< Proverbs 24 >

1 Má ṣe ṣe ìlara àwọn ènìyàn búburú má ṣe jẹ́ kí àwùjọ wọn wù ọ́;
Do not be envious of evil men, And do not desire to be with them.
2 nítorí ọkàn wọn ń gbèrò ohun búburú, ètè wọn sì ń sọ̀rọ̀ nípa dídá rúgúdù sílẹ̀.
For their heart meditates [on] destruction, And their lips speak perverseness.
3 Nípa ọgbọ́n ni ilé di kíkọ́ nípa òye sì ni ó ti fìdímúlẹ̀;
A house is built by wisdom, And it establishes itself by understanding.
4 nípa ìmọ̀ ni àwọn yàrá rẹ̀ kún pẹ̀lú àwọn ohun ọ̀ṣọ́ tí ó lẹ́wà tí ó sì ṣọ̀wọ́n.
And the inner parts are filled by knowledge, [With] all precious and pleasant wealth.
5 Ọlọ́gbọ́n ènìyàn ní agbára púpọ̀, ènìyàn tí ó ní ìmọ̀ sì ń ní agbára sí i.
The wise [is] mighty in strength, And a man of knowledge is strengthening power,
6 Láti jagun, ó nílò ìtọ́sọ́nà: nínú ìṣẹ́gun ni ọ̀pọ̀ onígbìmọ̀.
For you make war for yourself by plans, And deliverance [is] in a multitude of counselors.
7 Ọgbọ́n ga ju fún aṣiwèrè àti gbọ̀ngàn ìlú níbi ibodè kò ní ohun tí yóò wí.
Wisdom [is] high for a fool, he does not open his mouth in the gate.
8 Ẹni tí ń pète ibi ni a ó mọ̀ bí ènìyàn ibi.
Whoever is devising to do evil, They call him a master of wicked thoughts.
9 Ète òmùgọ̀ ènìyàn jẹ́ ẹ̀ṣẹ̀, àwọn ènìyàn sì kórìíra ẹlẹ́gàn.
The thought of folly [is] sin, And a scorner [is] an abomination to man.
10 Bí ìwọ bá dákú lásìkò ìdààmú báwo ni agbára rẹ ha ti kéré tó!
You have showed yourself weak in a day of adversity, Your power is restricted,
11 Gba àwọn tí a ń wọ́ lọ sí ibi ikú là; fa àwọn tó ń ta gbọ̀nọ́ngbọ̀nọ́n lọ sí ibi ìparun padà.
If [from] delivering those taken to death, And you take back those slipping to the slaughter.
12 Bí ìwọ bá wí pé, “Ṣùgbọ́n a kò mọ nǹkan kan nípa èyí,” ǹjẹ́ ẹni tí ń díwọ̀n ọkàn kò kíyèsi i? Ǹjẹ́ ẹni tí ń ṣọ́ ẹ̀mí rẹ kò mọ̀ ọ́n? Ǹjẹ́ kò ní san án fún ẹnìkọ̀ọ̀kan gẹ́gẹ́ bí ohun tí ó ti ṣe?
When you say, “Behold, we did not know this.” Is the Ponderer of hearts not He who understands? And the Keeper of your soul He who knows? And He has rendered to man according to his work.
13 Jẹ oyin, ìwọ ọmọ mi, nítorí tí ó dára, oyin láti inú afárá oyin dùn lẹ́nu.
My son, eat honey that [is] good, And the honeycomb [is] sweet to your palate.
14 Mọ̀ pẹ̀lú pé ọgbọ́n pẹ̀lú dùn fún ọkàn rẹ bí ìwọ bá rí i ìrètí ọjọ́ iwájú wà fún ọ ìrètí rẹ kì yóò sì já ṣófo.
So [is] the knowledge of wisdom to your soul, If you have found that there is a posterity And your hope is not cut off.
15 Má ṣe ba ní ibùba bí ènìyàn búburú láti gba ibùjókòó olódodo, má ṣe fi ibi ìsinmi rẹ̀ ṣe ìjẹ;
Do not lay wait, O wicked one, At the habitation of the righteous. Do not spoil his resting place.
16 nítorí bí olódodo ènìyàn bá tilẹ̀ ṣubú ní ìgbà méje, yóò tún padà dìde sá á ni, ṣùgbọ́n ìdààmú yóò fa ènìyàn búburú lulẹ̀.
For the righteous fall and rise seven [times], And the wicked stumble in evil.
