< Proverbs 31 >

1 Àwọn ọ̀rọ̀-ìjìnlẹ̀ ti Lemueli ọba, ọ̀rọ̀ ẹ̀kọ́ tí ìyá rẹ̀ kọ́ ọ,
The words of king Lemuel, the prophecy with which his mother instructed him.
2 “Gbọ́ ìwọ ọmọ mi, gbọ́ ìwọ ọmọ inú mi! Gbọ́ ìwọ ọmọ ẹ̀jẹ́ mi.
What [hast thou done], O my son: and what, O son of my body? and what, O son of my vows?
3 Má ṣe lo agbára rẹ lórí obìnrin, okun rẹ lórí àwọn tí ó pa àwọn ọba run.
Give not unto women thy vigor, nor thy ways to those that ruin kings.
4 “Kì í ṣe fún àwọn ọba, ìwọ Lemueli, kì í ṣe fún ọba láti mu ọtí wáìnì, kì í ṣe fún alákòóso láti máa wá ọtí líle,
Not for kings, O Lemoel, not for kings [it is fitting] to drink wine, nor for princes, strong drink:
5 kí wọn má ba à mu ọtí yó kí wọn sì gbàgbé ohun tí òfin wí, kí wọn sì fi ẹ̀tọ́ àwọn tí ara ń ni dù wọ́n.
Lest either might drink, and forget what is written in the law, and pervert the cause of all the afflicted.
6 Fi ọtí líle fún àwọn tí ń ṣègbé wáìnì fún àwọn tí ó wà nínú ìrora.
Give strong drink unto him that is ready to perish, and wine unto those who have an embittered soul.
7 Jẹ́ kí wọn mu ọtí kí wọn sì gbàgbé òsì wọn kí wọn má sì rántí òsì wọn mọ́.
Let such a one drink, and forget his poverty, and remember his trouble no more.
8 “Sọ̀rọ̀ lórúkọ àwọn tí kò le sọ̀rọ̀ fúnra wọn fún ẹ̀tọ́ àwọn ẹni tí ń parun.
Open thy mouth for the dumb, for the cause of all fatherless children.
9 Sọ̀rọ̀ kí o sì ṣe ìdájọ́ àìṣègbè jà fún ẹ̀tọ́ àwọn tálákà àti aláìní.”
Open thy mouth, judge righteously, and decide the cause of the poor and needy.
10 Ta ni ó le rí aya oníwà rere? Ó níye lórí ju iyùn lọ.
Who can find a virtuous woman: for far above pearls is her value.
11 Ọkọ rẹ̀ ní ìgbẹ́kẹ̀lé púpọ̀ nínú rẹ̀ kò sì ṣí ìwà rere tí kò pé lọ́wọ́ rẹ̀.
The heart of her husband doth safely trust in her, and he will not see his gain diminish.
12 Ire ní ó ń ṣe fún un, kì í ṣe ibi ní gbogbo ọjọ́ ayé rẹ̀.
She treateth him well and not ill, all the days of her life.
13 Ó sa aṣọ irun àgùntàn olówùú àti ọ̀gbọ̀ Ó sì ṣiṣẹ́ pẹ̀lú ìyárí.
She seeketh for wool and flax, and worketh with her willing hands.
14 Ó dàbí ọkọ̀ ojú omi tí àwọn oníṣòwò; ó ń gbé oúnjẹ rẹ̀ wá láti ọ̀nà jíjìn.
She is become like the merchant's ships: from afar doth she bring her food.
15 Ó dìde nígbà tí òkùnkùn sì kùn; ó ṣe oúnjẹ fún ìdílé rẹ̀ àti ìpín oúnjẹ fún àwọn ìránṣẹ́bìnrin rẹ̀.
And she riseth while it is yet night, and giveth provision to her household, and a task to her maidens.
