< Proverbs 23 >

1 Nígbà tí ìwọ bá jókòó láti bá ìjòyè jẹun, kíyèsi ohun tí ó wà níwájú rẹ gidigidi.
Si tu es à table avec un grand, fais attention à ce qui est devant toi.
2 Ìwọ a sì fi ọ̀bẹ lé ara rẹ ní ọ̀fun, bí ìwọ bá jẹ́ òkúndùn ènìyàn.
Mets un couteau à ta gorge, si tu as trop d'avidité.
3 Má ṣe fẹ́ oúnjẹ dídùn rẹ̀: nítorí pé oúnjẹ ẹ̀tàn ni.
Ne convoite pas ses mets délicats, c'est un aliment trompeur.
4 Má ṣe ṣe làálàá láti lọ́rọ̀: ṣíwọ́ kúrò nínú ọgbọ́n ara rẹ.
Ne te tourmente pas pour devenir riche, abstiens-toi d'y appliquer ton intelligence.
5 Ìwọ ó ha fi ojú rẹ lépa ohun tí kò sí? Nítorí tí ọ̀rọ̀ hu ìyẹ́ apá fún ara rẹ̀, ó sì ń fò bí idì ní ojú ọ̀run.
Veux-tu poursuivre du regard ce qui va s'évanouir? Car la richesse se fait des ailes, et, comme l'aigle, elle s'envole vers les cieux.
6 Má ṣe jẹ oúnjẹ ẹni tí ó háwọ́, bẹ́ẹ̀ ni kí o má sì ṣe fẹ́ oúnjẹ dídùn rẹ̀.
Ne mange pas le pain de l'homme envieux, et ne convoite pas ses mets délicats;
7 Nítorí pé bí ẹni tí ń ṣírò ní ọkàn rẹ̀, bẹ́ẹ̀ ni ó rí: “Máa jẹ, kí o sì máa mu,” ni ó ń wí fún ọ; ṣùgbọ́n ọkàn rẹ̀ kò pẹ̀lú rẹ.
car il ne vaut pas plus que les pensées de son âme. « Mange et bois, » te dira-t-il; mais son cœur n'est pas avec toi.
8 Òkèlè tí ìwọ jẹ ni ìwọ ó pọ̀ jáde, ìwọ a sì sọ ọ̀rọ̀ dídùn rẹ̀ nù.
Tu vomiras le morceau que tu as mangé, et tu en seras pour tes belles paroles.
9 Má ṣe sọ̀rọ̀ ní etí aṣiwèrè; nítorí tí yóò gan ọgbọ́n ọ̀rọ̀ rẹ.
Ne parle pas aux oreilles de l'insensé, car il méprisera la sagesse de tes discours.
10 Má ṣe ṣí ààlà àtijọ́ kúrò; má sì ṣe bọ́ sínú oko aláìní baba.
Ne déplace pas la borne antique, et n'entre pas dans le champ des orphelins.
11 Nítorí pé Olùràpadà wọn lágbára; yóò gba ìjà wọn jà sí ọ.
Car leur vengeur est puissant: il défendra leur cause contre toi.
12 Fi àyà sí ẹ̀kọ́, àti etí rẹ sí ọ̀rọ̀-ìmọ̀.
Applique ton cœur à l'instruction, et tes oreilles aux paroles de la science.
13 Má ṣe fa ọwọ́ ìbáwí sẹ́yìn kúrò lára ọmọdé, nítorí pé bí ìwọ bá fi pàṣán nà án, òun kì yóò kú.
N'épargne pas la correction à l'enfant; si tu le frappes de la verge, il ne mourra point.
14 Bí ìwọ fi pàṣán nà án, ìwọ ó sì gbà ọkàn rẹ̀ là kúrò ní ọ̀run àpáàdì. (Sheol h7585)
Tu le frappes de la verge, et tu délivres son âme du schéol. (Sheol h7585)
15 Ọmọ mi, bí ọkàn rẹ bá gbọ́n, ọkàn mi yóò yọ̀, àní èmi pẹ̀lú.
Mon fils, si ton cœur est sage, mon cœur, à moi aussi, sera dans la joie.
16 Inú mi yóò sì dùn nígbà tí ètè rẹ̀ bá ń sọ̀rọ̀ títọ́.
Mes entrailles tressailliront d'allégresse, quand tes lèvres diront ce qui est droit.
17 Má ṣe jẹ́ kí àyà rẹ ó ṣe ìlara sí àwọn ẹlẹ́ṣẹ̀, ṣùgbọ́n kí ìwọ ó wà ní ìbẹ̀rù Olúwa, ní ọjọ́ gbogbo.
Que ton cœur n'envie pas les pécheurs, mais qu'il reste toujours dans la crainte de Yahweh;
18 Nítorí pé ìgbẹ̀yìn ń bẹ nítòótọ́; ìrètí rẹ̀ kì yóò sì gé kúrò.
car il y a un avenir, et ton espérance ne sera pas anéantie.
