< Proverbs 29 >

1 Ẹni tí ó sì ń ṣorí kunkun lẹ́yìn ọ̀pọ̀lọpọ̀ ìbáwí yóò parun lójijì láìsí àtúnṣe.
Un homme souvent réprimandé et persistant dans son entêtement est brisé soudain et sans retour.
2 Nígbà tí olódodo bá ń gbilẹ̀, àwọn ènìyàn a yọ̀ nígbà tí ènìyàn búburú ń ṣàkóso, àwọn ènìyàn ń kórìíra.
Quand dominent les justes, le peuple est en joie; quand les méchants gouvernent, le peuple gémit.
3 Ènìyàn tí ó fẹ́ràn ọgbọ́n mú kí baba rẹ̀ láyọ̀ ṣùgbọ́n ẹni ti ń bá panṣágà kẹ́gbẹ́ ba ọrọ̀ ọ rẹ̀ jẹ́.
L’Homme qui aime la sagesse réjouit son père; celui qui fréquente des courtisanes mange son bien.
4 Nípa ìdájọ́ òdodo ni ọba fi í mú ìlú tòrò nini, ṣùgbọ́n èyí tí ń ṣe ojúkòkòrò àbẹ̀tẹ́lẹ̀ fà á lulẹ̀.
Un roi grandit son pays par la justice: avide de dons, il le ruine.
5 Ẹnikẹ́ni tí ó bá tan aládùúgbò rẹ̀ ó ń dẹ àwọ̀n de ẹsẹ̀ ẹ rẹ̀.
Qui flatte son prochain tend un filet sous ses pas.
6 Ẹ̀ṣẹ̀ ènìyàn ibi ni ó jẹ́ ìdẹ̀kùn rẹ̀ ṣùgbọ́n olódodo le è kọrin kí ó sì máa yọ̀.
Le péché devient un piège pour le méchant; le juste jubile et savoure sa joie.
7 Olódodo ń máa ro ọ̀rọ̀ tálákà, ṣùgbọ́n ènìyàn búburú kò sú sí i láti rò ó.
Le juste se pénètre du droit des humbles; le méchant ne sait rien comprendre.
8 Àwọn ẹlẹ́yà a máa ru ìlú sókè, ṣùgbọ́n àwọn ọlọ́gbọ́n ènìyàn máa ń mú ìbínú kúrò.
Les persifleurs mettent la ville en ébullition; les sages apaisent les colères.
9 Bí ọlọ́gbọ́n ènìyàn bá lọ sí ilé ẹjọ́ pẹ̀lú aláìgbọ́n aláìgbọ́n a máa bínú a sì máa jà, kò sì ní sí àlàáfíà.
Quand un sage est en discussion avec un sot, celui-ci s’emporte ou ricane, mais de calme, point!
10 Àwọn tí ó ń tàjẹ̀ sílẹ̀ kò rí ẹni dídúró ṣinṣin wọ́n sì ń wá ọ̀nà láti pa olódodo.
Les assassins en veulent à l’innocent; les honnêtes gens recherchent sa personne.
11 Aláìgbọ́n ènìyàn fi gbogbo ẹnu rẹ̀ bínú ṣùgbọ́n ọlọ́gbọ́n ènìyàn a máa kó ìbínú rẹ̀ ní ìjánu.
Le sot lâche toute sa mauvaise humeur; le sage finit par la calmer.
12 Bí olórí bá fetí sí irọ́, gbogbo àwọn ìjòyè rẹ̀ a di ènìyàn búburú lójú rẹ̀.
Le souverain accueille-t-il le mensonge, tous ses serviteurs sont pervers.
13 Tálákà ènìyàn àti aninilára jọ ní àbùdá yìí, Olúwa jẹ́ kí ojú àwọn méjèèjì máa ríran.
Le pauvre et l’exploiteur se retrouvent ensemble: l’Eternel fait luire sa lumière aux yeux de tous deux.
14 Bí ọba kan bá ń ṣe ìdájọ́ tálákà pẹ̀lú òtítọ́ ìtẹ́ ìjọba rẹ yóò fìdímúlẹ̀ nígbà gbogbo.
Que le roi juge les humbles avec équité, son trône en sera affermi à jamais.
