< Proverbs 22 >

1 Yíyan orúkọ rere sàn ju púpọ̀ ọrọ̀ lọ, àti ojúrere dára ju fàdákà àti wúrà lọ.
Une bonne renommée vaut mieux que de grandes richesses; la bonne grâce vaut mieux que l'or et l'argent.
2 Ọlọ́rọ̀ àti tálákà péjọpọ̀: Olúwa ni ẹlẹ́dàá gbogbo wọn.
Le riche et le pauvre se sont rencontrés; c'est le Seigneur qui les a créé tous les deux.
3 Ọlọ́gbọ́n ènìyàn ti rí ibi tẹ́lẹ̀, ó ṣé ara rẹ̀ mọ́: ṣùgbọ́n àwọn òpè tẹ̀síwájú, a sì jẹ wọ́n ní yà.
L'homme habile, en voyant le pervers sévèrement châtié, se corrige lui- même; les imprudents passent outre, et sont punis à leur tour.
4 Èrè ìrẹ̀lẹ̀ àti ìbẹ̀rù Olúwa ni ọrọ̀ ọlá, àti ìyè.
La crainte du Seigneur fait naître la sagesse, et les biens, et la gloire, et la vie.
5 Ègún àti ìdẹ̀kùn ń bẹ ní ọ̀nà aláyídáyidà: ẹni tí ó bá pa ọkàn rẹ̀ mọ́ yóò jìnnà sí wọn.
Les chausse-trapes et les filets sont dans les voies tortueuses; mais celui qui garde son âme les évitera.
6 Tọ́ ọmọdé ní ọ̀nà tí yóò tọ̀: nígbà tí ó bá dàgbà, kì yóò kúrò nínú rẹ̀.
7 Ọlọ́rọ̀ ṣe olórí olùpọ́njú, ajigbèsè sì ṣe ìránṣẹ́ fún ẹni tí a jẹ ní gbèsè.
Les riches commanderont aux pauvres, et des serviteurs prêteront à usure à leurs propres maîtres.
8 Ẹni tí ó bá fúnrúgbìn ẹ̀ṣẹ̀, yóò ká asán: ọ̀pá ìbínú rẹ̀ yóò kùnà.
Qui sème la méchanceté récoltera le malheur, et il recevra le châtiment de ses œuvres. Dieu bénit l'homme joyeux et libéral; mais le mauvais semeur sera puni par la vanité même de ses travaux.
9 Ẹni tí ó ní ojú àánú ni a ó bùkún fún; nítorí tí ó fi nínú oúnjẹ rẹ̀ fún olùpọ́njú.
Celui qui a pitié des pauvres sera lui-même nourri; car il a donné de son pain au mendiant. Celui qui donne des présents se prépare victoire et honneur; mais il perd l'âme de ceux qui les acceptent.
10 Lé ẹlẹ́gàn sí ìta, ìjà yóò sì jáde; nítòótọ́ ìjà àti ẹ̀gàn yóò dẹ́kun.
Chassez de l'assemblée l'homme de pestilence; la discorde en sortira avec lui; car, lorsqu'il s'y assied, il la déshonore tout entière.
11 Ẹni tí ó fẹ́ ìwà funfun ti àyà, tí ó sì ń sọ̀rọ̀ iyì jáde, ọba yóò ṣe ọ̀rẹ́ rẹ̀.
Le Seigneur aime les cœurs saints, et tous les innocents Lui sont agréables; un roi gouverne à la parole.
12 Ojú Olúwa pa ìmọ̀ mọ́, ó sì yí ọ̀rọ̀ olùrékọjá pò.
Les yeux du Seigneur surveillent la doctrine; le pervers méprise Sa parole.
13 Ọ̀lẹ wí pé, “Kìnnìún ń bẹ lóde! Yóò pa mí ní ìgboro!”
Le paresseux apporte des excuses, et dit: Il y a un lion sur le chemin, et des assassins dans les rues.
14 Ẹnu àwọn àjèjì obìnrin, ihò jíjìn ni; ẹni tí a ń bínú sí láti ọ̀dọ̀ Olúwa wá ni yóò ṣubú sínú rẹ̀.
La bouche des méchants est un profond abîme; celui qui hait le Seigneur y tombera. Il y a devant l'homme des voies mauvaises, et il n'aime pas s'en détourner; cependant il est nécessaire d'éviter toute voie mauvaise et tortueuse.
