< Proverbs 24 >

1 Má ṣe ṣe ìlara àwọn ènìyàn búburú má ṣe jẹ́ kí àwùjọ wọn wù ọ́;
Be not thou envious against evil men, nor desire to be with them.
2 nítorí ọkàn wọn ń gbèrò ohun búburú, ètè wọn sì ń sọ̀rọ̀ nípa dídá rúgúdù sílẹ̀.
For their heart meditates oppression, and their lips talk of mischief.
3 Nípa ọgbọ́n ni ilé di kíkọ́ nípa òye sì ni ó ti fìdímúlẹ̀;
Through wisdom a house is built, and by understanding it is established,
4 nípa ìmọ̀ ni àwọn yàrá rẹ̀ kún pẹ̀lú àwọn ohun ọ̀ṣọ́ tí ó lẹ́wà tí ó sì ṣọ̀wọ́n.
and by knowledge the chambers are filled with all precious and pleasant riches.
5 Ọlọ́gbọ́n ènìyàn ní agbára púpọ̀, ènìyàn tí ó ní ìmọ̀ sì ń ní agbára sí i.
A wise man is strong, yea, a man of knowledge increases might.
6 Láti jagun, ó nílò ìtọ́sọ́nà: nínú ìṣẹ́gun ni ọ̀pọ̀ onígbìmọ̀.
For by wise guidance thou shall make thy war, and in the multitude of counselors there is safety.
7 Ọgbọ́n ga ju fún aṣiwèrè àti gbọ̀ngàn ìlú níbi ibodè kò ní ohun tí yóò wí.
Wisdom is too high for a fool. He opens not his mouth in the gate.
8 Ẹni tí ń pète ibi ni a ó mọ̀ bí ènìyàn ibi.
He who devises to do evil, men shall call him a mischief-maker.
9 Ète òmùgọ̀ ènìyàn jẹ́ ẹ̀ṣẹ̀, àwọn ènìyàn sì kórìíra ẹlẹ́gàn.
The thought of folly is sin. And the scoffer is an abomination to men.
10 Bí ìwọ bá dákú lásìkò ìdààmú báwo ni agbára rẹ ha ti kéré tó!
If thou faint in the day of adversity, thy strength is small.
11 Gba àwọn tí a ń wọ́ lọ sí ibi ikú là; fa àwọn tó ń ta gbọ̀nọ́ngbọ̀nọ́n lọ sí ibi ìparun padà.
Deliver those who are carried away to death, and hold thou back those who are ready to be slain.
12 Bí ìwọ bá wí pé, “Ṣùgbọ́n a kò mọ nǹkan kan nípa èyí,” ǹjẹ́ ẹni tí ń díwọ̀n ọkàn kò kíyèsi i? Ǹjẹ́ ẹni tí ń ṣọ́ ẹ̀mí rẹ kò mọ̀ ọ́n? Ǹjẹ́ kò ní san án fún ẹnìkọ̀ọ̀kan gẹ́gẹ́ bí ohun tí ó ti ṣe?
If thou say, Behold, we did not know this, Does not he who weighs the hearts consider it? And he who keeps thy soul, does he not know it? And shall not he render to every man according to his work?
13 Jẹ oyin, ìwọ ọmọ mi, nítorí tí ó dára, oyin láti inú afárá oyin dùn lẹ́nu.
My son, eat thou honey, for it is good, and the droppings of the honeycomb, which are sweet to thy taste,
14 Mọ̀ pẹ̀lú pé ọgbọ́n pẹ̀lú dùn fún ọkàn rẹ bí ìwọ bá rí i ìrètí ọjọ́ iwájú wà fún ọ ìrètí rẹ kì yóò sì já ṣófo.
so the knowledge of wisdom is to thy soul. If thou have found it, then there shall be a reward, and thy hope shall not be cut off.
15 Má ṣe ba ní ibùba bí ènìyàn búburú láti gba ibùjókòó olódodo, má ṣe fi ibi ìsinmi rẹ̀ ṣe ìjẹ;
Lay not in wait, O wicked man, against the habitation of the righteous. Do not destroy his resting place.
16 nítorí bí olódodo ènìyàn bá tilẹ̀ ṣubú ní ìgbà méje, yóò tún padà dìde sá á ni, ṣùgbọ́n ìdààmú yóò fa ènìyàn búburú lulẹ̀.
For a righteous man falls seven times, and rises up again, but the wicked are overthrown by calamity.
