< Proverbs 30 >

1 Àwọn ọ̀rọ̀ Aguri ọmọ Jake, ọ̀rọ̀ ìsọtẹ́lẹ̀ tí ọkùnrin yìí sọ fún Itieli. Sí Itieli àti sí Ukali.
Ô mon fils, révère mes paroles; recueille-les et repens-toi. Voici ce que dit un homme à ceux qui se confient en Dieu; mais je m'arrête,
2 “Èmi ni aláìmòye ju nínú àwọn ènìyàn; n kò ní òye ènìyàn.
car je suis moi-même le plus insensé des hommes, et la sagesse des mortels n'est point en moi
3 Èmi kò tilẹ̀ kọ́ ọgbọ́n tàbí ní ìmọ̀ ẹni mímọ́ nì.
mais Dieu m'a enseigné la sagesse, et je connais la doctrine des saints.
4 Ta ni ó ti gòkè lọ sí ọ̀run tí ó sì padà sọ̀kalẹ̀? Ta ni ó ti kó afẹ́fẹ́ jọ sí ihò àtẹ́lẹwọ́ rẹ̀? Ta ni ó ti ta kókó omi sétí aṣọ? Ta ni ó fi gbogbo ìpìlẹ̀ ayé lélẹ̀? Kí ni orúkọ rẹ̀, àti orúkọ ọmọ rẹ̀? Sọ fún mi bí o bá mọ̀.
Qui donc est monté au ciel et en est descendu? Qui a rassemblé les vents dans un pli de Son manteau? Qui a contenu les eaux comme dans un vêtement? Qui a pouvoir sur les extrémités de la terre? Quel est Son Nom? Quel est le nom de Ses enfants?
5 “Gbogbo ọ̀rọ̀ Ọlọ́run jẹ́ aláìlábùkù; òun ni ààbò fún gbogbo ẹni fi í ṣe ibi ìpamọ́ wọn.
Toutes les paroles de Dieu sont des flammes, et Il protège ceux qui Le craignent.
6 Má ṣe fi kún ọ̀rọ̀ rẹ̀, àìṣe bẹ́ẹ̀ yóò bá ọ wí yóò sì sọ ọ́ di òpùrọ́.
N'ajoute rien à Ses paroles, de peur qu'Il ne te reprenne et ne t'accuse de mensonge.
7 “Ohun méjì ni mo ń béèrè lọ́wọ́ rẹ, Olúwa; má ṣe fi wọ́n dù mí kí ń tó kú.
Seigneur, je Te demande deux choses: Ne me retire pas Ta grâce avant que je meure;
8 Mú èké ṣíṣe àti irọ́ jìnnà sí mi; má ṣe fún mi ní òsì tàbí ọrọ̀, ṣùgbọ́n fún mi ní oúnjẹ òòjọ́ mi nìkan.
éloigne de moi les paroles vaines et le mensonge; ne me donne ni la richesse ni la pauvreté; mais accorde-moi ce qui m'est nécessaire et suffisant;
9 Àìṣe bẹ́ẹ̀, mo lè ní àníjù kí n sì gbàgbé rẹ kí ń sì wí pé, ‘Ta ni Olúwa?’ Tàbí kí ń di òtòṣì kí ń sì jalè kí ń sì ṣe àìbọ̀wọ̀ fún orúkọ Ọlọ́run mi.
de peur que, rassasié, je ne devienne trompeur, et ne dise: Qui me voit? ou que, poussé par le besoin, je ne dérobe, et que je ne parjure le Nom du Seigneur.
10 “Má ṣe ba ìránṣẹ́ lórúkọ jẹ́ lọ́dọ̀ ọ̀gá rẹ̀, kí ó má ba fi ọ́ bú, kí ìwọ má ba jẹ̀bi.
Ne livre pas l'esclave fugitif à son maître; de peur qu'il ne te maudisse, et que tu ne périsses à ton tour.
11 “Àwọn kan wá ṣépè fún àwọn baba wọn tí wọn kò sì súre fún àwọn ìyá wọn.
Une race pervertie maudit son père, et ne bénit pas sa mère.
12 Àwọn tí ó mọ́ ní ojú ara wọn síbẹ̀ tí wọn kò sì mọ́ kúrò nínú èérí wọn;
Une race pervertie s'estime juste, et qui pourtant n'a point lavé le devant de sa porte.
13 àwọn ẹni tí ojú wọn gbéga nígbà gbogbo, tí ìwolẹ̀ wọn sì kún fún ìgbéraga.
Une race pervertie a les yeux hautains; l'orgueil est sur ses paupières.
14 Àwọn ẹni tí eyín wọn jẹ́ idà àwọn tí èrìgì wọn kún fún ọ̀bẹ láti jẹ àwọn tálákà run kúrò ní ilẹ̀ ayé àwọn aláìní kúrò láàrín àwọn ọmọ ènìyàn.
D'une race pervertie les dents sont des glaives; et ses mâchoires, des couteaux pour détruire et dévorer, sur la terre, les humbles et les pauvres parmi les hommes.
15 “Eṣúṣú ni ọmọbìnrin méjì. ‘Mú wá! Mú wá!’ ní wọn ń ké. “Àwọn nǹkan mẹ́ta kan wà tí kò ní ìtẹ́lọ́rùn láéláé, mẹ́rin tí kò jẹ́ wí láéláé pé, ‘Ó tó!’:
La sangsue avait trois filles qu'elle aimait d'un tendre amour; et à elles trois, elles ne remplissaient pas son cœur; une quatrième ne suffit pas pour lui faire dire: C'est assez.
