< Proverbs 24 >

1 Má ṣe ṣe ìlara àwọn ènìyàn búburú má ṣe jẹ́ kí àwùjọ wọn wù ọ́;
Nu invidia pe oamenii răi, nici nu dori să fii cu ei.
2 nítorí ọkàn wọn ń gbèrò ohun búburú, ètè wọn sì ń sọ̀rọ̀ nípa dídá rúgúdù sílẹ̀.
Fiindcă inima lor studiază nimicirea și buzele lor vorbesc ticăloșie.
3 Nípa ọgbọ́n ni ilé di kíkọ́ nípa òye sì ni ó ti fìdímúlẹ̀;
Prin înțelepciune este zidită o casă; și prin înțelegere este întemeiată;
4 nípa ìmọ̀ ni àwọn yàrá rẹ̀ kún pẹ̀lú àwọn ohun ọ̀ṣọ́ tí ó lẹ́wà tí ó sì ṣọ̀wọ́n.
Și prin cunoaștere vor fi încăperile umplute cu toate averile prețioase și plăcute.
5 Ọlọ́gbọ́n ènìyàn ní agbára púpọ̀, ènìyàn tí ó ní ìmọ̀ sì ń ní agbára sí i.
Un om înțelept este puternic; da, un om al cunoașterii mărește puterea.
6 Láti jagun, ó nílò ìtọ́sọ́nà: nínú ìṣẹ́gun ni ọ̀pọ̀ onígbìmọ̀.
Căci prin sfat înțelept îți vei purta războiul, și în mulțimea sfătuitorilor este siguranță.
7 Ọgbọ́n ga ju fún aṣiwèrè àti gbọ̀ngàn ìlú níbi ibodè kò ní ohun tí yóò wí.
Înțelepciunea este prea înaltă pentru un nebun; el nu își deschide gura la poartă.
8 Ẹni tí ń pète ibi ni a ó mọ̀ bí ènìyàn ibi.
Cel ce plănuiește să facă răul va fi numit o persoană ticăloasă.
9 Ète òmùgọ̀ ènìyàn jẹ́ ẹ̀ṣẹ̀, àwọn ènìyàn sì kórìíra ẹlẹ́gàn.
Gândul la nechibzuință este păcat, și batjocoritorul este urâciune pentru oameni.
10 Bí ìwọ bá dákú lásìkò ìdààmú báwo ni agbára rẹ ha ti kéré tó!
Dacă leșini în ziua de restriște, puterea ta este mică.
11 Gba àwọn tí a ń wọ́ lọ sí ibi ikú là; fa àwọn tó ń ta gbọ̀nọ́ngbọ̀nọ́n lọ sí ibi ìparun padà.
Dacă te abții să eliberezi pe cei duși la moarte și pe aceia ce sunt gata să fie uciși,
12 Bí ìwọ bá wí pé, “Ṣùgbọ́n a kò mọ nǹkan kan nípa èyí,” ǹjẹ́ ẹni tí ń díwọ̀n ọkàn kò kíyèsi i? Ǹjẹ́ ẹni tí ń ṣọ́ ẹ̀mí rẹ kò mọ̀ ọ́n? Ǹjẹ́ kò ní san án fún ẹnìkọ̀ọ̀kan gẹ́gẹ́ bí ohun tí ó ti ṣe?
Dacă spui: Iată, noi nu am știut aceasta; nu ia aminte el, cel ce cumpănește inimile? Și cel ce îți păzește sufletul, nu știe aceasta? Și nu va întoarce fiecărui om conform faptelor sale?
13 Jẹ oyin, ìwọ ọmọ mi, nítorí tí ó dára, oyin láti inú afárá oyin dùn lẹ́nu.
Fiul meu, mănâncă miere, pentru că este bună; și fagurele care este dulce pentru cerul gurii tale;
14 Mọ̀ pẹ̀lú pé ọgbọ́n pẹ̀lú dùn fún ọkàn rẹ bí ìwọ bá rí i ìrètí ọjọ́ iwájú wà fún ọ ìrètí rẹ kì yóò sì já ṣófo.
Așa va fi cunoașterea înțelepciunii pentru sufletul tău; după ce ai găsit-o, atunci va fi o răsplată și așteptarea ta nu va fi stârpită.
15 Má ṣe ba ní ibùba bí ènìyàn búburú láti gba ibùjókòó olódodo, má ṣe fi ibi ìsinmi rẹ̀ ṣe ìjẹ;
Nu pândi stricatule, împotriva locuinței celui drept; nu jefui locul lui de odihnă;
16 nítorí bí olódodo ènìyàn bá tilẹ̀ ṣubú ní ìgbà méje, yóò tún padà dìde sá á ni, ṣùgbọ́n ìdààmú yóò fa ènìyàn búburú lulẹ̀.
Fiindcă un om drept cade de șapte ori și se ridică din nou, dar cel stricat va cădea în ticăloșie.