15 Àyà ọmọdé ni ìwà wèrè dì sí; ṣùgbọ́n pàṣán ìtọ́ni ni yóò lé e jìnnà kúrò lọ́dọ̀ rẹ̀.
La folie est attachée au cœur du jeune homme; la verge et la discipline sont loin de lui.
16 Ẹni tó ń ni tálákà lára láti ní ọrọ̀, tí ó sì ń ta ọlọ́rọ̀ lọ́rẹ, yóò di aláìní bí ó ti wù kó rí. Gbọ́ ọ̀rọ̀ ọlọ́gbọ́n ènìyàn.
Celui qui trompe l'indigent augmente ses biens; mais il les diminue en faisant des présents au riche.
17 Dẹtí rẹ sílẹ̀, kí o gbọ́ ọ̀rọ̀ àwọn ọlọ́gbọ́n, kí o sì fi àyà rẹ sí ẹ̀kọ́ mi.
Incline ton oreille aux discours du sage; sois attentif à mes paroles; affermis ton cœur sur elles, afin que tu saches qu'elles sont bonnes.
18 Nítorí ohun dídùn ni bí ìwọ bá pa wọ́n mọ́ ní inú rẹ; nígbà tí a sì pèsè wọn tán ní ètè rẹ.
Si tu les déposes en ton cœur, elles réjouiront ton cœur et tes lèvres.
19 Kí ìgbẹ́kẹ̀lé rẹ lè wà ní ti Olúwa, èmi fihàn ọ́ lónìí, àní fún ọ.
Que ton espérance soit dans le Seigneur, et qu'Il te fasse connaître Sa voie.
20 Èmi kò ha ti kọ̀wé ohun dáradára sí ọ ní ti ìmọ̀ràn àti ní ti ẹ̀kọ́,
Grave ces choses trois fois sur la face de ton cœur, afin de posséder la sagesse et la science.
21 kí ó lè mú ọ mọ ìdájú ọ̀rọ̀ òtítọ́; kí ìwọ le máa fi ìdáhùn òtítọ́ fún àwọn tí ó rán ọ?
C'est pour cela que je t'enseigne la parole véritable et la doctrine bonne à suivre, afin que tu répondes les paroles de la vérité à ceux qui se présenteront devant toi.
22 Má ṣe ja tálákà ní olè, nítorí tí ó jẹ́ tálákà: bẹ́ẹ̀ ni kí o má sì ṣe ni olùpọ́njú lára ní ibodè,
Ne fais pas violence au pauvre, car il est dans le besoin; devant les portes de la ville, ne méprise point l'homme sans appui;
23 nítorí Olúwa yóò gbèjà wọn, yóò sì gba ọkàn àwọn tí ń gba tiwọn náà.
car le Seigneur Lui-même plaidera sa cause; et ainsi tu mettras ton âme en un sûr asile.
24 Má ṣe bá oníbìínú ènìyàn ṣe ọ̀rẹ́; má sì ṣe bá ọkùnrin onínú-fùfù rìn.
Ne sois pas le compagnon d'un orgueilleux; ne demeure pas avec un ami porté à la colère;
25 Kí ìwọ má ba à kọ́ ìwà rẹ̀, ìwọ a sì gba ìkẹ́kùn fún ara rẹ.
de peur que tu n'apprennes leurs voies, et que tu n'en reçoives des filets pour ton âme.
26 Má ṣe wà nínú àwọn tí ń ṣe ìgbọ̀nwọ́, tàbí nínú àwọn tí ó dúró fún gbèsè.
Ne t'engage pour personne, même par crainte de déplaire;
27 Bí ìwọ kò bá ní nǹkan tí ìwọ ó fi san, nítorí kín ni yóò ṣe gba ẹni rẹ kúrò lábẹ́ rẹ?
car si tu n'as pas de quoi payer, ils te prendront ta couverture sur les flancs.
28 Má ṣe yẹ ààlà ilẹ̀ ìgbàanì, tí àwọn baba rẹ ti pa.
Ne déplaces pas les bornes que, de tout temps, les pères ont posées.
29 Ìwọ ha rí ènìyàn tí ó ń fi àìṣe ìmẹ́lẹ́ ṣe iṣẹ́ rẹ̀? Òun yóò dúró níwájú àwọn ọba; òun kì yóò dúró níwájú àwọn ènìyàn lásán.
Il convient que l'homme clairvoyant et habile au travail s'approche des rois, mais non qu'il s'approche des pervers.

< Proverbs 22 >