16 Ibojì, inú tí ó yàgàn, ilẹ̀ tí omi kì í tẹ́lọ́rùn láéláé, àti iná, tí kì í wí láéláé pé, ‘Ó tó!’ (Sheol h7585)
L'enfer, l'amour d'une femme, une terre qui manque d'eau, l'eau et le feu ne diront jamais: C'est assez. (Sheol h7585)
17 “Ojú tí ń fi baba ṣẹ̀fẹ̀, tí ó kẹ́gàn ìgbọ́ràn sí ìyá, ẹyẹ ìwò ẹ̀bá odò ni yóò yọ ọ́, igún yóò mú un jẹ.
L'œil qui se moque d'un père et qui n'honore point la vieillesse d'une mère, que les corbeaux du vallon l'arrachent, et que les aiglons le dévorent.
18 “Àwọn nǹkan mẹ́ta wà tí ó jẹ́ ìyàlẹ́nu fún mi, mẹ́rin tí kò yé mi,
Il y a trois choses qu'il m'est impossible de comprendre, et une quatrième que j'ignore
19 ipa ẹyẹ idì ní òfúrufú ipa ejò lórí àpáta ipa ọkọ̀ ojú omi lójú agbami Òkun àti ipa ọ̀nà ọkùnrin tí ó mú wúńdíá lọ́wọ́.
la trace d'un aigle dans les airs, celle d'un serpent dans les rochers, les sentiers d'un ruisseau qui vogue sur l'eau, et les voies d'un homme dans sa jeunesse.
20 “Èyí ni ọ̀nà alágbèrè obìnrin ó jẹun ó sì nu ẹnu rẹ̀ ó sì wí pé, ‘N kò ṣe ohunkóhun tí kò tọ́.’
Telle est la voie de la femme adultère, qui, après ce qu'elle a fait, se lave, et dit n'avoir rien fait d'inconvenant.
21 “Lábẹ́ nǹkan mẹ́ta ni ilé ayé ti ń wárìrì lábẹ́ ohun mẹ́rin ni kò ti lè mí fín ín.
Trois choses troublent la terre; il en est une quatrième qu'elle ne peut supporter
22 Ìránṣẹ́ tí ó di ọba aláìgbọ́n tí ó ní ọ̀pọ̀lọpọ̀ oúnjẹ,
un esclave devenu roi; un insensé regorgeant de biens;
23 obìnrin tí gbogbo ènìyàn kórìíra tí ó sì wá lọ́kọ ìránṣẹ́bìnrin tí ó gbọkọ mọ́ ọ̀gá rẹ̀ lọ́wọ́.
une servante qui a supplanté sa maîtresse, et une méchante femme réunie à un bon mari.
24 “Àwọn ohun mẹ́rin ló kéré láyé síbẹ̀ wọ́n gbọ́n gidigidi.
Il y a sur la terre quatre êtres bien petits, et ils sont plus sages que les sages
25 Àwọn èèrà jẹ́ aláìlágbára ẹ̀dá, síbẹ̀ wọ́n kó oúnjẹ wọn pamọ́ ní àsìkò òjò.
la fourmi, qui n'a point de force, et prépare en été sa nourriture;
26 Ehoro jẹ́ aláìlágbára ẹ̀dá; síbẹ̀ wọ́n ń ṣe ihò wọn sí ibi pálapàla àpáta;
le hérisson, peuple débile, qui fait sa demeure sur les rochers;
27 àwọn eṣú kò ní ọba, síbẹ̀ gbogbo wọ́n ń jáde lọ ní ọ̀wọ̀ọ̀wọ́
la sauterelle, qui n'a point de roi et marche comme une armée en bon ordre, au commandement d'une seule;
28 Ọmọnílé fi ọwọ́ rẹ̀ dì mú, síbẹ̀ a ń rí i ní ààfin ọba.
et le lézard moucheté, qui se tient droit, et, quoique facile à prendre, habite les forteresses des rois.
29 “Àwọn ohun mẹ́ta ní ń bẹ tí ń rìn rere, ohun mẹ́rin ni ó dára púpọ̀ ní ìrìn rírìn:
Il y a trois êtres dont la démarche est belle, et un quatrième dont le maintien est majestueux
30 Kìnnìún, alágbára láàrín ẹranko tí kì í sá fún ohunkóhun
le lionceau, le plus fort des animaux, qui ne recule devant rien, et ne redoute aucune bête;
31 Ẹsin tí a dì lẹ́gbẹ̀ẹ́; àti òbúkọ, àti ọba láàrín àwọn ènìyàn rẹ̀.
le coq, qui se promène, plein d'ardeur, parmi les poules; et le bouc qui conduit le troupeau, et le roi qui gouverne une nation.
32 “Bí ìwọ bá ti hùwà aṣiwèrè nípa gbígbé ara rẹ ga, tàbí tí o bá ti gbèrò ibi, da ọwọ́ rẹ bo ẹnu rẹ!
Si tu t'es laissé aller à la joie, et que tu étendes les mains pour te disculper, tu seras confondu.
33 Nítorí bí fífún omi ọmú tí í mú wàrà wá, tí fífún imú sì ń mú ẹ̀jẹ̀ jáde, bẹ́ẹ̀ ni rírú ìbínú sókè í mú ìjà wá.”
Trais le lait avec trop de force, il deviendra du beurre; blesse-toi les narines, il en sortira du sang; cherche querelle, il s'ensuivra des rixes et des procès.

< Proverbs 30 >