< Proverbs 4 >

1 Tẹ́tí, ẹ̀yin ọmọ mi, sí ẹ̀kọ́ baba; fetísílẹ̀ kí o sì ní òye sí i.
Hear, you sons, the instruction of a father, And give attention to know understanding.
2 Mo fún ọ ní ẹ̀kọ́ tí ó yè kooro, nítorí náà, má ṣe kọ ẹ̀kọ́ mi sílẹ̀.
For I have given to you good learning, do not forsake my law.
3 Nígbà tí mo jẹ́ ọ̀dọ́mọkùnrin ní ilé baba à mí, mo jẹ́ èwe, tí mo sì jẹ́ ọ̀kan ṣoṣo lọ́wọ́ ìyá mi.
For I have been a son to my father—tender, And an only one before my mother.
4 Ó kọ́ mi ó sì wí pé, “Jẹ́ kí àyà rẹ kí ó gba ọ̀rọ̀ mi dúró, pa òfin mi mọ́, kí ìwọ kí ó sì yè.
And he directs me, and he says to me: “Let your heart retain my words, Keep my commands, and live.
5 Gba ọgbọ́n, gba òye, má ṣe gbàgbé ọ̀rọ̀ mi tàbí kí o yẹsẹ̀ kúrò nínú rẹ̀.
Get wisdom, get understanding, Do not forget, nor turn away From the sayings of my mouth.
6 Má ṣe kọ ọgbọ́n sílẹ̀, yóò sì dáàbò bò ọ́, fẹ́ràn rẹ̀, yóò sì bojútó ọ.
Do not forsake her, and she preserves you, Love her, and she keeps you.
7 Ọgbọ́n ni ó ga jù; nítorí náà gba ọgbọ́n. Bí ó tilẹ̀ ná gbogbo ohun tí o ní, gba òye.
The first thing [is] wisdom—get wisdom, And with all your getting get understanding.
8 Gbé e ga, yóò sì gbé ọ ga dìrọ̀ mọ́ ọn, yóò sì bu iyì fún ọ.
Exalt her and she lifts you up, She honors you when you embrace her.
9 Yóò fi òdòdó ọ̀ṣọ́ ẹwà sí orí rẹ yóò sì fi adé ẹlẹ́wà fún ọ.”
She gives a wreath of grace to your head, She gives you a crown of beauty freely.”
10 Tẹ́tí, ọmọ mi, gba ohun tí mo sọ, ọjọ́ ayé è rẹ yóò sì gùn.
Hear, my son, and receive my sayings, And years of life [are] multiplied to you.
11 Mo tọ́ ọ ṣọ́nà ní ọ̀nà ti ọgbọ́n mo sì mú ọ lọ ní ọ̀nà ti tààrà.
I have directed you in a way of wisdom, I have caused you to tread in paths of uprightness.
12 Nígbà tí o rìn, ìgbésẹ̀ rẹ kò ní ní ìdíwọ́ nígbà tí o bá sáré, ìwọ kì yóò kọsẹ̀.
In your walking your step is not restricted, And if you run, you do not stumble.
13 Di ẹ̀kọ́ mú, má ṣe jẹ́ kí ó lọ; tọ́jú u rẹ̀ dáradára nítorí òun ni ìyè rẹ.
Lay hold on instruction, do not desist, Keep her, for she [is] your life.
14 Má ṣe gbé ẹsẹ̀ rẹ sí ojú ọnà àwọn ènìyàn búburú tàbí kí o rìn ní ọ̀nà àwọn ẹni ibi.
Do not enter into the path of the wicked, And do not be blessed in a way of evildoers.
15 Yẹra fún un, má ṣe rìn níbẹ̀; yàgò fún un kí o sì bá ọ̀nà tìrẹ lọ.
Avoid it, do not pass over into it, Turn aside from it, and pass on.
16 Nítorí wọn kò le sùn àyàfi tí wọ́n bá ṣe ibi, wọn kò ní tòògbé àyàfi tí wọ́n bá gbé ẹlòmíràn ṣubú.
For they do not sleep if they do no evil, And their sleep has been taken away violently, If they do not cause [some] to stumble.
17 Wọ́n ń jẹ oúnjẹ ìwà búburú wọ́n sì ń mu wáìnì ìwà ìkà.
For they have eaten bread of wickedness, And they drink wine of violence.
18 Ipa ọ̀nà olódodo dàbí àṣẹ̀ṣẹ̀yọ oòrùn tí ń tànmọ́lẹ̀ sí i títí ọjọ́ fi kanrí
And the path of the righteous [is] as a shining light, Going and brightening until the day is established,
19 ṣùgbọ́n ọ̀nà ènìyàn búburú dàbí òkùnkùn biribiri; wọn kò mọ ohun tí ó ń mú wọn kọsẹ̀.
The way of the wicked [is] as darkness, They have not known at what they stumble.
20 Ọmọ mi, tẹ́tí sí ohun tí mo sọ; fetísílẹ̀ dáradára sí ọ̀rọ̀ mi.
My son, give attention to my words, Incline your ear to my sayings,
21 Má ṣe jẹ́ kí wọ́n rá mọ́ ọ lójú pa wọ́n mọ́ sínú ọkàn rẹ,
Do not let them turn aside from your eyes, Preserve them in the midst of your heart.
22 nítorí ìyè ni wọ́n jẹ́ fún gbogbo ẹni tí ó rí wọn àti ìlera fún gbogbo ara ènìyàn.
For they [are] life to those finding them, And healing to all their flesh.
23 Ju gbogbo nǹkan tókù lọ, pa ọkàn rẹ mọ́, nítorí òun ni orísun ìyè.
Above every charge keep your heart, For out of it [are] the outgoings of life.
24 Mú àrékérekè kúrò ní ẹnu rẹ; sì jẹ́ kí ọ̀rọ̀ ìsọkúsọ jìnnà réré sí ẹnu rẹ.
Turn aside a contrary mouth from you, And put perverse lips far from you,
25 Jẹ́ kí ojú rẹ máa wo iwájú, jẹ́ kí ìwo ojú rẹ máa wo ọ̀kánkán iwájú rẹ sá á.
Your eyes look straightforward, And your eyelids look straight before you.
26 Kíyèsi ìrìn ẹsẹ̀ rẹ sì rìn ní àwọn ọ̀nà tí ó dára nìkan.
Ponder the path of your feet, And all your ways [are] established.
27 Má ṣe yà sọ́tùn ún tàbí sósì; pa ẹsẹ̀ rẹ mọ́ kúrò nínú ibi.
Do not incline [to] the right or to the left, Turn aside your foot from evil!

< Proverbs 4 >