< Proverbs 3 >

1 Ọmọ mi, má ṣe gbàgbé ẹ̀kọ́ mi. Ṣùgbọ́n pa òfin mi mọ́ sí ọkàn rẹ.
Fiul meu, nu uita legea mea, ci inima ta să păzească poruncile mele;
2 Nítorí ọjọ́ gígùn, ẹ̀mí gígùn, àti àlàáfíà, ni wọn yóò fi kùn un fún ọ.
Fiindcă ele vor adăuga zilelor tale lungime și ani de viață și pace.
3 Má ṣe jẹ́ kí ìfẹ́ àti òtítọ́ ṣíṣe fi ọ́ sílẹ̀ láéláé so wọ́n mọ́ ọrùn rẹ, kọ wọ́n sí wàláà àyà rẹ.
Să nu te părăsească mila și adevărul; leagă-le în jurul gâtului tău; scrie-le pe tăblia inimii tale;
4 Nígbà náà ni ìwọ yóò rí ojúrere àti orúkọ rere ní ojú Ọlọ́run àti lójú ènìyàn.
Astfel vei găsi favoare și bună înțelegere în ochii lui Dumnezeu și a oamenilor.
5 Gbẹ́kẹ̀lé Olúwa pẹ̀lú gbogbo ọkàn rẹ má ṣe sinmi lé òye ara à rẹ.
Încrede-te în DOMNUL cu toată inima ta și nu te sprijini pe propria ta înțelegere.
6 Mọ̀ ọ́n ní gbogbo ọ̀nà rẹ òun yóò sì máa tọ́ ipa ọ̀nà rẹ.
Recunoaște-l în toate căile tale și el îți va îndrepta cărările.
7 Má ṣe jẹ́ ọlọ́gbọ́n lójú ara à rẹ bẹ̀rù Olúwa kí o sì kórìíra ibi.
Nu fi înțelept în ochii tăi; teme-te de DOMNUL și depărtează-te de rău.
8 Èyí yóò mú ìlera fún ara rẹ àti okun fún àwọn egungun rẹ.
Va fi sănătate buricului tău și măduvă oaselor tale.
9 Fi ọrọ̀ rẹ bọ̀wọ̀ fún Olúwa, pẹ̀lú àkọ́so oko rẹ,
Onorează pe DOMNUL cu averea ta și cu primele roade din tot venitul tău;
10 nígbà náà ni àká rẹ yóò kún àkúnya àgbá rẹ yóò kún àkúnwọ́sílẹ̀ fún wáìnì tuntun.
Astfel vor fi umplute hambarele tale cu abundență și teascurile tale vor da pe dinafară cu vin nou.
11 Ọmọ mi, má ṣe kẹ́gàn ìbáwí Olúwa má sì ṣe bínú nígbà tí ó bá ń bá ọ wí,
Fiul meu, nu disprețui disciplinarea DOMNULUI, nici nu obosi la îndreptarea lui,
12 nítorí Olúwa a máa bá àwọn tí ó fẹ́ràn wí bí baba ti í bá ọmọ tí ó bá nínú dídùn sí wí.
Fiindcă DOMNUL îndreaptă pe cine iubește, precum un tată pe fiul în care își găsește plăcere.
13 Ìbùkún ni fún ẹni tí ó ní ìmọ̀, ẹni tí ó tún ní òye sí i,
Fericit este omul care găsește înțelepciune și omul care obține înțelegere.
14 nítorí ó ṣe èrè ju fàdákà lọ ó sì ní èrè lórí ju wúrà lọ.
Căci comerțul cu ea este mai bun decât comerțul cu argint, iar câștigul ei decât aurul fin.
15 Ó ṣe iyebíye ju iyùn lọ; kò sí ohunkóhun tí a lè fiwé e nínú ohun gbogbo tí ìwọ fẹ́.
Ea este mai prețioasă decât rubinele și toate lucrurile pe care le dorești nu sunt de comparat cu ea.
16 Ẹ̀mí gígùn ń bẹ ní ọwọ́ ọ̀tún rẹ̀; ní ọwọ́ òsì rẹ sì ni ọrọ̀ àti ọlá.
În mâna ei dreaptă se află lungimea zilelor și în stânga ei sunt bogățiile și onoarea.
17 Àwọn ọ̀nà rẹ jẹ́ ọ̀nà ìtura, òpópónà rẹ sì jẹ́ ti àlàáfíà.
Căile ei sunt căi plăcute și toate cărările ei sunt pace.
18 Igi ìyè ni ó jẹ́ fún gbogbo ẹni tí ó bá gbà á; àwọn tí ó bá sì dìímú yóò rí ìbùkún gbà.
Ea este un pom al vieții pentru cei ce o țin strâns și fericit este cel care o păstrează.
