< Proverbs 22 >
1 Yíyan orúkọ rere sàn ju púpọ̀ ọrọ̀ lọ, àti ojúrere dára ju fàdákà àti wúrà lọ.
Kivánatosb a jó hírnév nagy gazdagságnál; ezüstnél és aranynál a kedvesség jobb.
2 Ọlọ́rọ̀ àti tálákà péjọpọ̀: Olúwa ni ẹlẹ́dàá gbogbo wọn.
A gazdag és szegény összetalálkoznak, mindkettőt pedig az Úr szerzi.
3 Ọlọ́gbọ́n ènìyàn ti rí ibi tẹ́lẹ̀, ó ṣé ara rẹ̀ mọ́: ṣùgbọ́n àwọn òpè tẹ̀síwájú, a sì jẹ wọ́n ní yà.
Az eszes meglátja a bajt és elrejti magát; a bolondok pedig neki mennek és kárát vallják.
4 Èrè ìrẹ̀lẹ̀ àti ìbẹ̀rù Olúwa ni ọrọ̀ ọlá, àti ìyè.
Az alázatosságnak bére az Úr félelme, gazdagság és tisztesség és élet.
5 Ègún àti ìdẹ̀kùn ń bẹ ní ọ̀nà aláyídáyidà: ẹni tí ó bá pa ọkàn rẹ̀ mọ́ yóò jìnnà sí wọn.
Tövisek és tőrök vannak a gonosznak útában; a ki megőrzi a maga lelkét, távol jár azoktól.
6 Tọ́ ọmọdé ní ọ̀nà tí yóò tọ̀: nígbà tí ó bá dàgbà, kì yóò kúrò nínú rẹ̀.
Tanítsd a gyermeket az ő útjának módja szerint; még mikor megvénhedik is, el nem távozik attól.
7 Ọlọ́rọ̀ ṣe olórí olùpọ́njú, ajigbèsè sì ṣe ìránṣẹ́ fún ẹni tí a jẹ ní gbèsè.
A gazdag a szegényeken uralkodik, és szolgája a kölcsönvevő a kölcsönadónak.
8 Ẹni tí ó bá fúnrúgbìn ẹ̀ṣẹ̀, yóò ká asán: ọ̀pá ìbínú rẹ̀ yóò kùnà.
A ki vet álnokságot, arat nyomorúságot; és az ő haragjának vesszeje megtöretik.
9 Ẹni tí ó ní ojú àánú ni a ó bùkún fún; nítorí tí ó fi nínú oúnjẹ rẹ̀ fún olùpọ́njú.
Az irgalmas szemű ember megáldatik, mert adott az ő kenyeréből a szegénynek.
10 Lé ẹlẹ́gàn sí ìta, ìjà yóò sì jáde; nítòótọ́ ìjà àti ẹ̀gàn yóò dẹ́kun.
Űzd el a csúfolót, és elmegy a háborgás is, és megszünik a patvarkodás és a szidalmazás.
11 Ẹni tí ó fẹ́ ìwà funfun ti àyà, tí ó sì ń sọ̀rọ̀ iyì jáde, ọba yóò ṣe ọ̀rẹ́ rẹ̀.
A ki szereti a szívnek tisztaságát, beszéde kedvesség: annak barátja a király.
12 Ojú Olúwa pa ìmọ̀ mọ́, ó sì yí ọ̀rọ̀ olùrékọjá pò.
Az Úrnak szemei megőrzik a tudományt; a hitetlennek beszédét pedig felforgatja.
13 Ọ̀lẹ wí pé, “Kìnnìún ń bẹ lóde! Yóò pa mí ní ìgboro!”
A rest azt mondja: oroszlán van ottkin, az utczák közepén megölettetném.
14 Ẹnu àwọn àjèjì obìnrin, ihò jíjìn ni; ẹni tí a ń bínú sí láti ọ̀dọ̀ Olúwa wá ni yóò ṣubú sínú rẹ̀.
Mély verem az idegen asszonyoknak szája; a kire haragszik az Úr, oda esik.
15 Àyà ọmọdé ni ìwà wèrè dì sí; ṣùgbọ́n pàṣán ìtọ́ni ni yóò lé e jìnnà kúrò lọ́dọ̀ rẹ̀.
