< Proverbs 22 >
1 Yíyan orúkọ rere sàn ju púpọ̀ ọrọ̀ lọ, àti ojúrere dára ju fàdákà àti wúrà lọ.
Becsesebb a név nagy gazdagságnál, ezüstnél és aranynál jobb a kedvesség.
2 Ọlọ́rọ̀ àti tálákà péjọpọ̀: Olúwa ni ẹlẹ́dàá gbogbo wọn.
Gazdag és szegény találkoztak; mindnyájuk alkotója az Örökkévaló.
3 Ọlọ́gbọ́n ènìyàn ti rí ibi tẹ́lẹ̀, ó ṣé ara rẹ̀ mọ́: ṣùgbọ́n àwọn òpè tẹ̀síwájú, a sì jẹ wọ́n ní yà.
Az okos látta a bajt és elrejtőzött, de az együgyűek tova haladtak és lakoltak.
4 Èrè ìrẹ̀lẹ̀ àti ìbẹ̀rù Olúwa ni ọrọ̀ ọlá, àti ìyè.
Nyomában az alázatosságnak, az istenfélelemnek van gazdagság és dicsőség és élet.
5 Ègún àti ìdẹ̀kùn ń bẹ ní ọ̀nà aláyídáyidà: ẹni tí ó bá pa ọkàn rẹ̀ mọ́ yóò jìnnà sí wọn.
Tövisek, tőrök vannak az álnok útján; a ki lelkét megőrzi, távol marad tőlük.
6 Tọ́ ọmọdé ní ọ̀nà tí yóò tọ̀: nígbà tí ó bá dàgbà, kì yóò kúrò nínú rẹ̀.
Neveld a fiút az ő módja szerint, ha megöregszik sem tér el attól.
7 Ọlọ́rọ̀ ṣe olórí olùpọ́njú, ajigbèsè sì ṣe ìránṣẹ́ fún ẹni tí a jẹ ní gbèsè.
A gazdag uralkodik a szegényeken, és szolgája a kölcsönvevő a kölcsönadó embernek.
8 Ẹni tí ó bá fúnrúgbìn ẹ̀ṣẹ̀, yóò ká asán: ọ̀pá ìbínú rẹ̀ yóò kùnà.
A ki jogtalanságot vet, bajt fog aratni, és haragjának vesszeje megsemmisül.
9 Ẹni tí ó ní ojú àánú ni a ó bùkún fún; nítorí tí ó fi nínú oúnjẹ rẹ̀ fún olùpọ́njú.
A ki jóságos szemű, az meg fog áldatni, mert kenyeréből adott a szegénynek.
10 Lé ẹlẹ́gàn sí ìta, ìjà yóò sì jáde; nítòótọ́ ìjà àti ẹ̀gàn yóò dẹ́kun.
Űzd el a csúfolót és elmegy a viszály, s megszűnik per és szégyen.
11 Ẹni tí ó fẹ́ ìwà funfun ti àyà, tí ó sì ń sọ̀rọ̀ iyì jáde, ọba yóò ṣe ọ̀rẹ́ rẹ̀.
Szereti a tiszta szívűt, barátja a kedves ajkúnak a király.
12 Ojú Olúwa pa ìmọ̀ mọ́, ó sì yí ọ̀rọ̀ olùrékọjá pò.
Az Örökkévaló szemei megóvták a tudást és ő elferdítette a hűtelennek szavait.
13 Ọ̀lẹ wí pé, “Kìnnìún ń bẹ lóde! Yóò pa mí ní ìgboro!”
Mondta a rest: oroszlán van az utczán, a piaczok közepén meg fognak engem ölni.
14 Ẹnu àwọn àjèjì obìnrin, ihò jíjìn ni; ẹni tí a ń bínú sí láti ọ̀dọ̀ Olúwa wá ni yóò ṣubú sínú rẹ̀.
Mélységes gödör idegen nők szája, az Örökkévaló átkozottja esik oda bele.
15 Àyà ọmọdé ni ìwà wèrè dì sí; ṣùgbọ́n pàṣán ìtọ́ni ni yóò lé e jìnnà kúrò lọ́dọ̀ rẹ̀.
