adhatja;
32 Ṣùgbọ́n ẹni tí ń ṣe àgbèrè kò nírònú; ẹnikẹ́ni tí ó bá ń ṣe bẹ́ẹ̀ ó ń pa ara rẹ̀ run ni.
A ki pedig asszonynyal paráználkodik, bolond; a ki magát el akarja veszteni, az cselekszi ezt!
33 Ìfarapa àti ìtìjú ni tirẹ̀, ẹ̀gàn rẹ̀ kì yóò sì kúrò láéláé.
Vereséget és gyalázatot nyer, és az ő gyalázatja el nem töröltetik.
34 Nítorí owú yóò ru ìbínú ọkọ sókè, kì yóò sì ṣàánú nígbà tí ó bá ń gbẹ̀san.
Mert a féltékenység a férfiú haragja, és nem cselekszik kegyelmességgel a bosszúállásnak napján.
35 Kò nígbà nǹkan kan bí ohun ìtánràn; yóò kọ àbẹ̀tẹ́lẹ̀, bí ó ti wù kí ó pọ̀ tó.
Nem gondol semmi váltsággal, nem nyugszik meg rajta, még ha nagy sok ajándékot adsz is néki.

< Proverbs 6 >