< Proverbs 4 >

1 Tẹ́tí, ẹ̀yin ọmọ mi, sí ẹ̀kọ́ baba; fetísílẹ̀ kí o sì ní òye sí i.
Escuchad, hijos, la instrucción de un padre. Presta atención y conoce la comprensión;
2 Mo fún ọ ní ẹ̀kọ́ tí ó yè kooro, nítorí náà, má ṣe kọ ẹ̀kọ́ mi sílẹ̀.
porque te doy un aprendizaje sólido. No abandones mi ley.
3 Nígbà tí mo jẹ́ ọ̀dọ́mọkùnrin ní ilé baba à mí, mo jẹ́ èwe, tí mo sì jẹ́ ọ̀kan ṣoṣo lọ́wọ́ ìyá mi.
Porque yo era hijo de mi padre, tierna y única a los ojos de mi madre.
4 Ó kọ́ mi ó sì wí pé, “Jẹ́ kí àyà rẹ kí ó gba ọ̀rọ̀ mi dúró, pa òfin mi mọ́, kí ìwọ kí ó sì yè.
Me enseñó y me dijo: “Que tu corazón retenga mis palabras. Guarda mis mandamientos y vive.
5 Gba ọgbọ́n, gba òye, má ṣe gbàgbé ọ̀rọ̀ mi tàbí kí o yẹsẹ̀ kúrò nínú rẹ̀.
Obtenga sabiduría. Compréndelo. No lo olvides, y no te desvíes de las palabras de mi boca.
6 Má ṣe kọ ọgbọ́n sílẹ̀, yóò sì dáàbò bò ọ́, fẹ́ràn rẹ̀, yóò sì bojútó ọ.
No la abandones, y ella te preservará. Ámala, y ella te mantendrá.
7 Ọgbọ́n ni ó ga jù; nítorí náà gba ọgbọ́n. Bí ó tilẹ̀ ná gbogbo ohun tí o ní, gba òye.
La sabiduría es suprema. Consigue sabiduría. Sí, aunque te cueste todas tus posesiones, sé comprensivo.
8 Gbé e ga, yóò sì gbé ọ ga dìrọ̀ mọ́ ọn, yóò sì bu iyì fún ọ.
Estimadla, y ella os exaltará. Ella te llevará al honor cuando la abraces.
9 Yóò fi òdòdó ọ̀ṣọ́ ẹwà sí orí rẹ yóò sì fi adé ẹlẹ́wà fún ọ.”
Ella dará a tu cabeza una guirnalda de gracia. Te entregará una corona de esplendor”.
10 Tẹ́tí, ọmọ mi, gba ohun tí mo sọ, ọjọ́ ayé è rẹ yóò sì gùn.
Escucha, hijo mío, y recibe mis palabras. Los años de tu vida serán muchos.
11 Mo tọ́ ọ ṣọ́nà ní ọ̀nà ti ọgbọ́n mo sì mú ọ lọ ní ọ̀nà ti tààrà.
Te he enseñado el camino de la sabiduría. Te he guiado por caminos rectos.
12 Nígbà tí o rìn, ìgbésẹ̀ rẹ kò ní ní ìdíwọ́ nígbà tí o bá sáré, ìwọ kì yóò kọsẹ̀.
Cuando vayas, tus pasos no se verán obstaculizados. Cuando corras, no tropezarás.
13 Di ẹ̀kọ́ mú, má ṣe jẹ́ kí ó lọ; tọ́jú u rẹ̀ dáradára nítorí òun ni ìyè rẹ.
Agarra firmemente la instrucción. No la dejes ir. Quédate con ella, porque es tu vida.
14 Má ṣe gbé ẹsẹ̀ rẹ sí ojú ọnà àwọn ènìyàn búburú tàbí kí o rìn ní ọ̀nà àwọn ẹni ibi.
No entres en el camino de los malvados. No sigas el camino de los hombres malos.
15 Yẹra fún un, má ṣe rìn níbẹ̀; yàgò fún un kí o sì bá ọ̀nà tìrẹ lọ.
Evítalo y no pases de largo. Apártate de él y pasa de largo.
16 Nítorí wọn kò le sùn àyàfi tí wọ́n bá ṣe ibi, wọn kò ní tòògbé àyàfi tí wọ́n bá gbé ẹlòmíràn ṣubú.
Porque no duermen si no hacen el mal. Se les quita el sueño, a menos que hagan caer a alguien.
17 Wọ́n ń jẹ oúnjẹ ìwà búburú wọ́n sì ń mu wáìnì ìwà ìkà.
Porque comen el pan de la maldad y beber el vino de la violencia.
18 Ipa ọ̀nà olódodo dàbí àṣẹ̀ṣẹ̀yọ oòrùn tí ń tànmọ́lẹ̀ sí i títí ọjọ́ fi kanrí
Pero el camino de los justos es como la luz del amanecer que brilla más y más hasta el día perfecto.
19 ṣùgbọ́n ọ̀nà ènìyàn búburú dàbí òkùnkùn biribiri; wọn kò mọ ohun tí ó ń mú wọn kọsẹ̀.
El camino de los malvados es como la oscuridad. No saben con qué tropiezan.
20 Ọmọ mi, tẹ́tí sí ohun tí mo sọ; fetísílẹ̀ dáradára sí ọ̀rọ̀ mi.
Hijo mío, atiende a mis palabras. Poned el oído en mis palabras.
21 Má ṣe jẹ́ kí wọ́n rá mọ́ ọ lójú pa wọ́n mọ́ sínú ọkàn rẹ,
Que no se aparten de tus ojos. Manténgalos en el centro de su corazón.
22 nítorí ìyè ni wọ́n jẹ́ fún gbogbo ẹni tí ó rí wọn àti ìlera fún gbogbo ara ènìyàn.
Porque son la vida para los que las encuentran, y salud a todo su cuerpo.
23 Ju gbogbo nǹkan tókù lọ, pa ọkàn rẹ mọ́, nítorí òun ni orísun ìyè.
Guarda tu corazón con toda diligencia, porque de ella brota el manantial de la vida.
24 Mú àrékérekè kúrò ní ẹnu rẹ; sì jẹ́ kí ọ̀rọ̀ ìsọkúsọ jìnnà réré sí ẹnu rẹ.
Aparta de ti la boca perversa. Poner los labios corruptos lejos de ti.
25 Jẹ́ kí ojú rẹ máa wo iwájú, jẹ́ kí ìwo ojú rẹ máa wo ọ̀kánkán iwájú rẹ sá á.
Deja que tus ojos miren al frente. Fija tu mirada directamente delante de ti.
26 Kíyèsi ìrìn ẹsẹ̀ rẹ sì rìn ní àwọn ọ̀nà tí ó dára nìkan.
Haz que el camino de tus pies sea llano. Que se establezcan todos sus caminos.
27 Má ṣe yà sọ́tùn ún tàbí sósì; pa ẹsẹ̀ rẹ mọ́ kúrò nínú ibi.
No te vuelvas a la derecha ni a la izquierda. Retira tu pie del mal.

< Proverbs 4 >