< Proverbs 24 >

1 Má ṣe ṣe ìlara àwọn ènìyàn búburú má ṣe jẹ́ kí àwùjọ wọn wù ọ́;
Tiga kũiguĩra andũ arĩa aaganu ũiru, na ndũkanerirĩrie thiritũ yao,
2 nítorí ọkàn wọn ń gbèrò ohun búburú, ètè wọn sì ń sọ̀rọ̀ nípa dídá rúgúdù sílẹ̀.
nĩgũkorwo ngoro ciao ithugundaga o haaro, na mĩromo yao yaragia ũhoro wa kũrehere andũ thĩĩna.
3 Nípa ọgbọ́n ni ilé di kíkọ́ nípa òye sì ni ó ti fìdímúlẹ̀;
Nyũmba yakagwo na ũũgĩ, naguo ũtaũku nĩguo ũtũmaga ĩĩhaande;
4 nípa ìmọ̀ ni àwọn yàrá rẹ̀ kún pẹ̀lú àwọn ohun ọ̀ṣọ́ tí ó lẹ́wà tí ó sì ṣọ̀wọ́n.
ũmenyo nĩguo ũiyũragia tũnyũmba twayo, ũgatũiyũria na indo cia bata, na ũtonga mwega.
5 Ọlọ́gbọ́n ènìyàn ní agbára púpọ̀, ènìyàn tí ó ní ìmọ̀ sì ń ní agbára sí i.
Mũndũ mũũgĩ arĩ ũhoti mũnene, na mũndũ ũrĩ ũmenyo nĩakĩragĩrĩria kũgĩa na hinya;
6 Láti jagun, ó nílò ìtọ́sọ́nà: nínú ìṣẹ́gun ni ọ̀pọ̀ onígbìmọ̀.
ũgĩthiĩ mbaara-inĩ nĩũbatarĩtio nĩgũtaarwo, na nĩgeetha ũhootane nĩũbatarĩtio nĩ aheani kĩrĩra aingĩ.
7 Ọgbọ́n ga ju fún aṣiwèrè àti gbọ̀ngàn ìlú níbi ibodè kò ní ohun tí yóò wí.
Ũũgĩ ũrĩ igũrũ mũno, ndũngĩkinyĩrĩka nĩ mũndũ mũkĩĩgu; rĩrĩa kwagomanwo kĩhingo-inĩ, ndangĩona wa kuuga.
8 Ẹni tí ń pète ibi ni a ó mọ̀ bí ènìyàn ibi.
Mũndũ ũrĩa ũthugundaga ũũru-rĩ, andũ mamwĩtaga mungumania.
9 Ète òmùgọ̀ ènìyàn jẹ́ ẹ̀ṣẹ̀, àwọn ènìyàn sì kórìíra ẹlẹ́gàn.
Mathugunda ma ũrimũ nĩ mehia, na mũnyũrũrania nĩ kĩndũ kĩrĩ magigi harĩ andũ.
10 Bí ìwọ bá dákú lásìkò ìdààmú báwo ni agbára rẹ ha ti kéré tó!
Ũngĩtuĩka wa kũũrwo nĩ hinya hĩndĩ ya thĩĩna, hinya waku kaĩ nĩ mũnini-ĩ!
11 Gba àwọn tí a ń wọ́ lọ sí ibi ikú là; fa àwọn tó ń ta gbọ̀nọ́ngbọ̀nọ́n lọ sí ibi ìparun padà.
Honokia arĩa maratwarĩrĩrio gĩkuũ-inĩ; girĩrĩria arĩa maratũgũũga merekeire gĩthĩnjĩro.
12 Bí ìwọ bá wí pé, “Ṣùgbọ́n a kò mọ nǹkan kan nípa èyí,” ǹjẹ́ ẹni tí ń díwọ̀n ọkàn kò kíyèsi i? Ǹjẹ́ ẹni tí ń ṣọ́ ẹ̀mí rẹ kò mọ̀ ọ́n? Ǹjẹ́ kò ní san án fún ẹnìkọ̀ọ̀kan gẹ́gẹ́ bí ohun tí ó ti ṣe?