Az oktalanság hozzá van kötve a fiú szívéhez, a, fenyítés pálczája eltávolítja tőle.
16 Ẹni tó ń ni tálákà lára láti ní ọrọ̀, tí ó sì ń ta ọlọ́rọ̀ lọ́rẹ, yóò di aláìní bí ó ti wù kó rí. Gbọ́ ọ̀rọ̀ ọlọ́gbọ́n ènìyàn.
A ki fosztogatja a szegényt, hogy a magáét gyarapítsa, a gazdagnak ad majd – bizony szűkölködésre jut.
17 Dẹtí rẹ sílẹ̀, kí o gbọ́ ọ̀rọ̀ àwọn ọlọ́gbọ́n, kí o sì fi àyà rẹ sí ẹ̀kọ́ mi.
Hajlítsd füledet és halljad a bölcsek szavait, és szívedet fordítsd tudásomra.
18 Nítorí ohun dídùn ni bí ìwọ bá pa wọ́n mọ́ ní inú rẹ; nígbà tí a sì pèsè wọn tán ní ètè rẹ.
Mert kellemes az, hogy megőrzöd kebledben, megszilárdulnak egyaránt ajkaidon.
19 Kí ìgbẹ́kẹ̀lé rẹ lè wà ní ti Olúwa, èmi fihàn ọ́ lónìí, àní fún ọ.
Hogy az Örökkévalóban legyen bizodalmad, te veled is tudattam e napon.
20 Èmi kò ha ti kọ̀wé ohun dáradára sí ọ ní ti ìmọ̀ràn àti ní ti ẹ̀kọ́,
Nemde fölírtam neked kiváló dolgokat, tanácsokkal és tudással;
21 kí ó lè mú ọ mọ ìdájú ọ̀rọ̀ òtítọ́; kí ìwọ le máa fi ìdáhùn òtítọ́ fún àwọn tí ó rán ọ?
hogy tudassak veled valódiságot, igaz mondásokat, hogy küldőidnek válaszolhass igaz mondásokkal.
22 Má ṣe ja tálákà ní olè, nítorí tí ó jẹ́ tálákà: bẹ́ẹ̀ ni kí o má sì ṣe ni olùpọ́njú lára ní ibodè,
Ne rabold meg a szegényt, mivel szegény, s ne zúzd össze a nyomorút a kapuban;
23 nítorí Olúwa yóò gbèjà wọn, yóò sì gba ọkàn àwọn tí ń gba tiwọn náà.
mert az Örökkévaló viszi ügyüket s megfosztja kifosztóikat az élettől.
24 Má ṣe bá oníbìínú ènìyàn ṣe ọ̀rẹ́; má sì ṣe bá ọkùnrin onínú-fùfù rìn.
Ne barátkozzál haragos emberrel és heveskedő férfival ne jöjj össze;
25 Kí ìwọ má ba à kọ́ ìwà rẹ̀, ìwọ a sì gba ìkẹ́kùn fún ara rẹ.
nehogy eltanuljad az ő ösvényét és tőrt szereznél lelkednek.
26 Má ṣe wà nínú àwọn tí ń ṣe ìgbọ̀nwọ́, tàbí nínú àwọn tí ó dúró fún gbèsè.
Ne légy azok közt, kik kézbe csapnak, a kik kezeskednek adósságokért;
27 Bí ìwọ kò bá ní nǹkan tí ìwọ ó fi san, nítorí kín ni yóò ṣe gba ẹni rẹ kúrò lábẹ́ rẹ?
ha nincs neked miből fizetni, miért vegye el ágyadat alólad.
28 Má ṣe yẹ ààlà ilẹ̀ ìgbàanì, tí àwọn baba rẹ ti pa.
Ne told el az ősrégi határt, melyet vetettek az őseid.
29 Ìwọ ha rí ènìyàn tí ó ń fi àìṣe ìmẹ́lẹ́ ṣe iṣẹ́ rẹ̀? Òun yóò dúró níwájú àwọn ọba; òun kì yóò dúró níwájú àwọn ènìyàn lásán.
Láttál valakit, a ki ügyes az ő munkájában, királyok előtt állhat, ne álljon a sötét sorban levők előtt.