< Proverbs 28 >

1 Ènìyàn búburú ń sá bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé ẹnìkan kò lé e ṣùgbọ́n olódodo láyà bí i kìnnìún.
Utíkají bezbožní, ač jich žádný nehoní, ale spravedliví jako mladý lev smělí jsou.
2 Nígbà tí orílẹ̀-èdè bá ní orí kunkun, àwọn ọba rẹ̀ a máa pọ̀, ṣùgbọ́n olóye àti onímọ̀ a máa pa òfin mọ́.
Pro přestoupení země mnoho knížat jejích, ale pro člověka rozumného a umělého trvánlivé bývá panování.
3 Ọba tí ó ni àwọn tálákà lára dàbí àgbàrá òjò tí ó ń gbá gbogbo ọ̀gbìn lọ.
Muž chudý, kterýž utiská nuzné, podoben jest přívalu zachvacujícímu, za čímž nebývá chleba.
4 Àwọn tí ó kọ òfin sílẹ̀ a máa gbóríyìn fún ènìyàn búburú ṣùgbọ́n àwọn tí ó pa òfin mọ́ kọjú ìjà sí ènìyàn búburú.
Kteří opouštějí zákon, chválí bezbožného, ale kteříž ostříhají zákona, velmi jsou jim na odpor.
5 Òye ìdájọ́ òdodo kò yé àwọn ẹni ibi ṣùgbọ́n ó yé àwọn tí ń wá Olúwa dáradára.
Lidé zlí nesrozumívají soudu, ti pak, kteříž hledají Hospodina, rozumějí všemu.
6 Ó sàn láti jẹ́ tálákà tí ìrìn rẹ̀ jẹ́ aláìlábùkù ju ọlọ́rọ̀ tí ọ̀nà rẹ̀ rí pálapàla.
Lepší jest chudý, kterýž chodí v upřímnosti své, než převrácený na kterékoli cestě, ačkoli jest bohatý.
7 Ẹni tí ó pa òfin mọ́ jẹ́ olóye ọmọ ṣùgbọ́n ẹni tí ó bá ẹ́ jẹgúdújẹrá kẹ́gbẹ́ dójútì baba rẹ̀.
Kdo ostříhá zákona, jest syn rozumný; kdož pak s žráči tovaryší, hanbu činí otci svému.
8 Ẹni tí ó mú ọrọ̀ rẹ̀ di púpọ̀ nípa èrè àjẹjù ń kó jọ fún ẹlòmíràn, tí yóò ní àánú àwọn tálákà.
Kdo rozmnožuje statek svůj lichvou a úrokem, shromažďuje tomu, kdož by jej z milosti chudým rozděloval.
9 Bí ẹnikẹ́ni bá kọ etí ikún sí òfin, kódà àdúrà rẹ̀ jẹ́ ìríra.
Kdo odvrací ucho své, aby neslyšel zákona, i modlitba jeho jest ohavností.
10 Ẹni tí ó mú olódodo rìn ọ̀nà búburú yóò bọ́ sínú pàkúté ara rẹ̀ ṣùgbọ́n aláìlẹ́gàn yóò gba ogún rere.
Kdo zavodí upřímé na cestu zlou, do jámy své sám vpadne, ale upřímí dědičně obdrží dobré.
11 Ọlọ́rọ̀ ènìyàn le è gbọ́n lójú ara rẹ̀ ṣùgbọ́n tálákà tí ó ní òye rí ìdí, rẹ̀.
Moudrý jest u sebe sám muž bohatý, ale chudý rozumný vystihá jej.
12 Nígbà tí olódodo ń lékè ariwo ayọ̀ ta; ṣùgbọ́n nígbà tí ènìyàn búburú gorí òye, àwọn ènìyàn a na pápá bora.
Když plésají spravedliví, velmi to pěkně sluší; ale když povstávají bezbožní, vyhledáván bývá člověk.
13 Ẹni tí ó bo ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀ mọ́lẹ̀ kì yóò ṣe rere, ṣùgbọ́n ẹni tí ó bá jẹ́wọ́ tí ó sì kọ̀ wọ́n sílẹ̀ máa ń rí àánú gbà.
Kdo přikrývá přestoupení svá, nepovede se jemu šťastně; ale kdož je vyznává a opouští, milosrdenství důjde.
14 Ìbùkún ni fún ènìyàn náà tí ó bẹ̀rù Ọlọ́run nígbà gbogbo ṣùgbọ́n ẹni tí ó sé ọkàn rẹ̀ le bọ́ sínú wàhálà.
Blahoslavený člověk, kterýž se strachuje vždycky; ale kdož zatvrzuje srdce své, upadne ve zlé.