Ũngiuga atĩrĩ, “Ũhoro ũcio tũtiraũmenyete,” githĩ ũrĩa ũthimaga ngoro tiwe ũmenyaga? Ũrĩa ũrangagĩra muoyo waku-rĩ, githĩ ndooĩ kana nĩguo? Githĩ ndakaarĩha o mũndũ kũringana na ũrĩa ekĩte?
13 Jẹ oyin, ìwọ ọmọ mi, nítorí tí ó dára, oyin láti inú afárá oyin dùn lẹ́nu.
Mũrũ wakwa, rĩa ũũkĩ, nĩgũkorwo nĩ mwega; ũũkĩ uumĩte magua-inĩ ũrĩ mũrĩo ũkĩũcama.
14 Mọ̀ pẹ̀lú pé ọgbọ́n pẹ̀lú dùn fún ọkàn rẹ bí ìwọ bá rí i ìrètí ọjọ́ iwájú wà fún ọ ìrètí rẹ kì yóò sì já ṣófo.
Ningĩ menya atĩ ũũgĩ ũrĩ mũrĩo harĩ ngoro yaku; ũngĩgĩa naguo, nĩũkagĩa na kĩĩrĩgĩrĩro, na kĩĩrĩgĩrĩro gĩaku gĩtigaathira.
15 Má ṣe ba ní ibùba bí ènìyàn búburú láti gba ibùjókòó olódodo, má ṣe fi ibi ìsinmi rẹ̀ ṣe ìjẹ;
Ndũkanoohie mũndũ mũthingu njĩra-inĩ ũtharĩkĩre nyũmba yake ta mũitũ, ndũkanahithũkĩre gĩikaro gĩake;
16 nítorí bí olódodo ènìyàn bá tilẹ̀ ṣubú ní ìgbà méje, yóò tún padà dìde sá á ni, ṣùgbọ́n ìdààmú yóò fa ènìyàn búburú lulẹ̀.
nĩgũkorwo mũndũ mũthingu o na angĩgũa maita mũgwanja, agũũaga o agĩũkagĩra, no andũ arĩa aaganu marũndagwo nĩ mũtino.
17 Má ṣe yọ̀ nígbà tí ọ̀tá rẹ bá ṣubú; nígbà tí ó bá kọsẹ̀, má ṣe jẹ́ kí ọkàn rẹ kí ó yọ̀.
Hĩndĩ ĩrĩa thũ yaku yagũa-rĩ, ndũkanamĩkenerere; hĩndĩ ĩrĩa yahĩngwo-rĩ, ndũkareke ngoro yaku ĩkene,
18 Àìṣe bẹ́ẹ̀ Olúwa yóò rí i yóò sì bínú yóò sì yí ìbínú rẹ̀ padà kúrò lọ́dọ̀ rẹ̀.
nĩguo Jehova ndakone ũndũ ũcio arakare, akĩhũndũre marakara make kuuma kũrĩ thũ ĩyo.
19 Má ṣe fòyà nítorí àwọn ènìyàn ibi tàbí jowú àwọn ènìyàn búburú,
Ndũkanathĩĩnĩke ngoro nĩ ũndũ wa andũ arĩa ooru, kana wĩrirĩrie kũhaanana na arĩa aaganu,
20 nítorí ẹni ibi kò ní ìrètí ọjọ́ iwájú a ó sì pa fìtílà àwọn ènìyàn búburú kú.
nĩgũkorwo mũndũ ũrĩa mũũru ndarĩ na mwĩhoko wa thuutha-inĩ, na tawa wa ũrĩa mwaganu nĩũkahorio.
21 Bẹ̀rù Olúwa àti ọba, ọmọ mi, má sì ṣe darapọ̀ pẹ̀lú àwọn olórí kunkun.
Mũrũ wakwa, wĩtigĩre Jehova na wĩtigĩre mũthamaki, na ndũkagĩe na ngwatanĩro na andũ arĩa aremi,
22 Nítorí àwọn méjèèjì yóò rán ìparun òjijì sórí wọn, ta ni ó sì mọ irú ìyọnu tí wọ́n lè mú wá?
nĩgũkorwo acio eerĩ no mamũrehithĩrie mwanangĩko wa narua, na nũũ ũngĩmenya nĩ mĩtino ĩrĩkũ mangĩrehe?
