< Proverbs 22 >

1 Yíyan orúkọ rere sàn ju púpọ̀ ọrọ̀ lọ, àti ojúrere dára ju fàdákà àti wúrà lọ.
Cenniejsze [jest] dobre imię niż wielkie bogactwa, a przychylność lepsza niż srebro i złoto.
2 Ọlọ́rọ̀ àti tálákà péjọpọ̀: Olúwa ni ẹlẹ́dàá gbogbo wọn.
Bogaty i ubogi spotykają się, PAN jest stwórcą obydwu.
3 Ọlọ́gbọ́n ènìyàn ti rí ibi tẹ́lẹ̀, ó ṣé ara rẹ̀ mọ́: ṣùgbọ́n àwọn òpè tẹ̀síwájú, a sì jẹ wọ́n ní yà.
Roztropny dostrzega zło i ukrywa się, ale prości idą dalej i ponoszą karę.
4 Èrè ìrẹ̀lẹ̀ àti ìbẹ̀rù Olúwa ni ọrọ̀ ọlá, àti ìyè.
Owocem pokory i bojaźni PANA jest bogactwo, chwała i życie.
5 Ègún àti ìdẹ̀kùn ń bẹ ní ọ̀nà aláyídáyidà: ẹni tí ó bá pa ọkàn rẹ̀ mọ́ yóò jìnnà sí wọn.
Ciernie i sidła [są] na drodze przewrotnego; kto strzeże swej duszy, trzyma się z dala od nich.
6 Tọ́ ọmọdé ní ọ̀nà tí yóò tọ̀: nígbà tí ó bá dàgbà, kì yóò kúrò nínú rẹ̀.
Pouczaj dziecko w drodze, którą ma iść, a gdy się zestarzeje, nie odstąpi od niej.
7 Ọlọ́rọ̀ ṣe olórí olùpọ́njú, ajigbèsè sì ṣe ìránṣẹ́ fún ẹni tí a jẹ ní gbèsè.
Bogaty panuje nad ubogimi, a ten, co pożycza, jest sługą tego, który mu pożycza.
8 Ẹni tí ó bá fúnrúgbìn ẹ̀ṣẹ̀, yóò ká asán: ọ̀pá ìbínú rẹ̀ yóò kùnà.
Kto sieje nieprawość, będzie żąć cierpienie, a rózga jego gniewu przepadnie.
9 Ẹni tí ó ní ojú àánú ni a ó bùkún fún; nítorí tí ó fi nínú oúnjẹ rẹ̀ fún olùpọ́njú.
Kto ma dobrotliwe oko, będzie błogosławiony, bo dzieli się swym chlebem z ubogim.
10 Lé ẹlẹ́gàn sí ìta, ìjà yóò sì jáde; nítòótọ́ ìjà àti ẹ̀gàn yóò dẹ́kun.
Wyrzuć szydercę, a ustanie spór, owszem, zakończy się kłótnia i zniewaga.
11 Ẹni tí ó fẹ́ ìwà funfun ti àyà, tí ó sì ń sọ̀rọ̀ iyì jáde, ọba yóò ṣe ọ̀rẹ́ rẹ̀.
Kto kocha czystość serca, tego wdzięk warg sprawi, że król [będzie] jego przyjacielem.
12 Ojú Olúwa pa ìmọ̀ mọ́, ó sì yí ọ̀rọ̀ olùrékọjá pò.
Oczy PANA strzegą wiedzy, a on obala słowa przewrotnego.
13 Ọ̀lẹ wí pé, “Kìnnìún ń bẹ lóde! Yóò pa mí ní ìgboro!”
Leniwy mówi: Lew jest na dworze, będę zabity na środku ulicy.
14 Ẹnu àwọn àjèjì obìnrin, ihò jíjìn ni; ẹni tí a ń bínú sí láti ọ̀dọ̀ Olúwa wá ni yóò ṣubú sínú rẹ̀.
Usta obcych [kobiet są] głębokim dołem; wpadnie tam ten, na kogo PAN się gniewa.
15 Àyà ọmọdé ni ìwà wèrè dì sí; ṣùgbọ́n pàṣán ìtọ́ni ni yóò lé e jìnnà kúrò lọ́dọ̀ rẹ̀.
