< Proverbs 22 >

1 Yíyan orúkọ rere sàn ju púpọ̀ ọrọ̀ lọ, àti ojúrere dára ju fàdákà àti wúrà lọ.
Mieux vaux une bonne renommée que beaucoup de richesses: au-dessus de l’argent et de l’or est la bonne amitié.
2 Ọlọ́rọ̀ àti tálákà péjọpọ̀: Olúwa ni ẹlẹ́dàá gbogbo wọn.
Le riche et le pauvre se sont rencontrés. Le créateur de l’un et de l’autre, c’est le Seigneur.
3 Ọlọ́gbọ́n ènìyàn ti rí ibi tẹ́lẹ̀, ó ṣé ara rẹ̀ mọ́: ṣùgbọ́n àwọn òpè tẹ̀síwájú, a sì jẹ wọ́n ní yà.
l’homme habile a vu le mal et s’est caché: le simple a passé outre et il a souffert du dommage.
4 Èrè ìrẹ̀lẹ̀ àti ìbẹ̀rù Olúwa ni ọrọ̀ ọlá, àti ìyè.
La fin de la modestie est la crainte du Seigneur, les richesses, la gloire et la vie.
5 Ègún àti ìdẹ̀kùn ń bẹ ní ọ̀nà aláyídáyidà: ẹni tí ó bá pa ọkàn rẹ̀ mọ́ yóò jìnnà sí wọn.
Des armes et des glaives se trouvent sur la voie du pervers; mais celui qui garde son âme s’en retire bien loin.
6 Tọ́ ọmọdé ní ọ̀nà tí yóò tọ̀: nígbà tí ó bá dàgbà, kì yóò kúrò nínú rẹ̀.
C’est un proverbe: Le jeune homme suit sa voie; lors même qu’il sera vieux, il ne s’en écartera pas.
7 Ọlọ́rọ̀ ṣe olórí olùpọ́njú, ajigbèsè sì ṣe ìránṣẹ́ fún ẹni tí a jẹ ní gbèsè.
Le riche commande aux pauvres; et celui qui emprunte est l’esclave de celui qui prête.
8 Ẹni tí ó bá fúnrúgbìn ẹ̀ṣẹ̀, yóò ká asán: ọ̀pá ìbínú rẹ̀ yóò kùnà.
Celui qui sème l’iniquité moissonnera des maux, et par la verge de sa colère il sera détruit.
9 Ẹni tí ó ní ojú àánú ni a ó bùkún fún; nítorí tí ó fi nínú oúnjẹ rẹ̀ fún olùpọ́njú.
Celui qui est porté à la miséricorde sera béni: il a donné de son pain au pauvre. Il obtiendra la victoire et l’honneur, celui qui fait des présents; mais il ravit l’âme de ceux qui les reçoivent.
10 Lé ẹlẹ́gàn sí ìta, ìjà yóò sì jáde; nítòótọ́ ìjà àti ẹ̀gàn yóò dẹ́kun.
Chasse le railleur, et s’en ira avec lui la querelle, et cesseront les plaintes et les outrages.
11 Ẹni tí ó fẹ́ ìwà funfun ti àyà, tí ó sì ń sọ̀rọ̀ iyì jáde, ọba yóò ṣe ọ̀rẹ́ rẹ̀.
Celui qui aime la pureté du cœur, à cause de la grâce de ses lèvres, aura pour ami le roi.
12 Ojú Olúwa pa ìmọ̀ mọ́, ó sì yí ọ̀rọ̀ olùrékọjá pò.
Les yeux du Seigneur gardent la science; mais les paroles de l’homme inique sont confondues.
13 Ọ̀lẹ wí pé, “Kìnnìún ń bẹ lóde! Yóò pa mí ní ìgboro!”
Le paresseux dit: Le lion est dehors, au milieu des rues je dois être tué.
14 Ẹnu àwọn àjèjì obìnrin, ihò jíjìn ni; ẹni tí a ń bínú sí láti ọ̀dọ̀ Olúwa wá ni yóò ṣubú sínú rẹ̀.
C’est une fosse profonde que la bouche de l’étrangère; celui contre qui le Seigneur est irrité y tombera.
15 Àyà ọmọdé ni ìwà wèrè dì sí; ṣùgbọ́n pàṣán ìtọ́ni ni yóò lé e jìnnà kúrò lọ́dọ̀ rẹ̀.
