< Proverbs 31 >

1 Àwọn ọ̀rọ̀-ìjìnlẹ̀ ti Lemueli ọba, ọ̀rọ̀ ẹ̀kọ́ tí ìyá rẹ̀ kọ́ ọ,
Les paroles du roi Lémuel - la révélation que sa mère lui a enseignée:
2 “Gbọ́ ìwọ ọmọ mi, gbọ́ ìwọ ọmọ inú mi! Gbọ́ ìwọ ọmọ ẹ̀jẹ́ mi.
« Oh, mon fils! Oh, fils de mes entrailles! Oh, fils de mes vœux!
3 Má ṣe lo agbára rẹ lórí obìnrin, okun rẹ lórí àwọn tí ó pa àwọn ọba run.
Ne donne pas ta force aux femmes, ni vos voies à celles qui détruisent les rois.
4 “Kì í ṣe fún àwọn ọba, ìwọ Lemueli, kì í ṣe fún ọba láti mu ọtí wáìnì, kì í ṣe fún alákòóso láti máa wá ọtí líle,
Ce n'est pas pour les rois, Lemuel, ce n'est pas aux rois de boire du vin, ni pour les princes de dire: « Où est la boisson forte?
5 kí wọn má ba à mu ọtí yó kí wọn sì gbàgbé ohun tí òfin wí, kí wọn sì fi ẹ̀tọ́ àwọn tí ara ń ni dù wọ́n.
de peur qu'ils ne boivent et n'oublient la loi, et pervertissent la justice due à celui qui est affligé.
6 Fi ọtí líle fún àwọn tí ń ṣègbé wáìnì fún àwọn tí ó wà nínú ìrora.
Donnez une boisson forte à celui qui est prêt à périr, et du vin pour les âmes amères.
7 Jẹ́ kí wọn mu ọtí kí wọn sì gbàgbé òsì wọn kí wọn má sì rántí òsì wọn mọ́.
Qu'il boive, et qu'il oublie sa pauvreté, et ne plus se souvenir de sa misère.
8 “Sọ̀rọ̀ lórúkọ àwọn tí kò le sọ̀rọ̀ fúnra wọn fún ẹ̀tọ́ àwọn ẹni tí ń parun.
Ouvrez votre bouche pour le muet, pour la cause de tous ceux qui sont abandonnés.
9 Sọ̀rọ̀ kí o sì ṣe ìdájọ́ àìṣègbè jà fún ẹ̀tọ́ àwọn tálákà àti aláìní.”
Ouvre ta bouche, juge avec justice, et rendre justice aux pauvres et aux nécessiteux. »
10 Ta ni ó le rí aya oníwà rere? Ó níye lórí ju iyùn lọ.
Qui peut trouver une femme digne de ce nom? Car sa valeur est bien supérieure à celle des rubis.
11 Ọkọ rẹ̀ ní ìgbẹ́kẹ̀lé púpọ̀ nínú rẹ̀ kò sì ṣí ìwà rere tí kò pé lọ́wọ́ rẹ̀.
Le cœur de son mari a confiance en elle. Il ne manquera pas de gain.
12 Ire ní ó ń ṣe fún un, kì í ṣe ibi ní gbogbo ọjọ́ ayé rẹ̀.
Elle lui fait du bien, et non du mal, tous les jours de sa vie.
13 Ó sa aṣọ irun àgùntàn olówùú àti ọ̀gbọ̀ Ó sì ṣiṣẹ́ pẹ̀lú ìyárí.
Elle cherche la laine et le lin, et travaille avec ardeur avec ses mains.
14 Ó dàbí ọkọ̀ ojú omi tí àwọn oníṣòwò; ó ń gbé oúnjẹ rẹ̀ wá láti ọ̀nà jíjìn.
Elle est comme les navires marchands. Elle apporte son pain de loin.
15 Ó dìde nígbà tí òkùnkùn sì kùn; ó ṣe oúnjẹ fún ìdílé rẹ̀ àti ìpín oúnjẹ fún àwọn ìránṣẹ́bìnrin rẹ̀.
Elle se lève aussi alors qu'il fait encore nuit, donne de la nourriture à son foyer, et des portions pour ses servantes.
