< Proverbs 24 >
1 Má ṣe ṣe ìlara àwọn ènìyàn búburú má ṣe jẹ́ kí àwùjọ wọn wù ọ́;
Be thou not envious of bad men, and do not long to be with them.
2 nítorí ọkàn wọn ń gbèrò ohun búburú, ètè wọn sì ń sọ̀rọ̀ nípa dídá rúgúdù sílẹ̀.
For their heart meditateth destruction, and of mischief do their lips speak.
3 Nípa ọgbọ́n ni ilé di kíkọ́ nípa òye sì ni ó ti fìdímúlẹ̀;
Through wisdom is a house built; and through understanding is it firmly established;
4 nípa ìmọ̀ ni àwọn yàrá rẹ̀ kún pẹ̀lú àwọn ohun ọ̀ṣọ́ tí ó lẹ́wà tí ó sì ṣọ̀wọ́n.
And through knowledge are chambers filled with all manner of precious and pleasant wealth.
5 Ọlọ́gbọ́n ènìyàn ní agbára púpọ̀, ènìyàn tí ó ní ìmọ̀ sì ń ní agbára sí i.
A wise man is [always] in power; and a man of knowledge fortifieth [his] strength.
6 Láti jagun, ó nílò ìtọ́sọ́nà: nínú ìṣẹ́gun ni ọ̀pọ̀ onígbìmọ̀.
For by wise counsel canst thou conduct thy war; and there is help in a multitude of counsellors.
7 Ọgbọ́n ga ju fún aṣiwèrè àti gbọ̀ngàn ìlú níbi ibodè kò ní ohun tí yóò wí.
Wisdom is too high for a fool: in the gate can he not open his mouth.
8 Ẹni tí ń pète ibi ni a ó mọ̀ bí ènìyàn ibi.
Him that deviseth to do evil, men call a master of wicked devices.
9 Ète òmùgọ̀ ènìyàn jẹ́ ẹ̀ṣẹ̀, àwọn ènìyàn sì kórìíra ẹlẹ́gàn.
The counsel of folly is sin; and an abomination to men is the scorner.
10 Bí ìwọ bá dákú lásìkò ìdààmú báwo ni agbára rẹ ha ti kéré tó!
If thou despond on the day of distress, thy strength is small.
11 Gba àwọn tí a ń wọ́ lọ sí ibi ikú là; fa àwọn tó ń ta gbọ̀nọ́ngbọ̀nọ́n lọ sí ibi ìparun padà.
Deliver those that are taken unto death, and those that are moved away to the slaughter hold back.
12 Bí ìwọ bá wí pé, “Ṣùgbọ́n a kò mọ nǹkan kan nípa èyí,” ǹjẹ́ ẹni tí ń díwọ̀n ọkàn kò kíyèsi i? Ǹjẹ́ ẹni tí ń ṣọ́ ẹ̀mí rẹ kò mọ̀ ọ́n? Ǹjẹ́ kò ní san án fún ẹnìkọ̀ọ̀kan gẹ́gẹ́ bí ohun tí ó ti ṣe?
If thou shouldst say, Behold, we know not this man: lo, he that weigheth hearts will truly regard it, and he that keepeth thy soul will surely know it; and he will give a recompense to man according to his doing.
13 Jẹ oyin, ìwọ ọmọ mi, nítorí tí ó dára, oyin láti inú afárá oyin dùn lẹ́nu.
Eat honey, my son, because it is good; and the fine honey, which is sweet to thy palate:
14 Mọ̀ pẹ̀lú pé ọgbọ́n pẹ̀lú dùn fún ọkàn rẹ bí ìwọ bá rí i ìrètí ọjọ́ iwájú wà fún ọ ìrètí rẹ kì yóò sì já ṣófo.
So obtain the knowledge of wisdom for thy soul: when thou hast found her, then shall there be a [happy] future, and thy hope shall not be cut off.
15 Má ṣe ba ní ibùba bí ènìyàn búburú láti gba ibùjókòó olódodo, má ṣe fi ibi ìsinmi rẹ̀ ṣe ìjẹ;
Lie not in wait, O wicked man! against the dwelling of the righteous; waste not his resting-place;
16 nítorí bí olódodo ènìyàn bá tilẹ̀ ṣubú ní ìgbà méje, yóò tún padà dìde sá á ni, ṣùgbọ́n ìdààmú yóò fa ènìyàn búburú lulẹ̀.
For though the righteous were to fall seven times, he will rise up again; but the wicked shall stumble into misfortune.
