< Proverbs 5 >

1 Ọmọ mi, fiyèsí ọgbọ́n mi, kí o sì dẹtí rẹ sí òye mi,
Synu mój! bądź pilen mądrości mojej, a ku mojej roztropności nakłoń ucha twego,
2 kí ìwọ sì lè ní ìṣọ́ra kí ètè rẹ sì le pa ìmọ̀ mọ́.
Abyś strzegł ostrożności, a umiejętność aby wargi twoje zachowała.
3 Nítorí ètè àwọn àjèjì obìnrin a máa sun bi oyin, ọ̀rọ̀ rẹ̀ sì kúnná ju òróró lọ.
Bo choć niewiasty obcej wargi miodem opływają, a gładsze niż oliwa usta jej:
4 Ṣùgbọ́n ní ìgbẹ̀yìn gbẹ́yín, ó korò ju òróǹró lọ, ó mú bí idà olójú méjì.
Ale ostatnie rzeczy jej gorzkie jak piołun, a ostre jako miecz na obie strony ostry.
5 Ẹsẹ̀ rẹ̀ sọ̀kalẹ̀ lọ sí ọ̀nà ikú ìgbésẹ̀ rẹ̀ lọ tààrà sí ibojì òkú. (Sheol h7585)
Nogi jej zstępują do śmierci, a do piekła chód jej prowadzi. (Sheol h7585)
6 Kí ìwọ má ba à já ipa ọ̀nà ìyè; ọ̀nà rẹ̀ rí pálapàla, ṣùgbọ́n kò tilẹ̀ mọ́.
Jeźlibyś zważyć chciał ścieszkę żywota jej, nie pewne są drogi jej, nie poznasz ich.
7 Nítorí náà, ẹ̀yin ọmọ mi, ẹ dẹtí sí mi, kí ẹ̀yin kí ó má ṣe yàgò kúrò nínú ọ̀rọ̀ tí mo sọ.
Przetoż teraz, synowie! słuchajcie mię, a nie odstępujcie od powieści ust moich.
8 Rìn ní ọ̀nà tí ó jìnnà sí ti rẹ̀, má ṣe súnmọ́ ẹnu-ọ̀nà ilé rẹ̀,
Oddal od niej drogę twoję, a nie przybliżaj się ku drzwiom domu jej.
9 àìṣe bẹ́ẹ̀ ìwọ yóò gbé gbogbo ọlá rẹ lé ẹlòmíràn lọ́wọ́ àti ọjọ́ ayé rẹ fún ìkà ènìyàn.
Byś snać nie podał obcym sławy twojej, a lat twoich okrutnikowi;
10 Kí a má ba à fi ọrọ̀ rẹ fún àjèjì ènìyàn, kí làálàá rẹ sì sọ ilé ẹlòmíràn di ọlọ́rọ̀.
By się snać nie nasycili obcy siłą twoją, a prace twoje nie zostały w domu cudzym;
11 Ní ìgbẹ̀yìn ayé rẹ ìwọ yóò kérora, nígbà tí agbára rẹ àti ara rẹ bá ti joro tán.
I narzekałbyś w ostateczne czasy twoje, gdybyś zniszczył czerstwość twoję i ciało twoje;
12 Ìwọ yóò wí pé, “Mo ti kórìíra ẹ̀kọ́ tó! Ọkàn mi ṣe wá kórìíra ìbáwí!
I rzekłbyś: O jakożem miał ćwiczenie w nienawiści, a strofowaniem gardziło serce moje!
13 N kò gbọ́rọ̀ sí àwọn olùkọ́ mi lẹ́nu, tàbí kí n fetí sí àwọn tí ń kọ́ mi lẹ́kọ̀ọ́.
Nie słuchałem głosu ćwiczących mię, a tym, którzy mię uczyli, nie nakłaniałem ucha mego!
14 Mo ti bẹ̀rẹ̀ ìparun pátápátá ní àárín gbogbo àwùjọ ènìyàn.”
Maluczkom nie przyszedł we wszystko nieszczęście, w pośród zebrania i zgromadzenia.
15 Mu omi láti inú kànga tìrẹ, omi tí ń sàn láti inú kànga rẹ.
Pij wodę ze zdroju twego, a wody płynące ze źródła twego!
16 Ó ha yẹ kí omi ìsun rẹ kún àkúnya sí ojú ọ̀nà àti odò tí ń sàn lọ sí àárín ọjà?
Niech się precz rozchodzą źródła twoje, a po ulicach strumienie wód.
17 Jẹ́ kí wọn jẹ́ tìrẹ nìkan, má ṣe ṣe àjọpín wọn pẹ̀lú àjèjì láéláé.
Miej je sam dla siebie, a nie obcy z tobą.
18 Jẹ́ kí orísun rẹ kí ó ní ìbùkún; kí ìwọ ó sì máa yọ nínú aya ìgbà èwe rẹ.
Niech nie będzie zdrój twój błogosławiony, a wesel się z żony młodości twojej.
19 Abo àgbọ̀nrín tó dára, ìgalà tí ó wu ni jọjọ, jẹ́ kí ọmú rẹ̀ kí ó máa fi ayọ̀ fún ọ nígbà gbogbo, kí o sì máa yọ̀ nínú ìfẹ́ rẹ̀ nígbàkígbà.
Niechżeć będzie jako łani wdzięczna, i sarna rozkodzna; niech cię nasycają piersi jej na każdy czas, w miłości jej kochaj się ustawicznie.
20 Ọmọ mi, èéṣe tí ìwọ ó fi máa yọ̀ nínú ìfẹ́ obìnrin panṣágà, tí ìwọ ó sì fi dì mọ́ ìyàwó ẹlòmíràn?
Bo przeczże się masz kochać w obcej, synu mój! i odpoczywać na łonie cudzej?
21 Nítorí ọ̀nà ènìyàn kò fi ara sin rárá fún Olúwa Ó sì ń gbé gbogbo ọ̀nà rẹ̀ yẹ̀ wò.
Gdyż przed oczyma Pańskiemi są drogi człowiecze, a on wszystkie ścieszki jego waży.
22 Ìwà búburú ènìyàn búburú ni yóò mú kó bọ́ sínú okùn; okùn ẹ̀ṣẹ̀ ara rẹ̀ yóò sì dìímú.
Nieprawości własne pojmają niezbożnika, a w powrozach grzechu swego uwikle się.
23 Yóò kú ní àìgba ẹ̀kọ́ ìwà òmùgọ̀ ara rẹ̀ yóò sì mú kí ó máa ṣìnà kiri.
Onci umrze, przeto, że nie przyjmował ćwiczenia, a dla wielkości głupstwa swego będzie błądził.

< Proverbs 5 >