17 Má ṣe yọ̀ nígbà tí ọ̀tá rẹ bá ṣubú; nígbà tí ó bá kọsẹ̀, má ṣe jẹ́ kí ọkàn rẹ kí ó yọ̀.
Rejoice not when thine enemy falls, and let not thy heart be glad when he is overthrown,
18 Àìṣe bẹ́ẹ̀ Olúwa yóò rí i yóò sì bínú yóò sì yí ìbínú rẹ̀ padà kúrò lọ́dọ̀ rẹ̀.
lest Jehovah see it, and it displease him, and he turn away his wrath from him.
19 Má ṣe fòyà nítorí àwọn ènìyàn ibi tàbí jowú àwọn ènìyàn búburú,
Fret not thyself because of evildoers, nor be thou envious at the wicked.
20 nítorí ẹni ibi kò ní ìrètí ọjọ́ iwájú a ó sì pa fìtílà àwọn ènìyàn búburú kú.
For there shall be no reward to the evil man. The lamp of the wicked shall be put out.
21 Bẹ̀rù Olúwa àti ọba, ọmọ mi, má sì ṣe darapọ̀ pẹ̀lú àwọn olórí kunkun.
My son, fear thou Jehovah and the king, and do not associate with those who are given to change.
22 Nítorí àwọn méjèèjì yóò rán ìparun òjijì sórí wọn, ta ni ó sì mọ irú ìyọnu tí wọ́n lè mú wá?
For their calamity shall rise suddenly, and the destruction from them both, who knows it?
23 Àwọn wọ̀nyí pẹ̀lú tún jẹ́ ọ̀rọ̀ ọlọ́gbọ́n: láti ṣe ojúsàájú níbi ìdájọ́ kò dára rárá.
These also are from the wise: To have respect of persons in judgment is not good.
24 Ẹnikẹ́ni tí ó wí fún ẹlẹ́bi pé, “Ìwọ lo jàre,” àwọn ènìyàn yóò ṣẹ́ èpè fún un àwọn orílẹ̀-èdè yóò sì kọ̀ ọ́.
He who says to a wicked man, Thou are righteous, peoples shall curse him, nations shall abhor him.
25 Ṣùgbọ́n yóò dára fún àwọn tí ń dá ẹlẹ́bi lẹ́bi, ọ̀pọ̀ ìbùkún yóò sì wá sórí wọn.
But to those who rebuke him shall be delight, and a good blessing shall come upon them.
26 Ìdáhùn òtítọ́ dàbí ìfẹnukoni ní ẹnu.
He who gives a right answer kisses the lips.
27 Parí gbogbo iṣẹ́ ajé rẹ sì rí i pé oko rẹ ti ṣe dáradára; lẹ́yìn náà kọ́ ilé rẹ.
Prepare thy work outside, and make it ready for thee in the field, and afterwards build thy house.
28 Má ṣe rojọ́ èké mọ́ aládùúgbò rẹ láìnídìí, tàbí kí o fi ètè rẹ tannijẹ.
Be not a witness against thy neighbor without cause, and deceive not with thy lips.
29 Má ṣe wí pé, “Èmi yóò ṣe é fún un gẹ́gẹ́ bí ó ti ṣe fún mi; Èmi yóò san ohun tí ó ṣe fún mi padà fún un.”
Say not, I will do so to him as he has done to me; I will render to the man according to his work.
30 Mo kọjá níbi oko ọ̀lẹ, mo kọjá níbi ọgbà àjàrà aláìgbọ́n ènìyàn;
I went by the field of the sluggard, and by the vineyard of the man void of understanding.
31 ẹ̀gún ti hù ní ibi gbogbo, koríko ti gba gbogbo oko náà.
And, lo, it was all grown over with thorns. The face of it was covered with nettles, and the stone wall of it was broken down.
32 Mo fi ọkàn mi sí nǹkan tí mo kíyèsi mo sì kẹ́kọ̀ọ́ lára ohun tí mo rí;
Then I beheld, and considered well. I saw, and received instruction:
33 oorun díẹ̀, òògbé díẹ̀, ìkáwọ́gbera díẹ̀ láti sinmi,
Yet a little sleep, a little slumber, a little folding of the hands to sleep,
34 òsì yóò sì dé bá ọ bí adigunjalè àti àìní bí olè.
so thy poverty shall come as a robber, and thy want as an armed man.

< Proverbs 24 >