17 Má ṣe yọ̀ nígbà tí ọ̀tá rẹ bá ṣubú; nígbà tí ó bá kọsẹ̀, má ṣe jẹ́ kí ọkàn rẹ kí ó yọ̀.
At the fall of thy enemy do not rejoice; and at his stumbling let not thy heart be glad:
18 Àìṣe bẹ́ẹ̀ Olúwa yóò rí i yóò sì bínú yóò sì yí ìbínú rẹ̀ padà kúrò lọ́dọ̀ rẹ̀.
Lest the Lord see it and it be displeasing in his eyes, and he turn away from him his wrath.
19 Má ṣe fòyà nítorí àwọn ènìyàn ibi tàbí jowú àwọn ènìyàn búburú,
Fret not thyself because of evil-doers, neither be thou envious of the wicked;
20 nítorí ẹni ibi kò ní ìrètí ọjọ́ iwájú a ó sì pa fìtílà àwọn ènìyàn búburú kú.
For there will be no [happy] future for the bad man: the lamp of the wicked will be quenched.
21 Bẹ̀rù Olúwa àti ọba, ọmọ mi, má sì ṣe darapọ̀ pẹ̀lú àwọn olórí kunkun.
My son, fear the Lord and the king: with those that are desirous to change do not mingle thyself;
22 Nítorí àwọn méjèèjì yóò rán ìparun òjijì sórí wọn, ta ni ó sì mọ irú ìyọnu tí wọ́n lè mú wá?
For suddenly will their calamity arise; and who knoweth the ruin of both of them!
23 Àwọn wọ̀nyí pẹ̀lú tún jẹ́ ọ̀rọ̀ ọlọ́gbọ́n: láti ṣe ojúsàájú níbi ìdájọ́ kò dára rárá.
These things also are for the wise. To have respect of persons in judgment is not good.
24 Ẹnikẹ́ni tí ó wí fún ẹlẹ́bi pé, “Ìwọ lo jàre,” àwọn ènìyàn yóò ṣẹ́ èpè fún un àwọn orílẹ̀-èdè yóò sì kọ̀ ọ́.
Him that saith unto the wicked, Thou art righteous, will the people denounce, him will nations hold accursed;
25 Ṣùgbọ́n yóò dára fún àwọn tí ń dá ẹlẹ́bi lẹ́bi, ọ̀pọ̀ ìbùkún yóò sì wá sórí wọn.
But to those that punish delight shall be given, and upon them shall come the blessing of the good.
26 Ìdáhùn òtítọ́ dàbí ìfẹnukoni ní ẹnu.
Men will kiss the lips of him that giveth a proper answer.
27 Parí gbogbo iṣẹ́ ajé rẹ sì rí i pé oko rẹ ti ṣe dáradára; lẹ́yìn náà kọ́ ilé rẹ.
Prepare without thy work, and make it fit in the field for thyself: and afterward build thy house.
28 Má ṣe rojọ́ èké mọ́ aládùúgbò rẹ láìnídìí, tàbí kí o fi ètè rẹ tannijẹ.
Be not without cause a witness against thy neighbor; for wouldst thou beguile with thy lips?
29 Má ṣe wí pé, “Èmi yóò ṣe é fún un gẹ́gẹ́ bí ó ti ṣe fún mi; Èmi yóò san ohun tí ó ṣe fún mi padà fún un.”
Say not, As he hath done to me so will I do to him: I will recompense every man according to his doing.
30 Mo kọjá níbi oko ọ̀lẹ, mo kọjá níbi ọgbà àjàrà aláìgbọ́n ènìyàn;
By the field of a slothful man I once passed along, and by the vineyard of a man void of sense:
31 ẹ̀gún ti hù ní ibi gbogbo, koríko ti gba gbogbo oko náà.
And, lo, it was all grown over with thorns, nettles had covered its surface, and its stone-wall was broken down.
32 Mo fi ọkàn mi sí nǹkan tí mo kíyèsi mo sì kẹ́kọ̀ọ́ lára ohun tí mo rí;
And when I had indeed beheld [this] I took it to my heart: I saw it, and received a warning.
33 oorun díẹ̀, òògbé díẹ̀, ìkáwọ́gbera díẹ̀ láti sinmi,
“A little [more] sleep, a little slumber, a little folding of the hands in lying down;”
34 òsì yóò sì dé bá ọ bí adigunjalè àti àìní bí olè.
But then will thy poverty come like a rover; and thy wants as a man armed with a shield.