< Proverbs 21 >

1 Ọkàn ọba ń bẹ lọ́wọ́ Olúwa; a máa darí rẹ̀ lọ ibi tí ó fẹ́ bí ipa omi.
Arroyo de agua es el corazón del rey en las manos de Yahvé, quien lo inclina adonde quiere.
2 Gbogbo ọ̀nà ènìyàn dàbí i pé ó dára lójú rẹ̀, ṣùgbọ́n, Olúwa ló ń díwọ̀n ọkàn.
Parécenle rectos al hombre todos sus caminos, pero el que pesa los corazones es Yahvé.
3 Ṣíṣe ohun tí ó dára tí ó sì tọ̀nà ó ṣe ìtẹ́wọ́gbà sí Olúwa ju ẹbọ lọ.
Practicar la justicia y equidad agrada a Yahvé más que el sacrificio.
4 Ojú tí ó gbéga àti ọkàn ìgbéraga, ìmọ́lẹ̀ àwọn ènìyàn búburú, ẹ̀ṣẹ̀ ni!
Altivez de ojos y soberbia de corazón, son antorcha de los impíos, son pecados.
5 Ètè àwọn olóye jásí èrè bí ìkánjú ṣe máa ń fa òsì kíákíá.
Los pensamientos del diligente dan frutos en abundancia, mas el hombre precipitado no gana más que la pobreza.
6 Ìṣúra tí a kójọ nípasẹ̀ ahọ́n tí ń parọ́ jẹ́ ìrì lásán àti ìkẹ́kùn ikú.
Amontonar tesoros con lengua artera, es vanidad fugaz de hombres que buscan la muerte.
7 Ìwà ipá àwọn ènìyàn búburú yóò wọ́ wọn lọ, nítorí wọ́n kọ̀ láti ṣe ohun tí ó tọ́.
La rapiña de los impíos es su ruina, porque rehúsan obrar rectamente.
8 Ọ̀nà ẹlẹ́ṣẹ̀ kún fún ìwà ẹ̀ṣẹ̀ ṣùgbọ́n iṣẹ́ onínú funfun jẹ́ títọ́.
El camino del perverso es tortuoso, mas el proceder del honesto es recto.
9 Ó sàn láti máa gbé ní kọ̀rọ̀ orí òrùlé ju láti ṣe àjọpín ilé pẹ̀lú aya oníjà.
Mejor es habitar en la punta del techo, que en la misma casa al lado de una mujer rencillosa.
10 Ènìyàn búburú ń fẹ́ ibi aládùúgbò rẹ̀ kì í rí àánú kankan gbà lọ́dọ̀ rẹ̀.
El alma del impío desea el mal, ni siquiera su amigo halla gracia a sus ojos.
11 Nígbà tí a bá ń fìyà jẹ ẹlẹ́gàn, òpè a máa kọ́gbọ́n, nígbà tí a bá sì kọ́ ọlọ́gbọ́n yóò ní ìmọ̀.
Por el castigo del burlador escarmienta el necio; el sabio se hace más sabio por la enseñanza.
12 Olódodo ṣàkíyèsí ilé ènìyàn búburú ó sì mú ènìyàn búburú wá sí ìparun.
El justo contempla la casa del impío, y cómo los impíos corren a la ruina.
13 Ẹnikẹ́ni tí ó bá ti di etí rẹ̀ sí igbe olùpọ́njú, òun tìkára rẹ̀ yóò ké pẹ̀lú; ṣùgbọ́n a kì yóò gbọ́.
Quien cierra sus oídos a los clamores del pobre, clamará él mismo y no será oído.
14 Ọ̀rẹ́ ìkọ̀kọ̀, mú ìbínú kúrò: àti owó àbẹ̀tẹ́lẹ̀ láti ibi ìkọ̀kọ̀ wá, dẹ́kun ìbínú líle.
La dádiva secreta calma la cólera, y el don metido en el seno, la mayor ira.
15 Ayọ̀ ni fún olódodo láti ṣe ìdájọ́: ṣùgbọ́n ìparun ni fún àwọn oníṣẹ́ ẹ̀ṣẹ̀.
El justo halla su gozo en practicar la justicia, en tanto que los obradores de iniquidad se espantan.