19 Gbọ́, ìwọ ọmọ mi, kí o sì gbọ́n, kí o sì máa tọ́ àyà rẹ sí ọ̀nà títọ́.
Ecoute, mon fils, et sois sage; dirige ton cœur dans la voie droite.
20 Má ṣe wà nínú àwọn ọ̀mùtí; àti àwọn wọ̀bìà alájẹkì ọ̀jẹun;
Ne sois pas parmi les buveurs de vin, parmi ceux qui se gorgent de viandes;
21 nítorí pé ọ̀mùtí àti ọ̀jẹun ni yóò di tálákà; ìmúni-tòògbé ní sì ń fi àkísà wọ ọkùnrin láṣọ.
car le buveur et le gourmand s'appauvrissent, et la somnolence fait porter des haillons.
22 Fetí sí ti baba rẹ tí ó bí ọ, má sì ṣe gan ìyá rẹ, nígbà tí o bá gbó.
Ecoute ton père, lui qui t'a engendré, et ne méprise pas ta mère, quand elle est devenue vieille.
23 Ra òtítọ́, kí o má sì ṣe tà á; ra ọgbọ́n pẹ̀lú àti ẹ̀kọ́ àti òye.
Acquiers la vérité, et ne la vend pas, la sagesse, l'instruction et l'intelligence.
24 Baba olódodo ni yóò yọ̀ gidigidi: ẹni tí ó sì bí ọmọ ọlọ́gbọ́n, yóò ní ayọ̀ nínú rẹ̀.
Le père du juste est dans l'allégresse, celui qui donne le jour à un sage en aura de la joie.
25 Jẹ́ kí baba rẹ àti ìyá rẹ ó yọ̀, sì jẹ́ kí inú ẹni tí ó bí ọ dùn.
Que ton père et ta mère se réjouissent! Que celle qui t'a enfanté soit dans l'allégresse!
26 Ọmọ mi, fi àyà rẹ fún mi, kí o sì jẹ́ kí ojú rẹ ní inú dídùn sí ọ̀nà mi.
Mon fils, donne-moi ton cœur, et que tes yeux gardent mes voies:
27 Nítorí pé panṣágà obìnrin ọ̀gbun jíjìn ni; àti àjèjì obìnrin kànga híhá ni.
car la courtisane est une fosse profonde, et l'étrangère un puits étroit.
28 Òun á sì ba ní bùba bí olè, a sì sọ àwọn olùrékọjá di púpọ̀ nínú àwọn ènìyàn.
Elle dresse des embûches comme pour une proie et elle augmente parmi les hommes le nombre des prévaricateurs.
29 Ta ni ó ni òsì? Ta ni ó ni ìbànújẹ́? Ta ni ó ni ìjà? Ta ni ó ni asọ̀? Ta ni ó ni ọgbẹ́ láìnídìí?
Pour qui les ah? Pour qui les hélas? Pour qui les disputes? Pour qui les murmures? Pour qui les blessures sans raison? Pour qui les yeux rouges?...
30 Àwọn tí ó dúró pẹ́ níbi ọtí wáìnì; àwọn tí ń lọ láti dán ọtí wáìnì àdàlú wò.
Pour ceux qui s'attardent auprès du vin, pour ceux qui vont goûter du vin aromatisé.
31 Ìwọ má ṣe wò ọtí wáìnì nígbà tí ó pọ́n, nígbà tí ó bá ń fi àwọ̀ rẹ̀ hàn nínú ago, tí a gbé e mì, tí ó ń dùn.
Ne regarde pas le vin: comme il est vermeil; comme il donne son éclat dans la coupe, comme il coule aisément.
32 Níkẹyìn òun á bu ni ṣán bí ejò, a sì bunijẹ bí i paramọ́lẹ̀.
Il finit par mordre comme un serpent, et par piquer comme un basilic.
33 Ojú rẹ yóò wò àwọn àjèjì obìnrin, àyà rẹ yóò sì sọ̀rọ̀ àyídáyidà.
Tes yeux se porteront sur des étrangères, et ton cœur tiendra des discours pervers.
34 Nítòótọ́, ìwọ ó dàbí ẹni tí ó dùbúlẹ̀ ní àárín Òkun, tàbí ẹni tí ó dùbúlẹ̀ lókè-ọkọ̀.
Tu seras comme un homme couché au milieu de la mer, comme un homme endormi au sommet d'un mât.
35 Ìwọ ó sì wí pé, “Wọ́n lù mí; kò dùn mí; wọ́n lù mí, èmi kò sì mọ̀: nígbà wo ni èmi ó jí? Èmi ó tún máa wá òmíràn láti mu.”
« On m'a frappé... Je n'ai point de mal! On m'a battu... Je ne sens rien!... Quand me réveillerai-je?... Il m'en faut encore! »

< Proverbs 23 >