< Proverbs 24 >

1 Má ṣe ṣe ìlara àwọn ènìyàn búburú má ṣe jẹ́ kí àwùjọ wọn wù ọ́;
Be not thou envious of wicked men, And desire not to be with them!
2 nítorí ọkàn wọn ń gbèrò ohun búburú, ètè wọn sì ń sọ̀rọ̀ nípa dídá rúgúdù sílẹ̀.
For their heart studieth destruction, And their lips speak mischief.
3 Nípa ọgbọ́n ni ilé di kíkọ́ nípa òye sì ni ó ti fìdímúlẹ̀;
Through wisdom is a house builded, And by understanding is it established;
4 nípa ìmọ̀ ni àwọn yàrá rẹ̀ kún pẹ̀lú àwọn ohun ọ̀ṣọ́ tí ó lẹ́wà tí ó sì ṣọ̀wọ́n.
Yea, by knowledge are the chambers filled With all precious and goodly substance.
5 Ọlọ́gbọ́n ènìyàn ní agbára púpọ̀, ènìyàn tí ó ní ìmọ̀ sì ń ní agbára sí i.
The wise man is strong; Yea, the man of understanding establisheth his strength.
6 Láti jagun, ó nílò ìtọ́sọ́nà: nínú ìṣẹ́gun ni ọ̀pọ̀ onígbìmọ̀.
For by wise counsel shalt thou make war, And by the multitude of counsellors cometh success.
7 Ọgbọ́n ga ju fún aṣiwèrè àti gbọ̀ngàn ìlú níbi ibodè kò ní ohun tí yóò wí.
Wisdom is too high for the fool; He openeth not his mouth at the gate.
8 Ẹni tí ń pète ibi ni a ó mọ̀ bí ènìyàn ibi.
He that deviseth to do evil Shall be called mischief-master.
9 Ète òmùgọ̀ ènìyàn jẹ́ ẹ̀ṣẹ̀, àwọn ènìyàn sì kórìíra ẹlẹ́gàn.
The purpose of folly is sin; And a scoffer is an abomination to men.
10 Bí ìwọ bá dákú lásìkò ìdààmú báwo ni agbára rẹ ha ti kéré tó!
If thy spirit faint in the day of adversity, Faint will be thy strength.
11 Gba àwọn tí a ń wọ́ lọ sí ibi ikú là; fa àwọn tó ń ta gbọ̀nọ́ngbọ̀nọ́n lọ sí ibi ìparun padà.
Deliver thou those who are dragged to death, And those who totter to the slaughter, —O keep them back!
12 Bí ìwọ bá wí pé, “Ṣùgbọ́n a kò mọ nǹkan kan nípa èyí,” ǹjẹ́ ẹni tí ń díwọ̀n ọkàn kò kíyèsi i? Ǹjẹ́ ẹni tí ń ṣọ́ ẹ̀mí rẹ kò mọ̀ ọ́n? Ǹjẹ́ kò ní san án fún ẹnìkọ̀ọ̀kan gẹ́gẹ́ bí ohun tí ó ti ṣe?
If thou sayst, “Behold, we knew it not!” Doth not he that weigheth the heart observe it? Yea, he that keepeth thy soul knoweth it. And he will render to every man according to his works.
13 Jẹ oyin, ìwọ ọmọ mi, nítorí tí ó dára, oyin láti inú afárá oyin dùn lẹ́nu.
Eat honey, my son, for it is good, And the honeycomb, which is sweet to thy taste;
14 Mọ̀ pẹ̀lú pé ọgbọ́n pẹ̀lú dùn fún ọkàn rẹ bí ìwọ bá rí i ìrètí ọjọ́ iwájú wà fún ọ ìrètí rẹ kì yóò sì já ṣófo.
So learn thou wisdom for thy soul! When thou hast found it, there shall be a reward, And thy expectation shall not be cut off.
15 Má ṣe ba ní ibùba bí ènìyàn búburú láti gba ibùjókòó olódodo, má ṣe fi ibi ìsinmi rẹ̀ ṣe ìjẹ;
Plot not, O wicked man! against the habitation of the righteous; Spoil not his resting-place!
16 nítorí bí olódodo ènìyàn bá tilẹ̀ ṣubú ní ìgbà méje, yóò tún padà dìde sá á ni, ṣùgbọ́n ìdààmú yóò fa ènìyàn búburú lulẹ̀.
For though the righteous fall seven times, yet shall he rise up again; But the wicked shall fall into mischief.