Głupota jest przywiązana do serca dziecka, ale rózga karności wypędzi ją z niego.
16 Ẹni tó ń ni tálákà lára láti ní ọrọ̀, tí ó sì ń ta ọlọ́rọ̀ lọ́rẹ, yóò di aláìní bí ó ti wù kó rí. Gbọ́ ọ̀rọ̀ ọlọ́gbọ́n ènìyàn.
Kto ciemięży ubogiego, aby przysporzyć sobie [bogactwa, i] kto daje bogatemu, pewnie zubożeje.
17 Dẹtí rẹ sílẹ̀, kí o gbọ́ ọ̀rọ̀ àwọn ọlọ́gbọ́n, kí o sì fi àyà rẹ sí ẹ̀kọ́ mi.
Nadstaw ucha i słuchaj słów mędrców, i skłoń swe serce do mojej wiedzy;
18 Nítorí ohun dídùn ni bí ìwọ bá pa wọ́n mọ́ ní inú rẹ; nígbà tí a sì pèsè wọn tán ní ètè rẹ.
Bo to miło, jeśli zachowasz je w swoim sercu, będą razem ułożone na wargach.
19 Kí ìgbẹ́kẹ̀lé rẹ lè wà ní ti Olúwa, èmi fihàn ọ́ lónìí, àní fún ọ.
Oznajmiłem to dzisiaj właśnie tobie, abyś pokładał ufność w PANU.
20 Èmi kò ha ti kọ̀wé ohun dáradára sí ọ ní ti ìmọ̀ràn àti ní ti ẹ̀kọ́,
Czy nie napisałem ci znamienitych rzeczy zawierających rady i wiedzę;
21 kí ó lè mú ọ mọ ìdájú ọ̀rọ̀ òtítọ́; kí ìwọ le máa fi ìdáhùn òtítọ́ fún àwọn tí ó rán ọ?
Aby dać ci poznać pewność słów prawdy; abyś umiał odpowiedzieć słowami prawdy tym, którzy do ciebie posyłają?
22 Má ṣe ja tálákà ní olè, nítorí tí ó jẹ́ tálákà: bẹ́ẹ̀ ni kí o má sì ṣe ni olùpọ́njú lára ní ibodè,
Nie okradaj nędzarza, ponieważ jest ubogi, ani nie uciskaj w bramie biednego.
23 nítorí Olúwa yóò gbèjà wọn, yóò sì gba ọkàn àwọn tí ń gba tiwọn náà.
PAN bowiem będzie bronił ich sprawy i wydrze duszę tym, którzy im wydzierają.
24 Má ṣe bá oníbìínú ènìyàn ṣe ọ̀rẹ́; má sì ṣe bá ọkùnrin onínú-fùfù rìn.
Nie przyjaźnij się z człowiekiem gniewliwym i nie obcuj z człowiekiem porywczym.
25 Kí ìwọ má ba à kọ́ ìwà rẹ̀, ìwọ a sì gba ìkẹ́kùn fún ara rẹ.
Byś nie przywykł do jego dróg i nie zastawił sideł na swą duszę.
26 Má ṣe wà nínú àwọn tí ń ṣe ìgbọ̀nwọ́, tàbí nínú àwọn tí ó dúró fún gbèsè.
Nie bądź z tych, którzy dają porękę, ani z tych, którzy ręczą za długi;
27 Bí ìwọ kò bá ní nǹkan tí ìwọ ó fi san, nítorí kín ni yóò ṣe gba ẹni rẹ kúrò lábẹ́ rẹ?
Jeśli nie masz czym zapłacić, dlaczego miałby ktoś zabrać spod ciebie posłanie?
28 Má ṣe yẹ ààlà ilẹ̀ ìgbàanì, tí àwọn baba rẹ ti pa.
Nie przesuwaj dawnej granicy, którą ustalili twoi ojcowie.
29 Ìwọ ha rí ènìyàn tí ó ń fi àìṣe ìmẹ́lẹ́ ṣe iṣẹ́ rẹ̀? Òun yóò dúró níwájú àwọn ọba; òun kì yóò dúró níwájú àwọn ènìyàn lásán.
Widzisz człowieka pilnego w swoich sprawach? On będzie stał przed królami, nie będzie stał przed podłymi.

< Proverbs 22 >