16 Ẹni tí ó bá yà kúrò ní ọ̀nà òye, yóò máa gbé inú ìjọ àwọn òkú.
El que se desvía del camino de la sabiduría, irá a morar con los muertos.
17 Ẹni tí ó bá fẹ́ afẹ́, yóò di tálákà: ẹni tí ó fẹ́ ọtí wáìnì pẹ̀lú òróró kò le lọ́rọ̀.
El que ama los placeres se empobrece; quien ama el vino y los perfumes no se enriquece.
18 Ènìyàn búburú ni yóò ṣe owó ìràpadà fún olódodo, àti olùrékọjá fún ẹni dídúró ṣinṣin.
Rescate del justo es el impío, y el de los rectos, el pérfido.
19 Ó sàn láti jókòó ní aginjù ju pẹ̀lú oníjà obìnrin àti òṣónú lọ.
Mejor vivir en tierra desierta que con mujer pendenciera y colérica.
20 Ìṣúra iyebíye àti òróró wà ní ibùgbé ọlọ́gbọ́n; ṣùgbọ́n òmùgọ̀ ènìyàn n bà á jẹ́.
En la casa del sabio hay tesoros deseables y aceite, pero un necio los malbarata.
21 Ẹni tí ó bá tẹ̀lé òdodo àti àánú yóò rí ìyè, òdodo, àti ọlá.
Quien practica la justicia y la misericordia, hallará vida, justicia y honra.
22 Ọlọ́gbọ́n gòkè odi ìlú àwọn alágbára, ó sì bi ibi gíga agbára ìgbẹ́kẹ̀lé wọn ṣubú.
El sabio va a la guerra contra una ciudad de héroes y arrasa los baluartes en que ella confiaba.
23 Ẹnikẹ́ni tí ó bá pa ẹnu àti ahọ́n rẹ̀ mọ́, ó pa ọkàn rẹ̀ mọ́ kúrò nínú ìyọnu.
Quien guarda su boca y su lengua, guarda de angustias su alma.
24 Agbéraga àti alágídí ènìyàn ń gan orúkọ ara rẹ̀ nítorí ó ń hùwà nínú ìwà ìgbéraga rẹ̀, àti nínú ìbínú púpọ̀púpọ̀.
El soberbio y altanero, burlador es su nombre; obra con insolente furor.
25 Ẹlẹ́rìí èké yóò ṣègbé, àwọn tí ó gbọ́ ọ̀rọ̀ rẹ̀ yóò parun láé; nítorí tí ọwọ́ rẹ̀ kọ iṣẹ́ ṣíṣe.
Matan al haragán sus deseos; pues sus manos rehúsan trabajar.
26 Ó ń fi ìlara ṣe ojúkòkòrò ní gbogbo ọjọ́: ṣùgbọ́n olódodo a máa fi fún ni kì í sì í dáwọ́ dúró.
Todo el día se consume codiciando, mientras el justo da sin tasa.
27 Ẹbọ ènìyàn búburú, ìríra ni: mélòó mélòó ni nígbà tí ó mú un wá pẹ̀lú èrò ìwà ibi?
El sacrificio del impío es abominable, ¡cuánto más si uno lo ofrece con mala intención!
28 Ẹlẹ́rìí èké yóò ṣègbé: ṣùgbọ́n ọ̀rọ̀ ẹni tí ó gbọ́, yóò dúró.
El testigo mentiroso perecerá, pero quien escucha habla para siempre.
29 Ènìyàn búburú mú ojú ara rẹ̀ le: ṣùgbọ́n ẹni ìdúró ṣinṣin ni ó ń mú ọ̀nà rẹ̀ tọ́.
El malvado muestra dureza en su cara, el hombre recto dispone su camino.
30 Kò sí ọgbọ́n, kò sí ìmòye, tàbí ìmọ̀ràn tí ó le mókè níwájú Olúwa.
Contra Yahvé no hay sabiduría, ni prudencia, ni consejo.
31 A ń múra ẹṣin sílẹ̀ de ọjọ́ ogun: ṣùgbọ́n ìṣẹ́gun jẹ́ ti Olúwa.
Se prepara el caballo para el día del combate, pero la victoria viene de Yahvé.

< Proverbs 21 >