< Proverbs 24 >

1 Má ṣe ṣe ìlara àwọn ènìyàn búburú má ṣe jẹ́ kí àwùjọ wọn wù ọ́;
[My] son, envy not bad men, nor desire to be with them.
2 nítorí ọkàn wọn ń gbèrò ohun búburú, ètè wọn sì ń sọ̀rọ̀ nípa dídá rúgúdù sílẹ̀.
For their heart meditates falsehoods, and their lips speak mischiefs.
3 Nípa ọgbọ́n ni ilé di kíkọ́ nípa òye sì ni ó ti fìdímúlẹ̀;
A house is built by wisdom, and is set up by understanding.
4 nípa ìmọ̀ ni àwọn yàrá rẹ̀ kún pẹ̀lú àwọn ohun ọ̀ṣọ́ tí ó lẹ́wà tí ó sì ṣọ̀wọ́n.
By discretion the chambers are filled with all precious and excellent wealth.
5 Ọlọ́gbọ́n ènìyàn ní agbára púpọ̀, ènìyàn tí ó ní ìmọ̀ sì ń ní agbára sí i.
A wise man is better than a strong man; and a man who has prudence than a large estate.
6 Láti jagun, ó nílò ìtọ́sọ́nà: nínú ìṣẹ́gun ni ọ̀pọ̀ onígbìmọ̀.
War is carried on with generalship, and aid is supplied to the heart of a counsellor.
7 Ọgbọ́n ga ju fún aṣiwèrè àti gbọ̀ngàn ìlú níbi ibodè kò ní ohun tí yóò wí.
Wisdom and good understanding are in the gates of the wise: the wise turn not aside from the mouth of the Lord,
8 Ẹni tí ń pète ibi ni a ó mọ̀ bí ènìyàn ibi.
but deliberate in council. Death befalls uninstructed [men].
9 Ète òmùgọ̀ ènìyàn jẹ́ ẹ̀ṣẹ̀, àwọn ènìyàn sì kórìíra ẹlẹ́gàn.
The fools also dies in sins; and uncleanness [attaches] to a pestilent man.
10 Bí ìwọ bá dákú lásìkò ìdààmú báwo ni agbára rẹ ha ti kéré tó!
He shall be defiled in the evil day, and in the day of affliction, until he be utterly consumed.
11 Gba àwọn tí a ń wọ́ lọ sí ibi ikú là; fa àwọn tó ń ta gbọ̀nọ́ngbọ̀nọ́n lọ sí ibi ìparun padà.
Deliver them that are led away to death, and redeem them that are appointed to be slain; spare not [thy help].
12 Bí ìwọ bá wí pé, “Ṣùgbọ́n a kò mọ nǹkan kan nípa èyí,” ǹjẹ́ ẹni tí ń díwọ̀n ọkàn kò kíyèsi i? Ǹjẹ́ ẹni tí ń ṣọ́ ẹ̀mí rẹ kò mọ̀ ọ́n? Ǹjẹ́ kò ní san án fún ẹnìkọ̀ọ̀kan gẹ́gẹ́ bí ohun tí ó ti ṣe?
But if thou shouldest say, I know not this man; know that the Lord knows the hearts of all; and he that formed breath for all, he knows all things, who renders to every man according to his works.
13 Jẹ oyin, ìwọ ọmọ mi, nítorí tí ó dára, oyin láti inú afárá oyin dùn lẹ́nu.
[My] son, eat honey, for the honeycomb is good, that thy throat may be sweetened.
14 Mọ̀ pẹ̀lú pé ọgbọ́n pẹ̀lú dùn fún ọkàn rẹ bí ìwọ bá rí i ìrètí ọjọ́ iwájú wà fún ọ ìrètí rẹ kì yóò sì já ṣófo.
Thus shalt thou perceive wisdom in thy soul: for if thou find it, thine end shall be good, and hope shall not fail thee.
15 Má ṣe ba ní ibùba bí ènìyàn búburú láti gba ibùjókòó olódodo, má ṣe fi ibi ìsinmi rẹ̀ ṣe ìjẹ;
Bring not an ungodly man into the dwelling of the righteous: neither be deceived by the feeding of the belly.
16 nítorí bí olódodo ènìyàn bá tilẹ̀ ṣubú ní ìgbà méje, yóò tún padà dìde sá á ni, ṣùgbọ́n ìdààmú yóò fa ènìyàn búburú lulẹ̀.
For a righteous man will fall seven times, and rise [again]: but the ungodly shall be without strength in troubles.