19 Nípa ọgbọ́n, Olúwa fi ìpìlẹ̀ ilẹ̀ ayé sọlẹ̀; nípa òye, ó fi àwọn ọ̀run sí ipò wọn;
DOMNUL prin înțelepciune a fondat pământul, prin înțelegere a întemeiat cerurile.
20 nípa ìmọ̀ rẹ̀ ó pín ibú omi ní yà, àwọsánmọ̀ sì ń sẹ ìrì.
Prin cunoașterea lui sunt despicate adâncurile și norii picură roua.
21 Ọmọ mi, pa ọgbọ́n tí ó yè kooro àti ìmòye mọ́, má jẹ́ kí wọn lọ kúrò ní ibi tí ojú rẹ ti le tó wọn.
Fiul meu, să nu se depărteze ele de ochii tăi! Păzește înțelepciunea sănătoasă și discernerea;
22 Wọn yóò jẹ́ ìyè fún ọ, àti ẹ̀ṣọ́ fún ọrùn rẹ.
Astfel ele vor fi viață sufletului tău și grație gâtului tău.
23 Nígbà náà ni ìwọ yóò bá ọ̀nà rẹ lọ ní àìléwu, ìwọ kì yóò sì kọsẹ̀.
Atunci vei umbla în siguranță pe calea ta și piciorul tău nu se va poticni.
24 Nígbà tí ìwọ bá dùbúlẹ̀, ìwọ kì yóò bẹ̀rù, nígbà tí ìwọ bá dùbúlẹ̀, oorun rẹ yóò jẹ́ oorun ayọ̀.
Când te culci, nu te vei teme; da, te vei culca și somnul tău va fi dulce.
25 Má ṣe bẹ̀rù ìdààmú òjijì, tàbí ti ìparun tí ó ń dé bá àwọn ènìyàn búburú.
Nu te teme de spaima năprasnică, nici de pustiirea celor stricați când vine.
26 Nítorí Olúwa yóò jẹ́ ìgbẹ́kẹ̀lé rẹ, kì yóò sì jẹ́ kí ẹsẹ̀ rẹ bọ́ sínú pàkúté.
Fiindcă DOMNUL va fi încrederea ta și îți va păstra piciorul să nu fie prins.
27 Má ṣe fa ọwọ́ ìre sẹ́yìn kúrò lọ́dọ̀ àwọn tí ṣe tìrẹ, nígbà tí ó bá wà ní ìkápá rẹ láti ṣe ohun kan.
Nu opri binele de la cei cărora li se cuvine, când stă în puterea mâinii tale să o faci.
28 Má ṣe wí fún aládùúgbò rẹ pé, “Padà wá nígbà tó ṣe díẹ̀; èmi yóò fi fún ọ ní ọ̀la,” nígbà tí o ní i pẹ̀lú rẹ nísinsin yìí.
Nu spune vecinului tău: Du-te și revino, și mâine îți voi da; când ai lângă tine ce îi trebuie.
29 Má ṣe pète ohun búburú fún aládùúgbò rẹ, ti o gbé nítòsí rẹ, tí ó sì fọkàn tán ọ.
Nu plănui răul împotriva vecinului tău, văzând că el trăiește în siguranță lângă tine.
30 Má ṣe fẹ̀sùn kan ènìyàn láìnídìí, nígbà tí kò ṣe ọ́ ní ibi kankan rárá.
Nu te certa fără motiv cu un om, dacă nu ți-a făcut niciun rău.
31 Má ṣe ṣe ìlara ènìyàn jàgídíjàgan tàbí kí o yàn láti rìn ní ọ̀nà rẹ̀.
Nu invidia pe opresor și nu alege niciuna din căile lui.
32 Nítorí Olúwa kórìíra ènìyàn aláyídáyidà ṣùgbọ́n a máa fọkàn tán ẹni dídúró ṣinṣin.
Fiindcă cel pervers este urâciune pentru DOMNUL, dar taina lui este cu cei drepți.
33 Ègún Olúwa ń bẹ lórí ilé ènìyàn búburú, ṣùgbọ́n ó bùkún fún ilé olódodo.
Blestemul DOMNULUI este în casa celui stricat, dar el binecuvântează locuința celor drepți.
34 Ó fi àwọn ẹlẹ́yà ṣe yẹ̀yẹ́, ṣùgbọ́n ó fi oore-ọ̀fẹ́ fún onírẹ̀lẹ̀.
Într-adevăr, el batjocorește pe batjocoritori, dar dă har celor umili.
35 Ọlọ́gbọ́n jogún iyì, ṣùgbọ́n àwọn aṣiwèrè ni yóò ru ìtìjú wọn.
Cei înțelepți vor moșteni glorie, dar rușinea va fi înălțarea proștilor.

< Proverbs 3 >