< Proverbs 23 >

1 Nígbà tí ìwọ bá jókòó láti bá ìjòyè jẹun, kíyèsi ohun tí ó wà níwájú rẹ gidigidi.
Rĩrĩa waikara thĩ kũrĩĩanĩra na mwathi wa bũrũri-rĩ, wĩmenyerere nũũ ũcio mũrĩ nake;
2 Ìwọ a sì fi ọ̀bẹ lé ara rẹ ní ọ̀fun, bí ìwọ bá jẹ́ òkúndùn ènìyàn.
wĩigĩrĩre kahiũ mũmero ũngĩkorwo ũrĩ mũndũ mũkoroku.
3 Má ṣe fẹ́ oúnjẹ dídùn rẹ̀: nítorí pé oúnjẹ ẹ̀tàn ni.
Ndũkerirĩrie irio ciake irĩ mũrĩo, nĩgũkorwo nĩ irio cia gũkũheenereria.
4 Má ṣe ṣe làálàá láti lọ́rọ̀: ṣíwọ́ kúrò nínú ọgbọ́n ara rẹ.
Tiga kwĩnogia na kwenda gwĩtongia; gĩa na ũũgĩ wa kũhota kwĩrigĩrĩria.
5 Ìwọ ó ha fi ojú rẹ lépa ohun tí kò sí? Nítorí tí ọ̀rọ̀ hu ìyẹ́ apá fún ara rẹ̀, ó sì ń fò bí idì ní ojú ọ̀run.
No wone ũtonga, ũcooke ũbuĩrie, nĩgũkorwo ti-itherũ ũtonga nĩwĩmeragia mathagu, na ũkombũka ta nderi yerekeire matu-inĩ.
6 Má ṣe jẹ oúnjẹ ẹni tí ó háwọ́, bẹ́ẹ̀ ni kí o má sì ṣe fẹ́ oúnjẹ dídùn rẹ̀.
Tiga kũrĩa irio cia mũndũ mũkarĩ, ndũkerirĩrie irio ciake cia mũrĩo;
7 Nítorí pé bí ẹni tí ń ṣírò ní ọkàn rẹ̀, bẹ́ẹ̀ ni ó rí: “Máa jẹ, kí o sì máa mu,” ni ó ń wí fún ọ; ṣùgbọ́n ọkàn rẹ̀ kò pẹ̀lú rẹ.
tondũ nĩ mũndũ wa arĩa meciiragia o ũhoro wa thogora hĩndĩ ciothe. Akwĩraga atĩrĩ, “Rĩa na ũnyue,” no ngoro yake ndĩrĩ hamwe nawe.
8 Òkèlè tí ìwọ jẹ ni ìwọ ó pọ̀ jáde, ìwọ a sì sọ ọ̀rọ̀ dídùn rẹ̀ nù.
Nĩũgatahĩka kĩrĩa kĩnini ũgaakorwo ũrĩĩte, nacio ngaatho ciaku nĩikoorĩra thĩ.
9 Má ṣe sọ̀rọ̀ ní etí aṣiwèrè; nítorí tí yóò gan ọgbọ́n ọ̀rọ̀ rẹ.
Ndũkaarie na mũndũ mũkĩĩgu, nĩgũkorwo we no anyararire ũũgĩ wa ciugo ciaku.
10 Má ṣe ṣí ààlà àtijọ́ kúrò; má sì ṣe bọ́ sínú oko aláìní baba.
Ndũkaneherie ihiga rĩa tene rĩa mũhaka, kana ũhatĩke mĩhaka ya mĩgũnda ya ciana cia ngoriai,
11 Nítorí pé Olùràpadà wọn lágbára; yóò gba ìjà wọn jà sí ọ.
tondũ Mũgitĩri wacio nĩ arĩ na hinya; nĩakamaciirĩrĩra agũũkĩrĩre.
12 Fi àyà sí ẹ̀kọ́, àti etí rẹ sí ọ̀rọ̀-ìmọ̀.
Ringĩrĩria ngoro yaku gũthikĩrĩria ũrutani, na matũ maku kũigua ciugo cia ũmenyo.
