< Proverbs 3 >
1 Ọmọ mi, má ṣe gbàgbé ẹ̀kọ́ mi. Ṣùgbọ́n pa òfin mi mọ́ sí ọkàn rẹ.
Сын мой! наставления моего не забывай, и заповеди мои да хранит сердце твое;
2 Nítorí ọjọ́ gígùn, ẹ̀mí gígùn, àti àlàáfíà, ni wọn yóò fi kùn un fún ọ.
ибо долготы дней, лет жизни и мира они приложат тебе.
3 Má ṣe jẹ́ kí ìfẹ́ àti òtítọ́ ṣíṣe fi ọ́ sílẹ̀ láéláé so wọ́n mọ́ ọrùn rẹ, kọ wọ́n sí wàláà àyà rẹ.
Милость и истина да не оставляют тебя: обвяжи ими шею твою, напиши их на скрижали сердца твоего,
4 Nígbà náà ni ìwọ yóò rí ojúrere àti orúkọ rere ní ojú Ọlọ́run àti lójú ènìyàn.
и обретешь милость и благоволение в очах Бога и людей.
5 Gbẹ́kẹ̀lé Olúwa pẹ̀lú gbogbo ọkàn rẹ má ṣe sinmi lé òye ara à rẹ.
Надейся на Господа всем сердцем твоим, и не полагайся на разум твой.
6 Mọ̀ ọ́n ní gbogbo ọ̀nà rẹ òun yóò sì máa tọ́ ipa ọ̀nà rẹ.
Во всех путях твоих познавай Его, и Он направит стези твои.
7 Má ṣe jẹ́ ọlọ́gbọ́n lójú ara à rẹ bẹ̀rù Olúwa kí o sì kórìíra ibi.
Не будь мудрецом в глазах твоих; бойся Господа и удаляйся от зла:
8 Èyí yóò mú ìlera fún ara rẹ àti okun fún àwọn egungun rẹ.
это будет здравием для тела твоего и питанием для костей твоих.
9 Fi ọrọ̀ rẹ bọ̀wọ̀ fún Olúwa, pẹ̀lú àkọ́so oko rẹ,
Чти Господа от имения твоего и от начатков всех прибытков твоих,
10 nígbà náà ni àká rẹ yóò kún àkúnya àgbá rẹ yóò kún àkúnwọ́sílẹ̀ fún wáìnì tuntun.
и наполнятся житницы твои до избытка, и точила твои будут переливаться новым вином.
11 Ọmọ mi, má ṣe kẹ́gàn ìbáwí Olúwa má sì ṣe bínú nígbà tí ó bá ń bá ọ wí,
Наказания Господня, сын мой, не отвергай, и не тяготись обличением Его;
12 nítorí Olúwa a máa bá àwọn tí ó fẹ́ràn wí bí baba ti í bá ọmọ tí ó bá nínú dídùn sí wí.
ибо кого любит Господь, того наказывает и благоволит к тому, как отец к сыну своему.
13 Ìbùkún ni fún ẹni tí ó ní ìmọ̀, ẹni tí ó tún ní òye sí i,
Блажен человек, который снискал мудрость, и человек, который приобрел разум,
14 nítorí ó ṣe èrè ju fàdákà lọ ó sì ní èrè lórí ju wúrà lọ.
потому что приобретение ее лучше приобретения серебра, и прибыли от нее больше, нежели от золота:
15 Ó ṣe iyebíye ju iyùn lọ; kò sí ohunkóhun tí a lè fiwé e nínú ohun gbogbo tí ìwọ fẹ́.
она дороже драгоценных камней; никакое зло не может противиться ей; она хорошо известна всем, приближающимся к ней, и ничто из желаемого тобою не сравнится с нею.
16 Ẹ̀mí gígùn ń bẹ ní ọwọ́ ọ̀tún rẹ̀; ní ọwọ́ òsì rẹ sì ni ọrọ̀ àti ọlá.
Долгоденствие - в правой руке ее, а в левой у нее - богатство и слава; из уст ее выходит правда; закон и милость она на языке носит;
17 Àwọn ọ̀nà rẹ jẹ́ ọ̀nà ìtura, òpópónà rẹ sì jẹ́ ti àlàáfíà.
пути ее - пути приятные, и все стези ее - мирные.
18 Igi ìyè ni ó jẹ́ fún gbogbo ẹni tí ó bá gbà á; àwọn tí ó bá sì dìímú yóò rí ìbùkún gbà.
Она - древо жизни для тех, которые приобретают ее, - и блаженны, которые сохраняют ее!