17 Má ṣe yọ̀ nígbà tí ọ̀tá rẹ bá ṣubú; nígbà tí ó bá kọsẹ̀, má ṣe jẹ́ kí ọkàn rẹ kí ó yọ̀.
Rejoice not when thine enemy falleth, And let not thy heart be glad when he stumbleth;
18 Àìṣe bẹ́ẹ̀ Olúwa yóò rí i yóò sì bínú yóò sì yí ìbínú rẹ̀ padà kúrò lọ́dọ̀ rẹ̀.
Lest the LORD see, and it displease him, And he turn away his anger from him.
19 Má ṣe fòyà nítorí àwọn ènìyàn ibi tàbí jowú àwọn ènìyàn búburú,
Fret not thyself on account of evil men, Neither be thou envious of the wicked;
20 nítorí ẹni ibi kò ní ìrètí ọjọ́ iwájú a ó sì pa fìtílà àwọn ènìyàn búburú kú.
For there shall be no posterity to the evil man; The lamp of the wicked shall be put out.
21 Bẹ̀rù Olúwa àti ọba, ọmọ mi, má sì ṣe darapọ̀ pẹ̀lú àwọn olórí kunkun.
My son, fear thou the LORD and the king; And mingle not with them that are given to change!
22 Nítorí àwọn méjèèjì yóò rán ìparun òjijì sórí wọn, ta ni ó sì mọ irú ìyọnu tí wọ́n lè mú wá?
For their calamity shall rise up suddenly, And their ruin, coming from them both, in a moment.
23 Àwọn wọ̀nyí pẹ̀lú tún jẹ́ ọ̀rọ̀ ọlọ́gbọ́n: láti ṣe ojúsàájú níbi ìdájọ́ kò dára rárá.
These also are words of the wise. It is not good to have respect of persons in judgment.
24 Ẹnikẹ́ni tí ó wí fún ẹlẹ́bi pé, “Ìwọ lo jàre,” àwọn ènìyàn yóò ṣẹ́ èpè fún un àwọn orílẹ̀-èdè yóò sì kọ̀ ọ́.
He that saith to the wicked, “Thou art righteous,” Him shall the people curse; Nations shall abhor him.
25 Ṣùgbọ́n yóò dára fún àwọn tí ń dá ẹlẹ́bi lẹ́bi, ọ̀pọ̀ ìbùkún yóò sì wá sórí wọn.
But it shall be well with them that punish him, And the blessing of prosperity shall come upon them.
26 Ìdáhùn òtítọ́ dàbí ìfẹnukoni ní ẹnu.
He that giveth a right answer Kisseth the lips.
27 Parí gbogbo iṣẹ́ ajé rẹ sì rí i pé oko rẹ ti ṣe dáradára; lẹ́yìn náà kọ́ ilé rẹ.
Arrange thy work without, And prepare it in thy field: Afterwards thou mayst build thy house.
28 Má ṣe rojọ́ èké mọ́ aládùúgbò rẹ láìnídìí, tàbí kí o fi ètè rẹ tannijẹ.
Be not a witness without cause against thy neighbor, And deceive not with thy lips.
29 Má ṣe wí pé, “Èmi yóò ṣe é fún un gẹ́gẹ́ bí ó ti ṣe fún mi; Èmi yóò san ohun tí ó ṣe fún mi padà fún un.”
Say not, “As he hath done to me, So will I do to him; I will render to the man according to his doings.”
30 Mo kọjá níbi oko ọ̀lẹ, mo kọjá níbi ọgbà àjàrà aláìgbọ́n ènìyàn;
I passed by the field of the slothful, And by the vineyard of the man void of understanding,
31 ẹ̀gún ti hù ní ibi gbogbo, koríko ti gba gbogbo oko náà.
And, lo! it was all overgrown with thorns, And the face thereof was covered with nettles, And the stone wall thereof was broken down.
32 Mo fi ọkàn mi sí nǹkan tí mo kíyèsi mo sì kẹ́kọ̀ọ́ lára ohun tí mo rí;
Then I saw, and considered it well; I looked upon it. and received instruction.
33 oorun díẹ̀, òògbé díẹ̀, ìkáwọ́gbera díẹ̀ láti sinmi,
“A little sleep, a little slumber! A little folding of the hands to rest!”
34 òsì yóò sì dé bá ọ bí adigunjalè àti àìní bí olè.
So shall poverty come upon thee like a highwayman; Yea, want like an armed man.

< Proverbs 24 >