< Proverbs 30 >
1 Àwọn ọ̀rọ̀ Aguri ọmọ Jake, ọ̀rọ̀ ìsọtẹ́lẹ̀ tí ọkùnrin yìí sọ fún Itieli. Sí Itieli àti sí Ukali.
Paroles d'Agur, fils de Jaqué, prophétie, oracle donné par l'Homme à Ithiel, à Ithiel et à Uchal.
2 “Èmi ni aláìmòye ju nínú àwọn ènìyàn; n kò ní òye ènìyàn.
Oui, je suis plus stupide que personne, et je n'ai point l'intelligence d'un humain;
3 Èmi kò tilẹ̀ kọ́ ọgbọ́n tàbí ní ìmọ̀ ẹni mímọ́ nì.
et je n'ai ni appris la sagesse, ni connu la science des saints.
4 Ta ni ó ti gòkè lọ sí ọ̀run tí ó sì padà sọ̀kalẹ̀? Ta ni ó ti kó afẹ́fẹ́ jọ sí ihò àtẹ́lẹwọ́ rẹ̀? Ta ni ó ti ta kókó omi sétí aṣọ? Ta ni ó fi gbogbo ìpìlẹ̀ ayé lélẹ̀? Kí ni orúkọ rẹ̀, àti orúkọ ọmọ rẹ̀? Sọ fún mi bí o bá mọ̀.
Qui monta au ciel, et en redescendit? Qui enserra le vent dans ses mains? Qui enveloppa les eaux dans sa robe? Qui plaça toutes les bornes de la terre? Quel est son nom et le nom de son fils, si tu le sais?
5 “Gbogbo ọ̀rọ̀ Ọlọ́run jẹ́ aláìlábùkù; òun ni ààbò fún gbogbo ẹni fi í ṣe ibi ìpamọ́ wọn.
Toute parole de Dieu est pure. Il est un bouclier pour ceux qui se confient en Lui.
6 Má ṣe fi kún ọ̀rọ̀ rẹ̀, àìṣe bẹ́ẹ̀ yóò bá ọ wí yóò sì sọ ọ́ di òpùrọ́.
N'ajoute rien à ce qu'il a dit, de peur qu'il ne te châtie, et que tu ne sois convaincu de mensonge.
7 “Ohun méjì ni mo ń béèrè lọ́wọ́ rẹ, Olúwa; má ṣe fi wọ́n dù mí kí ń tó kú.
Je Te demande deux choses: ne me les refuse pas, avant que je meure!
8 Mú èké ṣíṣe àti irọ́ jìnnà sí mi; má ṣe fún mi ní òsì tàbí ọrọ̀, ṣùgbọ́n fún mi ní oúnjẹ òòjọ́ mi nìkan.
Eloigne de moi la fausseté et le langage menteur; ne me donne ni pauvreté, ni richesse, nourris-moi du pain qui est pour moi le nécessaire;
9 Àìṣe bẹ́ẹ̀, mo lè ní àníjù kí n sì gbàgbé rẹ kí ń sì wí pé, ‘Ta ni Olúwa?’ Tàbí kí ń di òtòṣì kí ń sì jalè kí ń sì ṣe àìbọ̀wọ̀ fún orúkọ Ọlọ́run mi.
de peur que rassasié je ne te renie, et ne dise: « Qui est l'Éternel? » ou qu'appauvri je ne dérobe, et ne m'attaque au nom de mon Dieu!
10 “Má ṣe ba ìránṣẹ́ lórúkọ jẹ́ lọ́dọ̀ ọ̀gá rẹ̀, kí ó má ba fi ọ́ bú, kí ìwọ má ba jẹ̀bi.
Ne calomnie pas le serviteur auprès de son maître, de peur qu'il ne te maudisse, et que tu ne sois puni!
11 “Àwọn kan wá ṣépè fún àwọn baba wọn tí wọn kò sì súre fún àwọn ìyá wọn.
Il est une race qui maudit son père, et ne bénit point sa mère.
12 Àwọn tí ó mọ́ ní ojú ara wọn síbẹ̀ tí wọn kò sì mọ́ kúrò nínú èérí wọn;
Il est une race qui est pure à ses propres yeux, tandis que de sa souillure elle n'est point lavée.
13 àwọn ẹni tí ojú wọn gbéga nígbà gbogbo, tí ìwolẹ̀ wọn sì kún fún ìgbéraga.
Il est une race… que ses yeux sont altiers, et ses paupières hautaines!
14 Àwọn ẹni tí eyín wọn jẹ́ idà àwọn tí èrìgì wọn kún fún ọ̀bẹ láti jẹ àwọn tálákà run kúrò ní ilẹ̀ ayé àwọn aláìní kúrò láàrín àwọn ọmọ ènìyàn.
Il est une race dont les dents sont des glaives, et les molaires des couteaux, pour dévorer le malheureux sur la terre, et les indigents, parmi les hommes.