A gyermek elméjéhez köttetett a bolondság; de a fenyítés vesszeje messze elűzi ő tőle azt.
16 Ẹni tó ń ni tálákà lára láti ní ọrọ̀, tí ó sì ń ta ọlọ́rọ̀ lọ́rẹ, yóò di aláìní bí ó ti wù kó rí. Gbọ́ ọ̀rọ̀ ọlọ́gbọ́n ènìyàn.
A ki elnyomja a szegényt, hogy szaporítsa az ő marháját; a ki ád a gazdagnak: végre szűkölködésre jut.
17 Dẹtí rẹ sílẹ̀, kí o gbọ́ ọ̀rọ̀ àwọn ọlọ́gbọ́n, kí o sì fi àyà rẹ sí ẹ̀kọ́ mi.
Hajtsd füledet, és hallgasd a bölcseknek beszédeit; és a te elmédet figyelmeztesd az én tudományomra.
18 Nítorí ohun dídùn ni bí ìwọ bá pa wọ́n mọ́ ní inú rẹ; nígbà tí a sì pèsè wọn tán ní ètè rẹ.
Mert gyönyörűséges lesz, ha megtartod azokat szívedben; legyenek együtt állandók a te ajkaidon!
19 Kí ìgbẹ́kẹ̀lé rẹ lè wà ní ti Olúwa, èmi fihàn ọ́ lónìí, àní fún ọ.
Hogy az Úrban legyen a te bizodalmad, arra tanítottalak ma téged, igen, téged.
20 Èmi kò ha ti kọ̀wé ohun dáradára sí ọ ní ti ìmọ̀ràn àti ní ti ẹ̀kọ́,
Nem írtam-é néked drága szép tanulságokat, tanácsokban és tudományban?
21 kí ó lè mú ọ mọ ìdájú ọ̀rọ̀ òtítọ́; kí ìwọ le máa fi ìdáhùn òtítọ́ fún àwọn tí ó rán ọ?
Hogy tudtodra adjam néked az igazság beszédinek bizonyos voltát: hogy igaz beszédet vígy válaszul elküldőidnek.
22 Má ṣe ja tálákà ní olè, nítorí tí ó jẹ́ tálákà: bẹ́ẹ̀ ni kí o má sì ṣe ni olùpọ́njú lára ní ibodè,
Ne rabold ki a szegényt, mert szegény ő; és meg ne rontsd a nyomorultat a kapuban;
23 nítorí Olúwa yóò gbèjà wọn, yóò sì gba ọkàn àwọn tí ń gba tiwọn náà.
Mert az Úr forgatja azoknak ügyét, és az ő kirablóik életét elragadja.
24 Má ṣe bá oníbìínú ènìyàn ṣe ọ̀rẹ́; má sì ṣe bá ọkùnrin onínú-fùfù rìn.
Ne tarts barátságot a haragossal, és a dühösködővel ne menj;
25 Kí ìwọ má ba à kọ́ ìwà rẹ̀, ìwọ a sì gba ìkẹ́kùn fún ara rẹ.
Hogy el ne tanuld az ő útait, és tőrt ne keress tennen magadnak.
26 Má ṣe wà nínú àwọn tí ń ṣe ìgbọ̀nwọ́, tàbí nínú àwọn tí ó dúró fún gbèsè.
Ne légy azok közt, a kik kézbe csapnak, a kik adósságért kezeskednek.
27 Bí ìwọ kò bá ní nǹkan tí ìwọ ó fi san, nítorí kín ni yóò ṣe gba ẹni rẹ kúrò lábẹ́ rẹ?
Ha nincs néked miből megadnod; miért vegye el a te ágyadat te alólad?
28 Má ṣe yẹ ààlà ilẹ̀ ìgbàanì, tí àwọn baba rẹ ti pa.
Ne bontsd el a régi határt, melyet csináltak a te eleid.
29 Ìwọ ha rí ènìyàn tí ó ń fi àìṣe ìmẹ́lẹ́ ṣe iṣẹ́ rẹ̀? Òun yóò dúró níwájú àwọn ọba; òun kì yóò dúró níwájú àwọn ènìyàn lásán.
Láttál-é az ő dolgában szorgalmatos embert? A királyok előtt álland, nem marad meg az alsó rendűek között.