17 Má ṣe yọ̀ nígbà tí ọ̀tá rẹ bá ṣubú; nígbà tí ó bá kọsẹ̀, má ṣe jẹ́ kí ọkàn rẹ kí ó yọ̀.
If thine enemy should fall, rejoice not over him, neither be elated at his overthrow.
18 Àìṣe bẹ́ẹ̀ Olúwa yóò rí i yóò sì bínú yóò sì yí ìbínú rẹ̀ padà kúrò lọ́dọ̀ rẹ̀.
For the Lord will see [it], and it will not please him, and he will turn away his wrath from him.
19 Má ṣe fòyà nítorí àwọn ènìyàn ibi tàbí jowú àwọn ènìyàn búburú,
Rejoice not in evil-doers, neither be envious of sinners.
20 nítorí ẹni ibi kò ní ìrètí ọjọ́ iwájú a ó sì pa fìtílà àwọn ènìyàn búburú kú.
For the evil man shall have no posterity: and the light of the wicked shall be put out.
21 Bẹ̀rù Olúwa àti ọba, ọmọ mi, má sì ṣe darapọ̀ pẹ̀lú àwọn olórí kunkun.
[My] son, fear God and the king; and do not disobey either of them.
22 Nítorí àwọn méjèèjì yóò rán ìparun òjijì sórí wọn, ta ni ó sì mọ irú ìyọnu tí wọ́n lè mú wá?
For they will suddenly punish the ungodly, and who can know the vengeance [inflicted] by both?
23 Àwọn wọ̀nyí pẹ̀lú tún jẹ́ ọ̀rọ̀ ọlọ́gbọ́n: láti ṣe ojúsàájú níbi ìdájọ́ kò dára rárá.
And this thing I say to you that are wise [for you] to learn: It is not good to have respect of persons in judgment.
24 Ẹnikẹ́ni tí ó wí fún ẹlẹ́bi pé, “Ìwọ lo jàre,” àwọn ènìyàn yóò ṣẹ́ èpè fún un àwọn orílẹ̀-èdè yóò sì kọ̀ ọ́.
He that says of the ungodly, He is righteous, shall be cursed by peoples, and hateful among the nations.
25 Ṣùgbọ́n yóò dára fún àwọn tí ń dá ẹlẹ́bi lẹ́bi, ọ̀pọ̀ ìbùkún yóò sì wá sórí wọn.
But they that reprove [him] shall appear more excellent, and blessing shall come upon them;
26 Ìdáhùn òtítọ́ dàbí ìfẹnukoni ní ẹnu.
and [men] will kiss lips that answer well.
27 Parí gbogbo iṣẹ́ ajé rẹ sì rí i pé oko rẹ ti ṣe dáradára; lẹ́yìn náà kọ́ ilé rẹ.
Prepare thy works for [thy] going forth, and prepare thyself for the field; and come after me, and thou shalt rebuild thine house.
28 Má ṣe rojọ́ èké mọ́ aládùúgbò rẹ láìnídìí, tàbí kí o fi ètè rẹ tannijẹ.
Be not a false witness against thy [fellow] citizen, neither exaggerate with thy lips.
29 Má ṣe wí pé, “Èmi yóò ṣe é fún un gẹ́gẹ́ bí ó ti ṣe fún mi; Èmi yóò san ohun tí ó ṣe fún mi padà fún un.”
Say not, As he has treated me, so will I treat him, and I will avenge myself on him for that wherein he has injured me.
30 Mo kọjá níbi oko ọ̀lẹ, mo kọjá níbi ọgbà àjàrà aláìgbọ́n ènìyàn;
A foolish man is like a farm, and a senseless man is like a vineyard.
31 ẹ̀gún ti hù ní ibi gbogbo, koríko ti gba gbogbo oko náà.
If thou let him alone, he will altogether remain barren and covered with weeds; and he becomes destitute, and his stone walls are broken down.
32 Mo fi ọkàn mi sí nǹkan tí mo kíyèsi mo sì kẹ́kọ̀ọ́ lára ohun tí mo rí;
Afterwards I reflected, I looked that I might receive instruction.
33 oorun díẹ̀, òògbé díẹ̀, ìkáwọ́gbera díẹ̀ láti sinmi,
[The sluggard says, ]I slumber a little, and I sleep a little, and for a little while I fold my arms across [my] breast.
34 òsì yóò sì dé bá ọ bí adigunjalè àti àìní bí olè.
But if thou do this, thy poverty will come speedily; and thy want like a swift courier.

< Proverbs 24 >