17 Má ṣe yọ̀ nígbà tí ọ̀tá rẹ bá ṣubú; nígbà tí ó bá kọsẹ̀, má ṣe jẹ́ kí ọkàn rẹ kí ó yọ̀.
Nu te bucura când dușmanul tău cade și nu lăsa să se veselească inima ta când el se poticnește,
18 Àìṣe bẹ́ẹ̀ Olúwa yóò rí i yóò sì bínú yóò sì yí ìbínú rẹ̀ padà kúrò lọ́dọ̀ rẹ̀.
Ca nu cumva DOMNUL să vadă și să nu îi placă și să își întoarcă furia de la el.
19 Má ṣe fòyà nítorí àwọn ènìyàn ibi tàbí jowú àwọn ènìyàn búburú,
Nu te îngrijora din cauza celor răi, nici nu fi invidios pe cei stricați,
20 nítorí ẹni ibi kò ní ìrètí ọjọ́ iwájú a ó sì pa fìtílà àwọn ènìyàn búburú kú.
Deoarece pentru cel rău nu va fi nicio răsplată; candela celui stricat va fi stinsă.
21 Bẹ̀rù Olúwa àti ọba, ọmọ mi, má sì ṣe darapọ̀ pẹ̀lú àwọn olórí kunkun.
Fiul meu, teme-te de DOMNUL și de împărat; și nu te amesteca cu cei ce sunt dedați schimbării,
22 Nítorí àwọn méjèèjì yóò rán ìparun òjijì sórí wọn, ta ni ó sì mọ irú ìyọnu tí wọ́n lè mú wá?
Căci nenorocirea lor va veni dintr-o dată și cine știe ruina amândurora?
23 Àwọn wọ̀nyí pẹ̀lú tún jẹ́ ọ̀rọ̀ ọlọ́gbọ́n: láti ṣe ojúsàájú níbi ìdájọ́ kò dára rárá.
Acestea aparțin de asemenea înțeleptului. Nu este bine să părtinești oamenii la judecată.
24 Ẹnikẹ́ni tí ó wí fún ẹlẹ́bi pé, “Ìwọ lo jàre,” àwọn ènìyàn yóò ṣẹ́ èpè fún un àwọn orílẹ̀-èdè yóò sì kọ̀ ọ́.
Cel ce spune celui stricat: Tu ești drept; pe el îl va blestema poporul, națiunile îl vor detesta;
25 Ṣùgbọ́n yóò dára fún àwọn tí ń dá ẹlẹ́bi lẹ́bi, ọ̀pọ̀ ìbùkún yóò sì wá sórí wọn.
Dar celor ce îl mustră va fi desfătare și o bună binecuvântare va veni peste ei.
26 Ìdáhùn òtítọ́ dàbí ìfẹnukoni ní ẹnu.
Fiecare va săruta buzele celui ce dă un răspuns drept.
27 Parí gbogbo iṣẹ́ ajé rẹ sì rí i pé oko rẹ ti ṣe dáradára; lẹ́yìn náà kọ́ ilé rẹ.
Pregătește-ți lucrarea de afară și potrivește-ți-o la câmp, și după aceea zidește-ți casa.
28 Má ṣe rojọ́ èké mọ́ aládùúgbò rẹ láìnídìí, tàbí kí o fi ètè rẹ tannijẹ.
Nu fi martor fără motiv împotriva aproapelui tău; și nu înșela cu buzele tale.
29 Má ṣe wí pé, “Èmi yóò ṣe é fún un gẹ́gẹ́ bí ó ti ṣe fún mi; Èmi yóò san ohun tí ó ṣe fún mi padà fún un.”
Nu spune: Îi voi face cum mi-a făcut; îi voi întoarce omului conform faptelor sale.
30 Mo kọjá níbi oko ọ̀lẹ, mo kọjá níbi ọgbà àjàrà aláìgbọ́n ènìyàn;
Am trecut pe lângă câmpul leneșului și pe lângă via omului lipsit de înțelegere,
31 ẹ̀gún ti hù ní ibi gbogbo, koríko ti gba gbogbo oko náà.
Și, iată, peste tot crescuseră spini, și mărăcini acoperiseră suprafața ei și zidul ei de piatră a fost dărâmat.
32 Mo fi ọkàn mi sí nǹkan tí mo kíyèsi mo sì kẹ́kọ̀ọ́ lára ohun tí mo rí;
Atunci am văzut și cu grijă am luat aminte; m-am uitat la acestea și am primit instruire.
33 oorun díẹ̀, òògbé díẹ̀, ìkáwọ́gbera díẹ̀ láti sinmi,
Încă puțin somn, puțină ațipire, puțină încrucișare a mâinilor pentru a dormi;
34 òsì yóò sì dé bá ọ bí adigunjalè àti àìní bí olè.
Așa va veni sărăcia ta ca unul care călătorește și lipsa ta ca un om înarmat.

< Proverbs 24 >