< Proverbs 23 >

1 Nígbà tí ìwọ bá jókòó láti bá ìjòyè jẹun, kíyèsi ohun tí ó wà níwájú rẹ gidigidi.
Gdy siądziesz, abyś jadł z panem, uważaj pilnie, kto jest przed tobą;
2 Ìwọ a sì fi ọ̀bẹ lé ara rẹ ní ọ̀fun, bí ìwọ bá jẹ́ òkúndùn ènìyàn.
Inaczej wraziłbyś nóż w gardło swoje, jeźlibyś był chciwy pokarmu.
3 Má ṣe fẹ́ oúnjẹ dídùn rẹ̀: nítorí pé oúnjẹ ẹ̀tàn ni.
Nie pragnij łakoci jego; bo są pokarmem obłudnym.
4 Má ṣe ṣe làálàá láti lọ́rọ̀: ṣíwọ́ kúrò nínú ọgbọ́n ara rẹ.
Nie staraj się, abyś się zbogacił; owszem, zaniechaj opatrzności twojej.
5 Ìwọ ó ha fi ojú rẹ lépa ohun tí kò sí? Nítorí tí ọ̀rọ̀ hu ìyẹ́ apá fún ara rẹ̀, ó sì ń fò bí idì ní ojú ọ̀run.
I miałżebyś obrócić oczy twoje na bogactwo, które prędko niszczeje? bo sobie uczyni skrzydła podobne orlim, i uleci do nieba.
6 Má ṣe jẹ oúnjẹ ẹni tí ó háwọ́, bẹ́ẹ̀ ni kí o má sì ṣe fẹ́ oúnjẹ dídùn rẹ̀.
Nie jedz chleba człowieka zazdrosnego, a nie żądaj łakoci jego.
7 Nítorí pé bí ẹni tí ń ṣírò ní ọkàn rẹ̀, bẹ́ẹ̀ ni ó rí: “Máa jẹ, kí o sì máa mu,” ni ó ń wí fún ọ; ṣùgbọ́n ọkàn rẹ̀ kò pẹ̀lú rẹ.
Albowiem jako on ciebie waży w myśli swej, tak ty waż pokarm jego. Mówić: Jedz i pij, ale serce jego nie jest z tobą.
8 Òkèlè tí ìwọ jẹ ni ìwọ ó pọ̀ jáde, ìwọ a sì sọ ọ̀rọ̀ dídùn rẹ̀ nù.
Sztuczkę twoję, którąś zjadł, zwrócisz, a utracisz wdzięczne słowa twoje.
9 Má ṣe sọ̀rọ̀ ní etí aṣiwèrè; nítorí tí yóò gan ọgbọ́n ọ̀rọ̀ rẹ.
Przed głupim nie mów; albowiem wzgardzi roztropnością powieści twoich.
10 Má ṣe ṣí ààlà àtijọ́ kúrò; má sì ṣe bọ́ sínú oko aláìní baba.
Nie przenoś granicy starej, a na rolę sierotek nie wchodź.
11 Nítorí pé Olùràpadà wọn lágbára; yóò gba ìjà wọn jà sí ọ.
Bo obrońca ich możny; onci się podejmuje sprawy ich przeciwko tobie.
12 Fi àyà sí ẹ̀kọ́, àti etí rẹ sí ọ̀rọ̀-ìmọ̀.
Obróć do nauki serce twoje, a uszy twoje do powieści umiejętności.
13 Má ṣe fa ọwọ́ ìbáwí sẹ́yìn kúrò lára ọmọdé, nítorí pé bí ìwọ bá fi pàṣán nà án, òun kì yóò kú.
Nie odejmuj od młodego karności; bo jeźli go ubijesz rózgą, nie umrze.
14 Bí ìwọ fi pàṣán nà án, ìwọ ó sì gbà ọkàn rẹ̀ là kúrò ní ọ̀run àpáàdì. (Sheol h7585)
Ty go bij rózgą, a duszę jego z piekła wyrwiesz. (Sheol h7585)
15 Ọmọ mi, bí ọkàn rẹ bá gbọ́n, ọkàn mi yóò yọ̀, àní èmi pẹ̀lú.
Synu mój! będzieli mądre serce twoje, będzie się weseliło serce moje, serce moje we mnie;
16 Inú mi yóò sì dùn nígbà tí ètè rẹ̀ bá ń sọ̀rọ̀ títọ́.
I rozweselą się nerki moje, gdy będą mówiły wargi twoje, co jest prawego.
17 Má ṣe jẹ́ kí àyà rẹ ó ṣe ìlara sí àwọn ẹlẹ́ṣẹ̀, ṣùgbọ́n kí ìwọ ó wà ní ìbẹ̀rù Olúwa, ní ọjọ́ gbogbo.
Niech nie zajrzy serce twoje grzesznikom; ale raczej chodż w bojańni Pańskiej na każdy dzień;
18 Nítorí pé ìgbẹ̀yìn ń bẹ nítòótọ́; ìrètí rẹ̀ kì yóò sì gé kúrò.
Bo iż jest zapłata, przeto nadzieja twoja nie będzie wykorzeniona.