16 Ó kíyèsi oko kan, ó sì rà á; nínú ohun tí ó ń wọlé fún un ó gbin ọgbà àjàrà rẹ̀.
She thinketh of a field, and buyeth it: with the fruit of her hands she planteth a vineyard.
17 Ó bẹ̀rẹ̀ iṣẹ́ rẹ̀ tagbára tagbára apá rẹ̀ le koko fún iṣẹ́.
She girdeth with strength her loins, and giveth vigor to her arms.
18 Ó rí i pé òwò òun pé fìtílà rẹ̀ kì í sì í kú ní òru.
She perceiveth that her profit is good: [therefore] her lamp goeth not out by night.
19 Ní ọwọ́ rẹ̀, ó di kẹ̀kẹ́ òwú mú ó sì na ọwọ́ rẹ̀ di ìrànwú mú.
She stretcheth out her hands to the spindle, and her palms hold fast the distaff.
20 O la ọwọ́ rẹ̀ sí àwọn tálákà ó sì na ọwọ́ rẹ̀ sí àwọn aláìní.
She spreadeth out wide her open palm to the poor: yea, her hands she stretcheth forth to the needy.
21 Nígbà tí òjò-dídì rọ̀, kò bẹ̀rù nítorí ìdílé rẹ̀ nítorí gbogbo wọn ni ó wọ aṣọ tí ó nípọn.
She hath no fear for her household of the snow: for all her household are clothed in scarlet.
22 Ó ṣe aṣọ títẹ́ fún ibùsùn rẹ̀; ẹ̀wù dáradára àti elése àlùkò ni aṣọ rẹ̀.
Tapestry-covering she maketh for herself: of linen and purple is her attire.
23 A bọ̀wọ̀ fún ọkọ rẹ̀ ní ẹnu ibodè ìlú níbi tí ó ń jókòó láàrín àwọn àgbàgbà ìlú.
Well known is in the gates her husband, when he sitteth with the elders of the land.
24 Ó ń ṣe àwọn aṣọ dáradára ó sì ń tà wọ́n ó sì ń kó ọjà fún àwọn oníṣòwò.
Fine tunics she maketh, and selleth them, and girdles she furnisheth unto the merchant.
25 Agbára àti ọlá ni ó wò ọ́ láṣọ ó le fi ọjọ́ iwájú rẹ́rìn-ín.
Strength and dignity are her clothing: and she smileth at the coming of the last day.
26 A sọ̀rọ̀ pẹ̀lú ọgbọ́n ìkọ́ni òtítọ́ sì ń bẹ létè e rẹ̀
She openeth her mouth with wisdom, and the law of kindness is on her tongue.
27 Ó ń bojútó gbogbo ètò ilé rẹ̀ kì í sì í jẹ oúnjẹ ìmẹ́lẹ́.
She looketh well to the ways of her household, and the bread of idleness she doth not eat.
28 Àwọn ọmọ rẹ̀ dìde wọ́n sì pè é ní alábùkún ọkọ rẹ̀ pẹ̀lú ń gbóríyìn fún un.
Her children rise up, and call her blessed; her husband, also, and he praiseth her:
29 “Ọ̀pọ̀lọpọ̀ obìnrin ní ń ṣe nǹkan ọlọ́lá ṣùgbọ́n ìwọ ju gbogbo wọn lọ.”
“Many daughters have done virtuously; but thou excellest them all.”
30 Ojú dáradára a máa tan ni, ẹwà sì jẹ́ asán nítorí obìnrin tí ó bẹ̀rù Olúwa yẹ kí ó gba oríyìn.
False is grace, and vain is beauty: a woman only that feareth the Lord shall indeed be praised.
31 Sì fún un ní èrè tí ó tọ́ sí i kí o sì jẹ́ kí iṣẹ́ rẹ̀ fún un ní ìyìn ní ẹnu ibodè ìlú.
Give her of the fruit of her hands, and let her own works praise her in the gates.

< Proverbs 31 >