15 “Eṣúṣú ni ọmọbìnrin méjì. ‘Mú wá! Mú wá!’ ní wọn ń ké. “Àwọn nǹkan mẹ́ta kan wà tí kò ní ìtẹ́lọ́rùn láéláé, mẹ́rin tí kò jẹ́ wí láéláé pé, ‘Ó tó!’:
L'Aluca a deux filles: Donne! Donne! Trois choses sont insatiables, il en est quatre qui jamais ne disent: « C'est assez! »
16 Ibojì, inú tí ó yàgàn, ilẹ̀ tí omi kì í tẹ́lọ́rùn láéláé, àti iná, tí kì í wí láéláé pé, ‘Ó tó!’ (Sheol )
les Enfers, et la femme stérile, la terre jamais rassasiée d'eau, et le feu qui jamais ne dit: « C'est assez! » (Sheol )
17 “Ojú tí ń fi baba ṣẹ̀fẹ̀, tí ó kẹ́gàn ìgbọ́ràn sí ìyá, ẹyẹ ìwò ẹ̀bá odò ni yóò yọ ọ́, igún yóò mú un jẹ.
L'œil qui se moque d'un père, et dédaigne l'obéissance envers une mère, les corbeaux de la vallée l'arracheront, et les petits de l'aigle le mangeront.
18 “Àwọn nǹkan mẹ́ta wà tí ó jẹ́ ìyàlẹ́nu fún mi, mẹ́rin tí kò yé mi,
Trois choses passent ma portée, il en est quatre que je ne pénètre pas:
19 ipa ẹyẹ idì ní òfúrufú ipa ejò lórí àpáta ipa ọkọ̀ ojú omi lójú agbami Òkun àti ipa ọ̀nà ọkùnrin tí ó mú wúńdíá lọ́wọ́.
la trace de l'aigle dans les Cieux, la trace du serpent sur le rocher, la trace du navire au sein de la mer, et la trace de l'homme qui va vers une vierge.
20 “Èyí ni ọ̀nà alágbèrè obìnrin ó jẹun ó sì nu ẹnu rẹ̀ ó sì wí pé, ‘N kò ṣe ohunkóhun tí kò tọ́.’
Telle est la manière de la femme adultère: elle mange, et s'essuie la bouche et dit: « Je n'ai point fait de mal. »
21 “Lábẹ́ nǹkan mẹ́ta ni ilé ayé ti ń wárìrì lábẹ́ ohun mẹ́rin ni kò ti lè mí fín ín.
Trois choses font trembler un pays, il en est quatre qu'il ne peut supporter:
22 Ìránṣẹ́ tí ó di ọba aláìgbọ́n tí ó ní ọ̀pọ̀lọpọ̀ oúnjẹ,
un esclave devenu roi, un insensé dans l'abondance,
23 obìnrin tí gbogbo ènìyàn kórìíra tí ó sì wá lọ́kọ ìránṣẹ́bìnrin tí ó gbọkọ mọ́ ọ̀gá rẹ̀ lọ́wọ́.
la femme dédaignée devenue épouse, et la servante qui a chassé sa maîtresse.
24 “Àwọn ohun mẹ́rin ló kéré láyé síbẹ̀ wọ́n gbọ́n gidigidi.
Il y a sur la terre quatre animaux très petits, et pourtant sages et bien avisés:
25 Àwọn èèrà jẹ́ aláìlágbára ẹ̀dá, síbẹ̀ wọ́n kó oúnjẹ wọn pamọ́ ní àsìkò òjò.
les fourmis, peuple qui n'est point fort, et pourtant en été elles font leurs provisions;
26 Ehoro jẹ́ aláìlágbára ẹ̀dá; síbẹ̀ wọ́n ń ṣe ihò wọn sí ibi pálapàla àpáta;
les gerboises, peuple qui n'est point vigoureux, et pourtant dans les rochers elles pratiquent leur gîte;
27 àwọn eṣú kò ní ọba, síbẹ̀ gbogbo wọ́n ń jáde lọ ní ọ̀wọ̀ọ̀wọ́
les sauterelles n'ont point de roi, et pourtant elles sortent toutes formées en bataillons;
28 Ọmọnílé fi ọwọ́ rẹ̀ dì mú, síbẹ̀ a ń rí i ní ààfin ọba.
le lézard saisit avec ses mains, et se trouve dans les palais des rois.
29 “Àwọn ohun mẹ́ta ní ń bẹ tí ń rìn rere, ohun mẹ́rin ni ó dára púpọ̀ ní ìrìn rírìn:
Trois ont une belle démarche, et quatre, une belle allure:
30 Kìnnìún, alágbára láàrín ẹranko tí kì í sá fún ohunkóhun
le lion, héros entre les animaux, et qui ne recule devant personne;
31 Ẹsin tí a dì lẹ́gbẹ̀ẹ́; àti òbúkọ, àti ọba láàrín àwọn ènìyàn rẹ̀.
[le coursier] ceint aux reins du harnais, ou le bélier et le roi à qui l'on ne peut tenir tête.
32 “Bí ìwọ bá ti hùwà aṣiwèrè nípa gbígbé ara rẹ ga, tàbí tí o bá ti gbèrò ibi, da ọwọ́ rẹ bo ẹnu rẹ!
Si tu as été fou par orgueil, et si tu as pensé à mal…. la main sur la bouche!
33 Nítorí bí fífún omi ọmú tí í mú wàrà wá, tí fífún imú sì ń mú ẹ̀jẹ̀ jáde, bẹ́ẹ̀ ni rírú ìbínú sókè í mú ìjà wá.”
Car la pression du lait produit du beurre, et la pression du nez produit du sang, et la pression de la colère produit la rixe.