La folie est liée au cœur de l’enfant, et la verge de la discipline la fera fuir.
16 Ẹni tó ń ni tálákà lára láti ní ọrọ̀, tí ó sì ń ta ọlọ́rọ̀ lọ́rẹ, yóò di aláìní bí ó ti wù kó rí. Gbọ́ ọ̀rọ̀ ọlọ́gbọ́n ènìyàn.
Celui qui opprime le pauvre pour augmenter ses richesses donnera lui-même à un plus riche et sera dans la détresse.
17 Dẹtí rẹ sílẹ̀, kí o gbọ́ ọ̀rọ̀ àwọn ọlọ́gbọ́n, kí o sì fi àyà rẹ sí ẹ̀kọ́ mi.
Incline ton oreille, et écoute les paroles des sages; applique ton cœur à ma doctrine.
18 Nítorí ohun dídùn ni bí ìwọ bá pa wọ́n mọ́ ní inú rẹ; nígbà tí a sì pèsè wọn tán ní ètè rẹ.
Elle sera belle pour toi, lorsque tu la garderas au fond de ton cœur, et elle se répandra sur tes lèvres;
19 Kí ìgbẹ́kẹ̀lé rẹ lè wà ní ti Olúwa, èmi fihàn ọ́ lónìí, àní fún ọ.
Afin que ta confiance soit dans le Seigneur: c’est pour cela que je te l’ai montrée aujourd’hui,
20 Èmi kò ha ti kọ̀wé ohun dáradára sí ọ ní ti ìmọ̀ràn àti ní ti ẹ̀kọ́,
Voilà que je te l’ai décrite triplement, avec réflexion et science;
21 kí ó lè mú ọ mọ ìdájú ọ̀rọ̀ òtítọ́; kí ìwọ le máa fi ìdáhùn òtítọ́ fún àwọn tí ó rán ọ?
Afin de te montrer la certitude et les paroles de la vérité, pour répondre à ceux qui t’ont envoyé.
22 Má ṣe ja tálákà ní olè, nítorí tí ó jẹ́ tálákà: bẹ́ẹ̀ ni kí o má sì ṣe ni olùpọ́njú lára ní ibodè,
Ne fais point violence au pauvre, parce qu’il est pauvre: et ne brise pas l’indigent à la porte;
23 nítorí Olúwa yóò gbèjà wọn, yóò sì gba ọkàn àwọn tí ń gba tiwọn náà.
Parce que le Seigneur jugera sa cause, et il percera ceux qui ont percé son âme.
24 Má ṣe bá oníbìínú ènìyàn ṣe ọ̀rẹ́; má sì ṣe bá ọkùnrin onínú-fùfù rìn.
Ne sois pas ami d’un homme colère, et ne marche pas avec un homme furieux;
25 Kí ìwọ má ba à kọ́ ìwà rẹ̀, ìwọ a sì gba ìkẹ́kùn fún ara rẹ.
De peur que tu n’apprennes ses voies, et que tu n’en retires un scandale pour ton âme.
26 Má ṣe wà nínú àwọn tí ń ṣe ìgbọ̀nwọ́, tàbí nínú àwọn tí ó dúró fún gbèsè.
Ne sois point avec ceux qui engagent leurs mains, et qui se rendent caution des dettes;
27 Bí ìwọ kò bá ní nǹkan tí ìwọ ó fi san, nítorí kín ni yóò ṣe gba ẹni rẹ kúrò lábẹ́ rẹ?
Car si tu n’as pas de quoi rendre, quel motif y a-t-il pour qu’il emporte la couverture de ton lit?
28 Má ṣe yẹ ààlà ilẹ̀ ìgbàanì, tí àwọn baba rẹ ti pa.
Ne dépasse pas les anciennes bornes qu’ont posées tes pères.
29 Ìwọ ha rí ènìyàn tí ó ń fi àìṣe ìmẹ́lẹ́ ṣe iṣẹ́ rẹ̀? Òun yóò dúró níwájú àwọn ọba; òun kì yóò dúró níwájú àwọn ènìyàn lásán.
As-tu vu un homme prompt dans son œuvre? il se tiendra devant les rois, et il ne sera pas devant les hommes obscurs.

< Proverbs 22 >