< Proverbs 5 >

1 Ọmọ mi, fiyèsí ọgbọ́n mi, kí o sì dẹtí rẹ sí òye mi,
Synu mój, zważaj na moją mądrość i nakłoń twego ucha ku mojemu rozumowi;
2 kí ìwọ sì lè ní ìṣọ́ra kí ètè rẹ sì le pa ìmọ̀ mọ́.
Abyś zachował rozwagę i [aby] twoje wargi strzegły wiedzy.
3 Nítorí ètè àwọn àjèjì obìnrin a máa sun bi oyin, ọ̀rọ̀ rẹ̀ sì kúnná ju òróró lọ.
Bo wargi obcej kobiety ociekają miodem, a jej usta gładsze są niż oliwa;
4 Ṣùgbọ́n ní ìgbẹ̀yìn gbẹ́yín, ó korò ju òróǹró lọ, ó mú bí idà olójú méjì.
Lecz jej koniec jest gorzki jak piołun, ostry jak miecz obosieczny.
5 Ẹsẹ̀ rẹ̀ sọ̀kalẹ̀ lọ sí ọ̀nà ikú ìgbésẹ̀ rẹ̀ lọ tààrà sí ibojì òkú. (Sheol h7585)
Jej nogi zstępują do śmierci, jej kroki prowadzą do piekła. (Sheol h7585)
6 Kí ìwọ má ba à já ipa ọ̀nà ìyè; ọ̀nà rẹ̀ rí pálapàla, ṣùgbọ́n kò tilẹ̀ mọ́.
Abyś nie rozważał ścieżki życia, jej drogi są [tak] niestałe, [że] nie poznasz [ich].
7 Nítorí náà, ẹ̀yin ọmọ mi, ẹ dẹtí sí mi, kí ẹ̀yin kí ó má ṣe yàgò kúrò nínú ọ̀rọ̀ tí mo sọ.
Teraz więc, synowie, słuchajcie mnie i nie odstępujcie od słów moich ust.
8 Rìn ní ọ̀nà tí ó jìnnà sí ti rẹ̀, má ṣe súnmọ́ ẹnu-ọ̀nà ilé rẹ̀,
Oddal od niej swą drogę i nie zbliżaj się do drzwi jej domu;
9 àìṣe bẹ́ẹ̀ ìwọ yóò gbé gbogbo ọlá rẹ lé ẹlòmíràn lọ́wọ́ àti ọjọ́ ayé rẹ fún ìkà ènìyàn.
Abyś nie oddał obcym twojej sławy, a twoich lat okrutnikowi;
10 Kí a má ba à fi ọrọ̀ rẹ fún àjèjì ènìyàn, kí làálàá rẹ sì sọ ilé ẹlòmíràn di ọlọ́rọ̀.
Aby obcy nie nasycili się twoim dobytkiem, a twój dorobek [nie został] w cudzym domu;
11 Ní ìgbẹ̀yìn ayé rẹ ìwọ yóò kérora, nígbà tí agbára rẹ àti ara rẹ bá ti joro tán.
I abyś nie jęczał u kresu swych dni, gdy twoja skóra i ciało będą zniszczone;
12 Ìwọ yóò wí pé, “Mo ti kórìíra ẹ̀kọ́ tó! Ọkàn mi ṣe wá kórìíra ìbáwí!
I nie musiał powiedzieć: O, jakże nienawidziłem karności i moje serce gardziło upomnieniem!
13 N kò gbọ́rọ̀ sí àwọn olùkọ́ mi lẹ́nu, tàbí kí n fetí sí àwọn tí ń kọ́ mi lẹ́kọ̀ọ́.
Nie słuchałem głosu moich wychowawców i nie nakłaniałem ucha ku tym, którzy mnie nauczali!
14 Mo ti bẹ̀rẹ̀ ìparun pátápátá ní àárín gbogbo àwùjọ ènìyàn.”
O mało co nie wpadłem we wszelkie nieszczęście wśród zebrania i zgromadzenia.
15 Mu omi láti inú kànga tìrẹ, omi tí ń sàn láti inú kànga rẹ.
Pij wodę z własnego zdroju i wody płynące z twojego źródła!
16 Ó ha yẹ kí omi ìsun rẹ kún àkúnya sí ojú ọ̀nà àti odò tí ń sàn lọ sí àárín ọjà?
Niech rozproszą się twoje źródła, a po ulicach strumienie wód.
17 Jẹ́ kí wọn jẹ́ tìrẹ nìkan, má ṣe ṣe àjọpín wọn pẹ̀lú àjèjì láéláé.
Niech należą tylko do ciebie, a nie do obcych wraz z tobą.
18 Jẹ́ kí orísun rẹ kí ó ní ìbùkún; kí ìwọ ó sì máa yọ nínú aya ìgbà èwe rẹ.
Niech twój zdrój będzie błogosławiony i ciesz się żoną twojej młodości.
19 Abo àgbọ̀nrín tó dára, ìgalà tí ó wu ni jọjọ, jẹ́ kí ọmú rẹ̀ kí ó máa fi ayọ̀ fún ọ nígbà gbogbo, kí o sì máa yọ̀ nínú ìfẹ́ rẹ̀ nígbàkígbà.
[Niech będzie jak] wdzięczna łania i rozkoszna sarna; niech jej piersi zawsze cię nasycają, nieustannie zachwycaj się jej miłością.
20 Ọmọ mi, èéṣe tí ìwọ ó fi máa yọ̀ nínú ìfẹ́ obìnrin panṣágà, tí ìwọ ó sì fi dì mọ́ ìyàwó ẹlòmíràn?
Dlaczego, synu mój, masz zachwycać się obcą kobietą i obejmować piersi cudzej?
21 Nítorí ọ̀nà ènìyàn kò fi ara sin rárá fún Olúwa Ó sì ń gbé gbogbo ọ̀nà rẹ̀ yẹ̀ wò.
Gdyż drogi człowieka są przed oczami PANA [i] waży [on] wszystkie jego ścieżki.
22 Ìwà búburú ènìyàn búburú ni yóò mú kó bọ́ sínú okùn; okùn ẹ̀ṣẹ̀ ara rẹ̀ yóò sì dìímú.
Niegodziwego schwytają jego własne nieprawości i uwikła się w powrozy swego grzechu.
23 Yóò kú ní àìgba ẹ̀kọ́ ìwà òmùgọ̀ ara rẹ̀ yóò sì mú kí ó máa ṣìnà kiri.
Umrze z braku karności i będzie błądził z powodu swojej wielkiej głupoty.

< Proverbs 5 >