13 Má ṣe fa ọwọ́ ìbáwí sẹ́yìn kúrò lára ọmọdé, nítorí pé bí ìwọ bá fi pàṣán nà án, òun kì yóò kú.
Ndũkanaage kũherithia mwana; ũngĩmũhũũra na rũthanju-rĩ, ndangĩkua.
14 Bí ìwọ fi pàṣán nà án, ìwọ ó sì gbà ọkàn rẹ̀ là kúrò ní ọ̀run àpáàdì. (Sheol h7585)
Mũhũũrage na rũthanju nĩguo ũhonokie muoyo wake kuuma kũrĩ gĩkuũ. (Sheol h7585)
15 Ọmọ mi, bí ọkàn rẹ bá gbọ́n, ọkàn mi yóò yọ̀, àní èmi pẹ̀lú.
Mũrũ wakwa, ngoro yaku ĩngĩgĩa na ũũgĩ-rĩ, hĩndĩ ĩyo ngoro yakwa no ĩkene;
16 Inú mi yóò sì dùn nígbà tí ètè rẹ̀ bá ń sọ̀rọ̀ títọ́.
ngoro yakwa nĩĩgacanjamũka rĩrĩa mĩromo yaku ĩkaaria maũndũ marĩa magĩrĩire.
17 Má ṣe jẹ́ kí àyà rẹ ó ṣe ìlara sí àwọn ẹlẹ́ṣẹ̀, ṣùgbọ́n kí ìwọ ó wà ní ìbẹ̀rù Olúwa, ní ọjọ́ gbogbo.
Ndũkanareke ngoro yaku ĩiguĩre ehia ũiru, no hĩndĩ ciothe gĩĩaga na kĩyo gĩa gwĩtigĩra Jehova.
18 Nítorí pé ìgbẹ̀yìn ń bẹ nítòótọ́; ìrètí rẹ̀ kì yóò sì gé kúrò.
Tondũ ti-itherũ wee ũrĩ na kĩĩrĩgĩrĩro thuutha-inĩ, na kĩĩrĩgĩrĩro gĩaku gĩtigaathira.
19 Gbọ́, ìwọ ọmọ mi, kí o sì gbọ́n, kí o sì máa tọ́ àyà rẹ sí ọ̀nà títọ́.
Mũrũ wakwa, thikĩrĩria nĩgeetha ũgĩe na ũũgĩ, na ũige ngoro yaku njĩra-inĩ ĩrĩa yagĩrĩire.
20 Má ṣe wà nínú àwọn ọ̀mùtí; àti àwọn wọ̀bìà alájẹkì ọ̀jẹun;
Ndũkegwatanie na andũ arĩa manyuuaga njoohi, kana arĩa makorokagĩra nyama,
21 nítorí pé ọ̀mùtí àti ọ̀jẹun ni yóò di tálákà; ìmúni-tòògbé ní sì ń fi àkísà wọ ọkùnrin láṣọ.
nĩgũkorwo arĩĩu na andũ arĩa akoroku matuĩkaga athĩĩni, naguo ũgũũta ũtũmaga mũndũ ehumbe matangari.
22 Fetí sí ti baba rẹ tí ó bí ọ, má sì ṣe gan ìyá rẹ, nígbà tí o bá gbó.
Thikagĩrĩria thoguo, we ũrĩa wagũciarire, na ndũkanyarare maitũguo, o na aakorwo nĩ mũkũrũ.
23 Ra òtítọ́, kí o má sì ṣe tà á; ra ọgbọ́n pẹ̀lú àti ẹ̀kọ́ àti òye.
Wĩgũrĩre ũhoro ũrĩa wa ma na ndũkanawendie; wĩgĩĩre na ũũgĩ, na ũtaaro, na ũtaũku.
24 Baba olódodo ni yóò yọ̀ gidigidi: ẹni tí ó sì bí ọmọ ọlọ́gbọ́n, yóò ní ayọ̀ nínú rẹ̀.
Ithe wa mwana mũthingu arĩ gĩkeno kĩnene mũno; nake ũrĩa ũrĩ na mwana mũũgĩ nĩakenagio nĩwe.