19 Nípa ọgbọ́n, Olúwa fi ìpìlẹ̀ ilẹ̀ ayé sọlẹ̀; nípa òye, ó fi àwọn ọ̀run sí ipò wọn;
Господь премудростью основал землю, небеса утвердил разумом;
20 nípa ìmọ̀ rẹ̀ ó pín ibú omi ní yà, àwọsánmọ̀ sì ń sẹ ìrì.
Его премудростью разверзлись бездны, и облака кропят росою.
21 Ọmọ mi, pa ọgbọ́n tí ó yè kooro àti ìmòye mọ́, má jẹ́ kí wọn lọ kúrò ní ibi tí ojú rẹ ti le tó wọn.
Сын мой! не упускай их из глаз твоих; храни здравомыслие и рассудительность,
22 Wọn yóò jẹ́ ìyè fún ọ, àti ẹ̀ṣọ́ fún ọrùn rẹ.
и они будут жизнью для души твоей и украшением для шеи твоей.
23 Nígbà náà ni ìwọ yóò bá ọ̀nà rẹ lọ ní àìléwu, ìwọ kì yóò sì kọsẹ̀.
Тогда безопасно пойдешь по пути твоему, и нога твоя не споткнется.
24 Nígbà tí ìwọ bá dùbúlẹ̀, ìwọ kì yóò bẹ̀rù, nígbà tí ìwọ bá dùbúlẹ̀, oorun rẹ yóò jẹ́ oorun ayọ̀.
Когда ляжешь спать, - не будешь бояться; и когда уснешь, - сон твой приятен будет.
25 Má ṣe bẹ̀rù ìdààmú òjijì, tàbí ti ìparun tí ó ń dé bá àwọn ènìyàn búburú.
Не убоишься внезапного страха и пагубы от нечестивых, когда она придет;
26 Nítorí Olúwa yóò jẹ́ ìgbẹ́kẹ̀lé rẹ, kì yóò sì jẹ́ kí ẹsẹ̀ rẹ bọ́ sínú pàkúté.
потому что Господь будет упованием твоим и сохранит ногу твою от уловления.
27 Má ṣe fa ọwọ́ ìre sẹ́yìn kúrò lọ́dọ̀ àwọn tí ṣe tìrẹ, nígbà tí ó bá wà ní ìkápá rẹ láti ṣe ohun kan.
Не отказывай в благодеянии нуждающемуся, когда рука твоя в силе сделать его.
28 Má ṣe wí fún aládùúgbò rẹ pé, “Padà wá nígbà tó ṣe díẹ̀; èmi yóò fi fún ọ ní ọ̀la,” nígbà tí o ní i pẹ̀lú rẹ nísinsin yìí.
Не говори другу твоему: “Пойди и приди опять, и завтра я дам”, когда ты имеешь при себе. Ибо ты не знаешь, что родит грядущий день.
29 Má ṣe pète ohun búburú fún aládùúgbò rẹ, ti o gbé nítòsí rẹ, tí ó sì fọkàn tán ọ.
Не замышляй против ближнего твоего зла, когда он без опасения живет с тобою.
30 Má ṣe fẹ̀sùn kan ènìyàn láìnídìí, nígbà tí kò ṣe ọ́ ní ibi kankan rárá.
Не ссорься с человеком без причины, когда он не сделал зла тебе.
31 Má ṣe ṣe ìlara ènìyàn jàgídíjàgan tàbí kí o yàn láti rìn ní ọ̀nà rẹ̀.
Не соревнуй человеку, поступающему насильственно, и не избирай ни одного из путей его;
32 Nítorí Olúwa kórìíra ènìyàn aláyídáyidà ṣùgbọ́n a máa fọkàn tán ẹni dídúró ṣinṣin.
потому что мерзость пред Господом развратный, а с праведными у Него общение.
33 Ègún Olúwa ń bẹ lórí ilé ènìyàn búburú, ṣùgbọ́n ó bùkún fún ilé olódodo.
Проклятие Господне на доме нечестивого, а жилище благочестивых Он благословляет.
34 Ó fi àwọn ẹlẹ́yà ṣe yẹ̀yẹ́, ṣùgbọ́n ó fi oore-ọ̀fẹ́ fún onírẹ̀lẹ̀.
Если над кощунниками Он посмеивается, то смиренным дает благодать.
35 Ọlọ́gbọ́n jogún iyì, ṣùgbọ́n àwọn aṣiwèrè ni yóò ru ìtìjú wọn.
Мудрые наследуют славу, а глупые - бесславие.