< Proverbs 5 >
1 Ọmọ mi, fiyèsí ọgbọ́n mi, kí o sì dẹtí rẹ sí òye mi,
My son, pay attention to my wisdom, and incline your ear to my prudence,
2 kí ìwọ sì lè ní ìṣọ́ra kí ètè rẹ sì le pa ìmọ̀ mọ́.
so that you may guard your thinking, and so that your lips may preserve discipline. Do not pay attention to the deceit of a woman.
3 Nítorí ètè àwọn àjèjì obìnrin a máa sun bi oyin, ọ̀rọ̀ rẹ̀ sì kúnná ju òróró lọ.
For the lips of a loose woman are like a dripping honeycomb, and her voice is smoother than oil.
4 Ṣùgbọ́n ní ìgbẹ̀yìn gbẹ́yín, ó korò ju òróǹró lọ, ó mú bí idà olójú méjì.
But in the end, she is as bitter as wormwood, and as sharp as a two-edged sword.
5 Ẹsẹ̀ rẹ̀ sọ̀kalẹ̀ lọ sí ọ̀nà ikú ìgbésẹ̀ rẹ̀ lọ tààrà sí ibojì òkú. (Sheol )
Her feet descend into death, and her steps reach even to Hell. (Sheol )
6 Kí ìwọ má ba à já ipa ọ̀nà ìyè; ọ̀nà rẹ̀ rí pálapàla, ṣùgbọ́n kò tilẹ̀ mọ́.
They do not walk along the path of life; her steps are wandering and untraceable.
7 Nítorí náà, ẹ̀yin ọmọ mi, ẹ dẹtí sí mi, kí ẹ̀yin kí ó má ṣe yàgò kúrò nínú ọ̀rọ̀ tí mo sọ.
Therefore, my son, listen to me now, and do not withdraw from the words of my mouth.
8 Rìn ní ọ̀nà tí ó jìnnà sí ti rẹ̀, má ṣe súnmọ́ ẹnu-ọ̀nà ilé rẹ̀,
Make your way at a distance from her, and do not approach the doors of her house.
9 àìṣe bẹ́ẹ̀ ìwọ yóò gbé gbogbo ọlá rẹ lé ẹlòmíràn lọ́wọ́ àti ọjọ́ ayé rẹ fún ìkà ènìyàn.
Do not give your honor to foreigners, and your years to the cruel.
10 Kí a má ba à fi ọrọ̀ rẹ fún àjèjì ènìyàn, kí làálàá rẹ sì sọ ilé ẹlòmíràn di ọlọ́rọ̀.
Otherwise, outsiders may be filled with your strength, and your labors may be in a foreign house,
11 Ní ìgbẹ̀yìn ayé rẹ ìwọ yóò kérora, nígbà tí agbára rẹ àti ara rẹ bá ti joro tán.
and you may mourn in the end, when you will have consumed your flesh and your body. And so you may say:
12 Ìwọ yóò wí pé, “Mo ti kórìíra ẹ̀kọ́ tó! Ọkàn mi ṣe wá kórìíra ìbáwí!
“Why have I detested discipline, and why has my heart not been quieted by correction?
13 N kò gbọ́rọ̀ sí àwọn olùkọ́ mi lẹ́nu, tàbí kí n fetí sí àwọn tí ń kọ́ mi lẹ́kọ̀ọ́.
And why have I not listened to the voice of those who guided me? And why has my ear not inclined to my teachers?
14 Mo ti bẹ̀rẹ̀ ìparun pátápátá ní àárín gbogbo àwùjọ ènìyàn.”
I have almost been with all evil in the midst of the church and of the assembly.”
15 Mu omi láti inú kànga tìrẹ, omi tí ń sàn láti inú kànga rẹ.
Drink water from your own cistern and from the springs of your own well.
16 Ó ha yẹ kí omi ìsun rẹ kún àkúnya sí ojú ọ̀nà àti odò tí ń sàn lọ sí àárín ọjà?
Let your fountains be diverted far and wide, and divide your waters in the streets.
17 Jẹ́ kí wọn jẹ́ tìrẹ nìkan, má ṣe ṣe àjọpín wọn pẹ̀lú àjèjì láéláé.
Hold them for yourself alone, and do not let strangers be partakers with you.
18 Jẹ́ kí orísun rẹ kí ó ní ìbùkún; kí ìwọ ó sì máa yọ nínú aya ìgbà èwe rẹ.
Let your spring be blessed, and rejoice with the wife of your youth:
19 Abo àgbọ̀nrín tó dára, ìgalà tí ó wu ni jọjọ, jẹ́ kí ọmú rẹ̀ kí ó máa fi ayọ̀ fún ọ nígbà gbogbo, kí o sì máa yọ̀ nínú ìfẹ́ rẹ̀ nígbàkígbà.
a beloved doe and most pleasing fawn. Let her breasts inebriate you at all times. Be delighted continually by her love.
20 Ọmọ mi, èéṣe tí ìwọ ó fi máa yọ̀ nínú ìfẹ́ obìnrin panṣágà, tí ìwọ ó sì fi dì mọ́ ìyàwó ẹlòmíràn?
Why are you seduced, my son, by a strange woman, and why are you kept warm by the bosom of another?
21 Nítorí ọ̀nà ènìyàn kò fi ara sin rárá fún Olúwa Ó sì ń gbé gbogbo ọ̀nà rẹ̀ yẹ̀ wò.
The Lord beholds the ways of man, and he considers all his steps.
22 Ìwà búburú ènìyàn búburú ni yóò mú kó bọ́ sínú okùn; okùn ẹ̀ṣẹ̀ ara rẹ̀ yóò sì dìímú.
His own iniquities take hold of the impious, and he is bound by the cords of his own sins.
23 Yóò kú ní àìgba ẹ̀kọ́ ìwà òmùgọ̀ ara rẹ̀ yóò sì mú kí ó máa ṣìnà kiri.
He shall die, for he has not held to discipline. And by the multitude of his foolishness, he shall be deceived.