17 Má ṣe yọ̀ nígbà tí ọ̀tá rẹ bá ṣubú; nígbà tí ó bá kọsẹ̀, má ṣe jẹ́ kí ọkàn rẹ kí ó yọ̀.
Do not rejoice in the falling of your enemy, And do not let your heart be joyful in his stumbling,
18 Àìṣe bẹ́ẹ̀ Olúwa yóò rí i yóò sì bínú yóò sì yí ìbínú rẹ̀ padà kúrò lọ́dọ̀ rẹ̀.
Lest YHWH see, and [it be] evil in His eyes, And He has turned His anger from off him.
19 Má ṣe fòyà nítorí àwọn ènìyàn ibi tàbí jowú àwọn ènìyàn búburú,
Do not fret yourself at evildoers, do not be envious at the wicked,
20 nítorí ẹni ibi kò ní ìrètí ọjọ́ iwájú a ó sì pa fìtílà àwọn ènìyàn búburú kú.
For there is not a posterity to the evil, The lamp of the wicked is extinguished.
21 Bẹ̀rù Olúwa àti ọba, ọmọ mi, má sì ṣe darapọ̀ pẹ̀lú àwọn olórí kunkun.
Fear YHWH, my son, and the king, Do not mix yourself up with changers,
22 Nítorí àwọn méjèèjì yóò rán ìparun òjijì sórí wọn, ta ni ó sì mọ irú ìyọnu tí wọ́n lè mú wá?
For their calamity rises suddenly, And the ruin of them both—who knows!
23 Àwọn wọ̀nyí pẹ̀lú tún jẹ́ ọ̀rọ̀ ọlọ́gbọ́n: láti ṣe ojúsàájú níbi ìdájọ́ kò dára rárá.
These are also for the wise: [It] is not good to discern faces in judgment.
24 Ẹnikẹ́ni tí ó wí fún ẹlẹ́bi pé, “Ìwọ lo jàre,” àwọn ènìyàn yóò ṣẹ́ èpè fún un àwọn orílẹ̀-èdè yóò sì kọ̀ ọ́.
Whoever is saying to the wicked, “You [are] righteous,” Peoples execrate him—nations abhor him.
25 Ṣùgbọ́n yóò dára fún àwọn tí ń dá ẹlẹ́bi lẹ́bi, ọ̀pọ̀ ìbùkún yóò sì wá sórí wọn.
And it is pleasant to those reproving, And a good blessing comes on them.
26 Ìdáhùn òtítọ́ dàbí ìfẹnukoni ní ẹnu.
He who is returning straightforward words kisses lips.
27 Parí gbogbo iṣẹ́ ajé rẹ sì rí i pé oko rẹ ti ṣe dáradára; lẹ́yìn náà kọ́ ilé rẹ.
Prepare your work in an out-place, And make it ready in the field—go afterward, Then you have built your house.
28 Má ṣe rojọ́ èké mọ́ aládùúgbò rẹ láìnídìí, tàbí kí o fi ètè rẹ tannijẹ.
Do not be a witness against your neighbor for nothing, Or you have enticed with your lips.
29 Má ṣe wí pé, “Èmi yóò ṣe é fún un gẹ́gẹ́ bí ó ti ṣe fún mi; Èmi yóò san ohun tí ó ṣe fún mi padà fún un.”
Do not say, “As he did to me, so I do to him, I render to each according to his work.”
30 Mo kọjá níbi oko ọ̀lẹ, mo kọjá níbi ọgbà àjàrà aláìgbọ́n ènìyàn;
I passed by near the field of a slothful man, And near the vineyard of a man lacking heart.
31 ẹ̀gún ti hù ní ibi gbogbo, koríko ti gba gbogbo oko náà.
And behold, it has gone up—all of it—thorns! Nettles have covered its face, And its stone wall has been broken down.
32 Mo fi ọkàn mi sí nǹkan tí mo kíyèsi mo sì kẹ́kọ̀ọ́ lára ohun tí mo rí;
And I see—I set my heart, I have seen—I have received instruction,
33 oorun díẹ̀, òògbé díẹ̀, ìkáwọ́gbera díẹ̀ láti sinmi,
A little sleep—a little slumber—A little folding of the hands to lie down.
34 òsì yóò sì dé bá ọ bí adigunjalè àti àìní bí olè.
And your poverty has come [as] a traveler, And your want as an armed man!

< Proverbs 24 >