15 Bí kìnnìún tí ń ké tàbí Beari tí ń halẹ̀ ni ènìyàn búburú tí ń jẹ ọba lórí àwọn aláìlágbára.
Lev řvoucí a nedvěd hladovitý jest panovník bezbožný nad lidem nuzným.
16 Ọmọ-aládé tí ó ṣe aláìmòye púpọ̀ ní ń ṣe ìwà ìkà púpọ̀ pẹ̀lú, ṣùgbọ́n èyí tí ó kórìíra ojúkòkòrò yóò mú ọjọ́ rẹ̀ pẹ́.
Kníže bez rozumu bývá veliký dráč, ale kdož v nenávisti má mrzký zisk, prodlí dnů.
17 Ẹni tí ọkàn rẹ̀ kò balẹ̀ nítorí ẹ̀ṣẹ̀ ìpànìyàn yóò máa joró rẹ̀ títí ikú má ṣe jẹ́ kí ẹnikẹ́ni ràn án lọ́wọ́.
Èlověka, kterýž násilí činí krvi lidské, ani nad jamou, když utíká, žádný ho nezadrží.
18 Ẹni tí ń rìn déédéé ní yóò là, ṣùgbọ́n ẹni tí ọ̀nà rẹ̀ jẹ́ àyídáyidà ni yóò ṣubú lójijì.
Kdo chodí upřímě, zachován bude, převrácený pak na kterékoli cestě padne pojednou.
19 Ẹni tí ó bá ro ilẹ̀ rẹ̀ yóò ní oúnjẹ lọ́pọ̀lọ́pọ̀ ṣùgbọ́n ẹni tí ń lé ohun asán yóò kún fún òsì.
Kdo dělá zemi svou, nasycen bývá chlebem; ale kdož následuje zahalečů, nasycen bývá chudobou.
20 Olóòtítọ́ ènìyàn yóò rí ìbùkún gbà gan an ṣùgbọ́n ẹni tí ojú ń kán láti di ọlọ́rọ̀ kì yóò lọ láìjìyà.
Muž věrný přispoří požehnání, ale kdož chvátá zbohatnouti, nebývá bez viny.
21 Ojúsàájú ṣíṣe kò dára, síbẹ̀ ènìyàn kan ń ṣẹ̀ nítorí òkèlè oúnjẹ kan.
Přijímati osobu není dobré; nebo mnohý pro kus chleba neprávě činí.
22 Ahun ń sáré àti là kò sì funra pé òsì dúró de òun.
Èlověk závistivý chvátá k statku, nic nevěda, že nouze na něj přijde.
23 Ẹni tí ó bá ènìyàn kan wí yóò rí ojúrere ni nígbẹ̀yìn ju ẹni tí ó ní ètè ẹ̀tàn lọ.
Kdo domlouvá člověku, potom spíše milost nalézá nežli ten, kterýž lahodí jazykem.
24 Ẹni tí ó ja baba tàbí ìyá rẹ̀ lólè tí ó sì wí pé, “Kì í ṣe ẹ̀ṣẹ̀,” irú kan ni òun àti ẹni tí ń pa ni run.
Kdo loupí otce svého a matku svou, a říká, že to není žádný hřích, tovaryš jest vražedlníka.
25 Ọ̀kánjúwà ènìyàn a máa dá ìjà sílẹ̀, ṣùgbọ́n ẹni tí ó bá gbẹ́kẹ̀lé Olúwa yóò gbilẹ̀.
Vysokomyslný vzbuzuje svár, ale kdo doufá v Hospodina, hojnost míti bude.
26 Ẹni tí ó gbẹ́kẹ̀lé ara rẹ̀ jẹ́ aláìgbọ́n ṣùgbọ́n ẹni tí ń rìn nínú ọgbọ́n wà láìléwu.
Kdo doufá v srdce své, blázen jest; ale kdož chodí moudře, pomůže sobě.
27 Ẹni tí ó ń fi fún tálákà kì yóò ṣe aláìní ohunkóhun, ṣùgbọ́n ẹni tí ó di ojú rẹ̀ sí wọn gba ọ̀pọ̀lọpọ̀ ègún.
Kdo dává chudému, nebude míti žádného nedostatku; kdož pak zakrývá oči své, bude míti množství zlořečení.
28 Nígbà tí ènìyàn búburú bá dórí ìjọba, àwọn ènìyàn a na pápá bora; ṣùgbọ́n nígbà tí ènìyàn búburú bá ṣègbé, àwọn olódodo ń gbilẹ̀ sí i.
Když povstávají bezbožní, skrývá se člověk; ale když hynou, rozmnožují se spravedliví.

< Proverbs 28 >