19 Gbọ́, ìwọ ọmọ mi, kí o sì gbọ́n, kí o sì máa tọ́ àyà rẹ sí ọ̀nà títọ́.
Słuchaj, synu mój! a bądź mądry, i nawiedź na drogę serce twoje.
20 Má ṣe wà nínú àwọn ọ̀mùtí; àti àwọn wọ̀bìà alájẹkì ọ̀jẹun;
Nie bywaj między pijanicami wina, ani między żarłokami mięsa;
21 nítorí pé ọ̀mùtí àti ọ̀jẹun ni yóò di tálákà; ìmúni-tòògbé ní sì ń fi àkísà wọ ọkùnrin láṣọ.
Boć pijanica i żarłok zubożeje, a ospały w łatach chodzić będzie.
22 Fetí sí ti baba rẹ tí ó bí ọ, má sì ṣe gan ìyá rẹ, nígbà tí o bá gbó.
Słuchaj ojca twego, który cię spłodził, a nie pogardzaj matką twoją, gdy się zstarzeje.
23 Ra òtítọ́, kí o má sì ṣe tà á; ra ọgbọ́n pẹ̀lú àti ẹ̀kọ́ àti òye.
Kupuj prawdę, a nie sprzedawaj jej; kupuj mądrość, umiejętność i rozum.
24 Baba olódodo ni yóò yọ̀ gidigidi: ẹni tí ó sì bí ọmọ ọlọ́gbọ́n, yóò ní ayọ̀ nínú rẹ̀.
Bardzo się raduje ojciec sprawiedliwego, a kto spłodził mądrego, weseli się z niego.
25 Jẹ́ kí baba rẹ àti ìyá rẹ ó yọ̀, sì jẹ́ kí inú ẹni tí ó bí ọ dùn.
Niech się tedy weseli ojciec twój, i matka twoja; i niech się rozraduje rodzicielka twoja.
26 Ọmọ mi, fi àyà rẹ fún mi, kí o sì jẹ́ kí ojú rẹ ní inú dídùn sí ọ̀nà mi.
Synu mój! daj mi serce twoje, a oczy twoje niechaj strzegą dróg moich.
27 Nítorí pé panṣágà obìnrin ọ̀gbun jíjìn ni; àti àjèjì obìnrin kànga híhá ni.
Bo nierządnica jest dół głęboki, a cudza żona jest studnia ciasna.
28 Òun á sì ba ní bùba bí olè, a sì sọ àwọn olùrékọjá di púpọ̀ nínú àwọn ènìyàn.
Ona też jako zbojca zasadzki czyni, a zuchwalców między ludźmi rozmnaża.
29 Ta ni ó ni òsì? Ta ni ó ni ìbànújẹ́? Ta ni ó ni ìjà? Ta ni ó ni asọ̀? Ta ni ó ni ọgbẹ́ láìnídìí?
Komu biada? Komu niestety? Komu zwady? Komu krzyk? Komu rany daremne? Komu zapalenie oczów?
30 Àwọn tí ó dúró pẹ́ níbi ọtí wáìnì; àwọn tí ń lọ láti dán ọtí wáìnì àdàlú wò.
Tym, którzy siadają na winie; tym, którzy chodzą, szukając przyprawnego wina.
31 Ìwọ má ṣe wò ọtí wáìnì nígbà tí ó pọ́n, nígbà tí ó bá ń fi àwọ̀ rẹ̀ hàn nínú ago, tí a gbé e mì, tí ó ń dùn.
Nie zapatruj się na wino, gdy się rumieni, i gdy wydaje w kubku łunę swoję, a prosto wyskakuje.
32 Níkẹyìn òun á bu ni ṣán bí ejò, a sì bunijẹ bí i paramọ́lẹ̀.
Bo na koniec jako wąż ukąsi, a jako żmija uszczknie;
33 Ojú rẹ yóò wò àwọn àjèjì obìnrin, àyà rẹ yóò sì sọ̀rọ̀ àyídáyidà.
Oczy twoje patrzyć będą na cudze żony, a serce twe będzie mówiło przewrotności;
34 Nítòótọ́, ìwọ ó dàbí ẹni tí ó dùbúlẹ̀ ní àárín Òkun, tàbí ẹni tí ó dùbúlẹ̀ lókè-ọkọ̀.
I będziesz jako ten, który leży w pośród morza, a jako ten, który śpi na wierzchu masztu;
35 Ìwọ ó sì wí pé, “Wọ́n lù mí; kò dùn mí; wọ́n lù mí, èmi kò sì mọ̀: nígbà wo ni èmi ó jí? Èmi ó tún máa wá òmíràn láti mu.”
Rzeczesz: Ubito mię, a nie stękałem, potłuczono mię, a nie czułem. Gdy się ocucę, udam się zaś do tego.

< Proverbs 23 >