25 Jẹ́ kí baba rẹ àti ìyá rẹ ó yọ̀, sì jẹ́ kí inú ẹni tí ó bí ọ dùn.
Thoguo na maitũguo marocanjamũka nĩ ũndũ waku; mũtumia ũrĩa wagũciarire arokena!
26 Ọmọ mi, fi àyà rẹ fún mi, kí o sì jẹ́ kí ojú rẹ ní inú dídùn sí ọ̀nà mi.
Mũrũ wakwa, heaga ngoro yaku, na ũreke maitho maku marũmagĩrĩre njĩra ciakwa,
27 Nítorí pé panṣágà obìnrin ọ̀gbun jíjìn ni; àti àjèjì obìnrin kànga híhá ni.
nĩgũkorwo mũmaraya nĩ irima iriku, nake mũtumia mũtharia nĩ gĩthima gĩkunderu.
28 Òun á sì ba ní bùba bí olè, a sì sọ àwọn olùrékọjá di púpọ̀ nínú àwọn ènìyàn.
Oohagĩria andũ njĩra-inĩ o ta njangiri, na nĩatũmaga kuongerereke andũ matarĩ ehokeku kĩrĩndĩ-inĩ.
29 Ta ni ó ni òsì? Ta ni ó ni ìbànújẹ́? Ta ni ó ni ìjà? Ta ni ó ni asọ̀? Ta ni ó ni ọgbẹ́ láìnídìí?
Nũũ ũrĩ na haaro? Nũũ ũrĩ na kĩeha? Nũũ ũrĩ hatĩka-inĩ? Nũũ ũrĩ na mateta? Nũũ ũgurarĩtio hatarĩ gĩtũmi? Nũũ ũtunĩhĩtie maitho?
30 Àwọn tí ó dúró pẹ́ níbi ọtí wáìnì; àwọn tí ń lọ láti dán ọtí wáìnì àdàlú wò.
Nĩ arĩa matindaga marũmanĩrĩire na ndibei, arĩa mathiiaga magĩcamaga mbakũri cia ndibei ĩrĩa ndukanie.
31 Ìwọ má ṣe wò ọtí wáìnì nígbà tí ó pọ́n, nígbà tí ó bá ń fi àwọ̀ rẹ̀ hàn nínú ago, tí a gbé e mì, tí ó ń dùn.
Tiga kwĩrorera ndibei rĩrĩa ĩtunĩhĩte, rĩrĩa ĩgũkenga ĩrĩ gĩkombe-inĩ, rĩrĩa ĩkũmerũka wega!
32 Níkẹyìn òun á bu ni ṣán bí ejò, a sì bunijẹ bí i paramọ́lẹ̀.
Mũthia-inĩ ĩrũmanaga ta nyoka, ĩgagũtheeca na thumu ta nduĩra.
33 Ojú rẹ yóò wò àwọn àjèjì obìnrin, àyà rẹ yóò sì sọ̀rọ̀ àyídáyidà.
Maitho maku makoonaga maũndũ mageni, na meciiria maku meciirie maũndũ ma waganu.
34 Nítòótọ́, ìwọ ó dàbí ẹni tí ó dùbúlẹ̀ ní àárín Òkun, tàbí ẹni tí ó dùbúlẹ̀ lókè-ọkọ̀.
Ũgaatuĩka ta mũndũ ũkomete iria-inĩ rĩrĩa inene gatagatĩ, o ta mũndũ ũkomete mũthia wa gĩtugĩ kĩa macua.
35 Ìwọ ó sì wí pé, “Wọ́n lù mí; kò dùn mí; wọ́n lù mí, èmi kò sì mọ̀: nígbà wo ni èmi ó jí? Èmi ó tún máa wá òmíràn láti mu.”
Nĩũkoiga atĩrĩ, “Ngũthĩtwo, no ndinatiihio! Nĩmahũũra, no ndinaigua ũndũ! Ngokĩra-rĩ, nĩguo ngacarie ĩngĩ ya kũnyua?”

< Proverbs 23 >