< Proverbs 3 >

1 Ọmọ mi, má ṣe gbàgbé ẹ̀kọ́ mi. Ṣùgbọ́n pa òfin mi mọ́ sí ọkàn rẹ.
Filho meu, não te esqueças de minha lei; e que teu coração guarde meus mandamentos.
2 Nítorí ọjọ́ gígùn, ẹ̀mí gígùn, àti àlàáfíà, ni wọn yóò fi kùn un fún ọ.
Porque te acrescentarão extensão de dias, e anos de vida e paz.
3 Má ṣe jẹ́ kí ìfẹ́ àti òtítọ́ ṣíṣe fi ọ́ sílẹ̀ láéláé so wọ́n mọ́ ọrùn rẹ, kọ wọ́n sí wàláà àyà rẹ.
Que a bondade e a fidelidade não te desamparem; amarra-as junto ao teu pescoço; escreve-as na tábua de teu coração.
4 Nígbà náà ni ìwọ yóò rí ojúrere àti orúkọ rere ní ojú Ọlọ́run àti lójú ènìyàn.
Então tu acharás graça e bom entendimento, aos olhos de Deus e dos homens.
5 Gbẹ́kẹ̀lé Olúwa pẹ̀lú gbogbo ọkàn rẹ má ṣe sinmi lé òye ara à rẹ.
Confia no SENHOR com todo o teu coração; e não te apoies em teu [próprio] entendimento.
6 Mọ̀ ọ́n ní gbogbo ọ̀nà rẹ òun yóò sì máa tọ́ ipa ọ̀nà rẹ.
Dá reconhecimento a ele em todas os teus caminhos; e ele endireitará tuas veredas.
7 Má ṣe jẹ́ ọlọ́gbọ́n lójú ara à rẹ bẹ̀rù Olúwa kí o sì kórìíra ibi.
Não sejas sábio aos teus [próprios] olhos; teme ao SENHOR, e afasta-te do mal.
8 Èyí yóò mú ìlera fún ara rẹ àti okun fún àwọn egungun rẹ.
Isto será remédio para teu corpo, e alívio para teus ossos.
9 Fi ọrọ̀ rẹ bọ̀wọ̀ fún Olúwa, pẹ̀lú àkọ́so oko rẹ,
Honra ao SENHOR com teus bens, e com a primeira parte de toda a tua renda.
10 nígbà náà ni àká rẹ yóò kún àkúnya àgbá rẹ yóò kún àkúnwọ́sílẹ̀ fún wáìnì tuntun.
E teus celeiros se encherão de fartura, e tuas prensas de uvas transbordarão de vinho novo.
11 Ọmọ mi, má ṣe kẹ́gàn ìbáwí Olúwa má sì ṣe bínú nígbà tí ó bá ń bá ọ wí,
Filho meu, não rejeites a correção do SENHOR, nem te desagrades de sua repreensão;
12 nítorí Olúwa a máa bá àwọn tí ó fẹ́ràn wí bí baba ti í bá ọmọ tí ó bá nínú dídùn sí wí.
Porque o SENHOR repreende a quem ele ama, assim como o pai ao filho, [a quem] ele quer bem.
13 Ìbùkún ni fún ẹni tí ó ní ìmọ̀, ẹni tí ó tún ní òye sí i,
Bem-aventurado o homem que encontra sabedoria, e o homem que ganha conhecimento.
14 nítorí ó ṣe èrè ju fàdákà lọ ó sì ní èrè lórí ju wúrà lọ.
Porque seu produto é melhor que o produto da prata; e seu valor, mais do que o do ouro fino.
15 Ó ṣe iyebíye ju iyùn lọ; kò sí ohunkóhun tí a lè fiwé e nínú ohun gbogbo tí ìwọ fẹ́.
Ela é mais preciosa do que rubis; e tudo o que podes desejar não se pode comparar a ela.
16 Ẹ̀mí gígùn ń bẹ ní ọwọ́ ọ̀tún rẹ̀; ní ọwọ́ òsì rẹ sì ni ọrọ̀ àti ọlá.
Extensão de dias [há] em sua mão direita; em sua esquerda riquezas e honra.
17 Àwọn ọ̀nà rẹ jẹ́ ọ̀nà ìtura, òpópónà rẹ sì jẹ́ ti àlàáfíà.
Seus caminhos são caminhos agradáveis; e todas as suas veredas são paz.
18 Igi ìyè ni ó jẹ́ fún gbogbo ẹni tí ó bá gbà á; àwọn tí ó bá sì dìímú yóò rí ìbùkún gbà.
Ela é uma árvore de vida para os que dela pegam; e bem-aventurados são todos os que a retêm.