16 Ó kíyèsi oko kan, ó sì rà á; nínú ohun tí ó ń wọlé fún un ó gbin ọgbà àjàrà rẹ̀.
Elle considère un champ, et l'achète. Avec le fruit de ses mains, elle plante une vigne.
17 Ó bẹ̀rẹ̀ iṣẹ́ rẹ̀ tagbára tagbára apá rẹ̀ le koko fún iṣẹ́.
Elle arme sa taille avec force, et rend ses bras forts.
18 Ó rí i pé òwò òun pé fìtílà rẹ̀ kì í sì í kú ní òru.
Elle perçoit que sa marchandise est rentable. Sa lampe ne s'éteint pas la nuit.
19 Ní ọwọ́ rẹ̀, ó di kẹ̀kẹ́ òwú mú ó sì na ọwọ́ rẹ̀ di ìrànwú mú.
Elle pose ses mains sur la quenouille, et ses mains tiennent le fuseau.
20 O la ọwọ́ rẹ̀ sí àwọn tálákà ó sì na ọwọ́ rẹ̀ sí àwọn aláìní.
Elle ouvre ses bras aux pauvres; oui, elle tend les mains aux nécessiteux.
21 Nígbà tí òjò-dídì rọ̀, kò bẹ̀rù nítorí ìdílé rẹ̀ nítorí gbogbo wọn ni ó wọ aṣọ tí ó nípọn.
Elle n'a pas peur de la neige pour sa maison, car toute sa famille est vêtue d'écarlate.
22 Ó ṣe aṣọ títẹ́ fún ibùsùn rẹ̀; ẹ̀wù dáradára àti elése àlùkò ni aṣọ rẹ̀.
Elle se fait des tapis de tapisserie. Ses vêtements sont en lin fin et de couleur violette.
23 A bọ̀wọ̀ fún ọkọ rẹ̀ ní ẹnu ibodè ìlú níbi tí ó ń jókòó láàrín àwọn àgbàgbà ìlú.
Son mari est respecté dans les portes, quand il s'assiéra parmi les anciens du pays.
24 Ó ń ṣe àwọn aṣọ dáradára ó sì ń tà wọ́n ó sì ń kó ọjà fún àwọn oníṣòwò.
Elle fait des vêtements de lin et les vend, et livre les coussins au marchand.
25 Agbára àti ọlá ni ó wò ọ́ láṣọ ó le fi ọjọ́ iwájú rẹ́rìn-ín.
La force et la dignité sont ses vêtements. Elle se moque du temps à venir.
26 A sọ̀rọ̀ pẹ̀lú ọgbọ́n ìkọ́ni òtítọ́ sì ń bẹ létè e rẹ̀
Elle ouvre sa bouche avec sagesse. L'instruction aimable est sur sa langue.
27 Ó ń bojútó gbogbo ètò ilé rẹ̀ kì í sì í jẹ oúnjẹ ìmẹ́lẹ́.
Elle s'occupe bien des affaires de sa famille, et ne mange pas le pain de l'oisiveté.
28 Àwọn ọmọ rẹ̀ dìde wọ́n sì pè é ní alábùkún ọkọ rẹ̀ pẹ̀lú ń gbóríyìn fún un.
Ses enfants se lèvent et la qualifient de bienheureuse. Son mari fait également son éloge:
29 “Ọ̀pọ̀lọpọ̀ obìnrin ní ń ṣe nǹkan ọlọ́lá ṣùgbọ́n ìwọ ju gbogbo wọn lọ.”
« Beaucoup de femmes font des choses nobles, mais vous les surpassez tous. »
30 Ojú dáradára a máa tan ni, ẹwà sì jẹ́ asán nítorí obìnrin tí ó bẹ̀rù Olúwa yẹ kí ó gba oríyìn.
Le charme est trompeur, et la beauté est vaine; mais une femme qui craint Yahvé, on la louera.
31 Sì fún un ní èrè tí ó tọ́ sí i kí o sì jẹ́ kí iṣẹ́ rẹ̀ fún un ní ìyìn ní ẹnu ibodè ìlú.
Donnez-lui du fruit de ses mains! Que ses œuvres la louent dans les portes!

< Proverbs 31 >