15 Ọ̀pá ìbániwí ń fún ni ní ọgbọ́n ṣùgbọ́n ọmọ tí a fi sílẹ̀ fúnra rẹ̀ a dójútì ìyá rẹ̀.
Verge et reproches inculquent la sagesse, un enfant livré à lui-même fait le déshonneur de sa mère.
16 Nígbà tí ènìyàn búburú ń gbilẹ̀, bẹ́ẹ̀ náà ni ẹ̀ṣẹ̀ ń gbilẹ̀ ṣùgbọ́n olódodo yóò rí ìṣubú wọn.
Quand les méchants dominent, le mal augmente, mais les justes seront témoins de leur chute.
17 Bá ọmọ rẹ wí, yóò sì fún ọ ní àlàáfíà yóò sì mú inú dídùn wá sí inú ọkàn rẹ.
Corrige ton fils, tu en auras du plaisir; il donnera de douces joies à ton âme.
18 Níbi tí kò ti sí ìfihàn, àwọn ènìyàn a gbé ìgbé ayé àìbìkítà, ṣùgbọ́n ìbùkún ní fún àwọn tí ń pa òfin mọ́.
Faute de, révélation prophétique, le peuple s’abandonne au désordre; mais heureux s’il observe la loi!
19 A kò le fi ọ̀rọ̀ lásán kìlọ̀ fún ìránṣẹ́ bí ó tilẹ̀ yé e, kò ní kọbi ara sí i.
Ce n’est pas avec des paroles qu’on corrige l’esclave: s’il les comprend, il n’en tient pas compte.
20 Ǹjẹ́ ó rí ènìyàn tí ń kánjú sọ̀rọ̀? Ìrètí wà fún aláìgbọ́n jù ú lọ.
Vois-tu un homme précipité dans ses paroles, le sot a plus d’avenir que lui.
21 Bí ènìyàn kan bá kẹ́ ìránṣẹ́ rẹ̀ lákẹ̀ẹ́jù láti kékeré yóò mú ìbànújẹ́ wá ní ìgbẹ̀yìn.
Qui gâte son esclave dès l’enfance aboutit à en faire un parasite.
22 Oníbìínú ènìyàn a ru ìjà sókè, onínú-fùfù ènìyàn a sì máa dá ọ̀pọ̀lọpọ̀ ẹ̀ṣẹ̀.
Un homme irascible provoque des disputes; qui se laisse emporter par la colère accumule les fautes.
23 Ìgbéraga ènìyàn a máa sọ ọ́ di ẹni ilẹ̀ ṣùgbọ́n onírẹ̀lẹ̀ ènìyàn a máa gba iyì kún iyì.
L’Orgueil de l’homme amène son abaissement; la modestie est une source d’honneur.
24 Ẹni tí ó ń kó ẹgbẹ́, olè kórìíra ọkàn ara rẹ̀, ó ń gbọ́ èpè olóhun kò sì le è fọhùn.
Qui partage avec un voleur est son propre ennemi: il entend l’adjuration et ne peut rien dénoncer.
25 Ìbẹ̀rù ènìyàn kan yóò sì di ìdẹ̀kùn ṣùgbọ́n ẹnikẹ́ni tí ó bẹ̀rù Olúwa wà láìléwu.
La peur fait tomber l’homme dans un piège; qui met sa confiance en l’Eternel est à l’abri.
26 Ọ̀pọ̀lọpọ̀ ni ń wá ojúrere alákòóso, ṣùgbọ́n láti ọ̀dọ̀ Olúwa ni ènìyàn tí ń gba ìdájọ́ òdodo.
Beaucoup recherchent la faveur du prince; mais c’est Dieu qui attribue à chacun son dû.
27 Olódodo kórìíra àwọn aláìṣòótọ́: ènìyàn búburú kórìíra olódodo.
Le malfaiteur est en horreur aux justes, et l’honnête homme est en horreur au méchant.

< Proverbs 29 >