23 Àwọn wọ̀nyí pẹ̀lú tún jẹ́ ọ̀rọ̀ ọlọ́gbọ́n: láti ṣe ojúsàájú níbi ìdájọ́ kò dára rárá.
O na ici no thimo cia andũ arĩa oogĩ: Kwenda mwena ũmwe gũkĩra ũrĩa ũngĩ ciira-inĩ ti ũndũ mwega:
24 Ẹnikẹ́ni tí ó wí fún ẹlẹ́bi pé, “Ìwọ lo jàre,” àwọn ènìyàn yóò ṣẹ́ èpè fún un àwọn orílẹ̀-èdè yóò sì kọ̀ ọ́.
Ũrĩa wothe wĩraga mũndũ ũrĩa ũrĩ na mahĩtia atĩrĩ, “Wee ndũrĩ na mahĩtia,” kĩrĩndĩ nĩgĩkamũruma, na athũũrwo nĩ ndũrĩrĩ.
25 Ṣùgbọ́n yóò dára fún àwọn tí ń dá ẹlẹ́bi lẹ́bi, ọ̀pọ̀ ìbùkún yóò sì wá sórí wọn.
No arĩa matuagĩra andũ arĩa aaganu ciira, nĩmakona wega, na magĩe na kĩrathimo kĩega.
26 Ìdáhùn òtítọ́ dàbí ìfẹnukoni ní ẹnu.
Icookio rĩa wĩhokeku nĩ ta kĩmumunyano kĩa mĩromo.
27 Parí gbogbo iṣẹ́ ajé rẹ sì rí i pé oko rẹ ti ṣe dáradára; lẹ́yìn náà kọ́ ilé rẹ.
Rĩĩkia wĩra wa gũtua mwako na nja, na ũhaarĩrie mĩgũnda yaku; thuutha ũcio cooka wĩakĩre nyũmba.
28 Má ṣe rojọ́ èké mọ́ aládùúgbò rẹ láìnídìí, tàbí kí o fi ètè rẹ tannijẹ.
Ndũkanarute ũira ũigĩrĩre mũndũ wa itũũra rĩaku kĩgeenyo, kana ũheenanie na mĩromo yaku.
29 Má ṣe wí pé, “Èmi yóò ṣe é fún un gẹ́gẹ́ bí ó ti ṣe fún mi; Èmi yóò san ohun tí ó ṣe fún mi padà fún un.”
Ndũkanoige atĩrĩ, “Ngũmwĩka o ta ũrĩa anjĩkĩte; ngwĩrĩhĩria harĩ mũndũ ũcio kũringana na ũrĩa eekire.”
30 Mo kọjá níbi oko ọ̀lẹ, mo kọjá níbi ọgbà àjàrà aláìgbọ́n ènìyàn;
Ndaahĩtũkĩire mũgũnda-inĩ wa kĩgũũta, ngĩhĩtũkĩra mũgũnda-inĩ wa mĩthabibũ wa mũndũ ũtooĩ gũkũũrana maũndũ;
31 ẹ̀gún ti hù ní ibi gbogbo, koríko ti gba gbogbo oko náà.
na rĩrĩ, mĩigua yamerete kũndũ guothe, na mũgũnda ũkaiyũra riya, naruo rũthingo rwa mahiga rũkamomoka.
32 Mo fi ọkàn mi sí nǹkan tí mo kíyèsi mo sì kẹ́kọ̀ọ́ lára ohun tí mo rí;
Nĩndacũũranirie na ngoro yakwa maũndũ macio ndonire, na ngĩĩruta ũndũ kuumana na ũrĩa ndonire:
33 oorun díẹ̀, òògbé díẹ̀, ìkáwọ́gbera díẹ̀ láti sinmi,
Mũtugo wa gũkoma hanini, gũcooka toro hanini, gũkũnja moko hanini ũhurũke;
34 òsì yóò sì dé bá ọ bí adigunjalè àti àìní bí olè.
naguo ũthĩĩni ũgaagũkorerera ta mũitũ, na wagi ũgũkorerere ta mũndũ wĩohete indo cia mbaara.

< Proverbs 24 >