19 Nípa ọgbọ́n, Olúwa fi ìpìlẹ̀ ilẹ̀ ayé sọlẹ̀; nípa òye, ó fi àwọn ọ̀run sí ipò wọn;
O SENHOR com sabedoria fundou a terra; ele preparou os céus com a inteligência.
20 nípa ìmọ̀ rẹ̀ ó pín ibú omi ní yà, àwọsánmọ̀ sì ń sẹ ìrì.
Com seu conhecimento se fenderam os abismos, e as nuvens gotejam orvalho.
21 Ọmọ mi, pa ọgbọ́n tí ó yè kooro àti ìmòye mọ́, má jẹ́ kí wọn lọ kúrò ní ibi tí ojú rẹ ti le tó wọn.
Filho meu, que [estes] não se afastem de teus olhos; guarda a sabedoria e o bom-senso.
22 Wọn yóò jẹ́ ìyè fún ọ, àti ẹ̀ṣọ́ fún ọrùn rẹ.
Porque serão vida para tua alma, e graça para teu pescoço.
23 Nígbà náà ni ìwọ yóò bá ọ̀nà rẹ lọ ní àìléwu, ìwọ kì yóò sì kọsẹ̀.
Então andarás por teu caminho em segurança; e com teus pés não tropeçarás.
24 Nígbà tí ìwọ bá dùbúlẹ̀, ìwọ kì yóò bẹ̀rù, nígbà tí ìwọ bá dùbúlẹ̀, oorun rẹ yóò jẹ́ oorun ayọ̀.
Quando te deitares, não terás medo; tu deitarás, e teu sono será suave.
25 Má ṣe bẹ̀rù ìdààmú òjijì, tàbí ti ìparun tí ó ń dé bá àwọn ènìyàn búburú.
Não temas o pavor repentino; nem da assolação dos perversos, quando vier.
26 Nítorí Olúwa yóò jẹ́ ìgbẹ́kẹ̀lé rẹ, kì yóò sì jẹ́ kí ẹsẹ̀ rẹ bọ́ sínú pàkúté.
Porque o SENHOR será tua esperança; e ele guardará teus pés para que não sejam presos.
27 Má ṣe fa ọwọ́ ìre sẹ́yìn kúrò lọ́dọ̀ àwọn tí ṣe tìrẹ, nígbà tí ó bá wà ní ìkápá rẹ láti ṣe ohun kan.
Não detenhas o bem daqueles que possuem o direito, se tiveres em tuas mãos poder para o fazeres.
28 Má ṣe wí fún aládùúgbò rẹ pé, “Padà wá nígbà tó ṣe díẹ̀; èmi yóò fi fún ọ ní ọ̀la,” nígbà tí o ní i pẹ̀lú rẹ nísinsin yìí.
Não digas a teu próximo: Vai, e volta [depois], que amanhã te darei; se tu tiveres contigo [o que ele te pede].
29 Má ṣe pète ohun búburú fún aládùúgbò rẹ, ti o gbé nítòsí rẹ, tí ó sì fọkàn tán ọ.
Não planejes o mal contra teu próximo, pois ele mora tendo confiança em ti.
30 Má ṣe fẹ̀sùn kan ènìyàn láìnídìí, nígbà tí kò ṣe ọ́ ní ibi kankan rárá.
Não brigues contra alguém sem motivo, se ele não fez mal contra ti.
31 Má ṣe ṣe ìlara ènìyàn jàgídíjàgan tàbí kí o yàn láti rìn ní ọ̀nà rẹ̀.
Não tenhas inveja do homem violento, nem escolhas [seguir] algum dos caminhos dele.
32 Nítorí Olúwa kórìíra ènìyàn aláyídáyidà ṣùgbọ́n a máa fọkàn tán ẹni dídúró ṣinṣin.
Porque o SENHOR abomina os perversos; mas ele [guarda] o seu segredo com os justos.
33 Ègún Olúwa ń bẹ lórí ilé ènìyàn búburú, ṣùgbọ́n ó bùkún fún ilé olódodo.
A maldição do SENHOR [está] na casa do perverso; porém ele abençoa a morada dos justos.
34 Ó fi àwọn ẹlẹ́yà ṣe yẹ̀yẹ́, ṣùgbọ́n ó fi oore-ọ̀fẹ́ fún onírẹ̀lẹ̀.
Certamente ele zombará dos zombadores; mas dará graça aos humildes.
35 Ọlọ́gbọ́n jogún iyì, ṣùgbọ́n àwọn aṣiwèrè ni yóò ru ìtìjú wọn.
Os sábios herdarão honra; porém os loucos terão sobre si confusão.

< Proverbs 3 >