< Proverbs 20 >

1 Ẹlẹ́yà ni ọtí wáìnì, aláriwo sì ní ọtí líle; ẹnikẹ́ni tí ó bá fi tànjẹ kò gbọ́n.
Wino czyni pośmiewcę, a napój mocny zwajcę; przetoż każdy, co się w nim kocha, nie bywa mądrym.
2 Ìbẹ̀rù ọba dàbí kíké e kìnnìún; ẹnikẹ́ni tí ó bá mú un bínú ba ayé ara rẹ̀ jẹ́.
Strach królewski jest jako, ryk lwięcia; kto go rozgniewa, grzeszy przeciwko duszy swojej.
3 Iyì ni ó jẹ́ fún ènìyàn láti sá fún ìjà, ṣùgbọ́n gbogbo aláìgbọ́n a máa tètè wá ìjà.
Uczciwa rzecz każdemu, poprzestać zwady; ale głupim jest, co się w nią wdaje.
4 Ọ̀lẹ kì í ṣiṣẹ́ oko nígbà tí ó yẹ, nítorí náà ní àsìkò ìkórè, yóò wá kò sì ní rì nǹkan.
Dla zimna leniwy nie orze; przetoż żebrać będzie we żniwa, ale nic nie otrzyma.
5 Ète ọkàn ènìyàn dàbí omi jíjìn; ṣùgbọ́n ènìyàn olóye á wá wọn jáde.
Rada w sercu męża jest jako woda głęboka: jednak mąż rozumny naczerpnie jej.
6 Ọ̀pọ̀lọpọ̀ ènìyàn ni wọ́n máa ń sọ pe àwọn ní ìfẹ́ àìṣẹ̀tàn, ṣùgbọ́n kò rọrùn láti rí ènìyàn olóòtítọ́.
Większa część ludzi przechwala się uczynnością swoją; ale w samej rzeczy, któż takiego znajdzie?
7 Olódodo ènìyàn a máa gbé ìgbé ayé àìlábùkù ìbùkún ni fún àwọn ọmọ rẹ̀ lẹ́yìn rẹ̀.
Sprawiedliwy chodzi w uprzejmości swojej; błogosławieni synowie jego po nim.
8 Nígbà tí ọba bá jókòó sórí ìtẹ́ rẹ̀ láti ṣe ìdájọ́ yóò fẹ́ gbogbo ibi dànù pẹ̀lú ojú rẹ̀.
Król siedząc na stolicy sądowej rozgania oczyma swemi wszystko złe.
9 Ta ni ó le è wí pé, “Mo ti ṣe ọkàn mi ní mímọ́, mo mọ́, n kò sì lẹ́ṣẹ̀”?
Któż rzecze: Oczyściłem serce moje? czystym jest od grzechu mego?
10 Ìwọ̀n èké àti òsùwọ̀n ìrẹ́jẹ Olúwa kórìíra méjèèjì.
Dwojaki gwicht i dwojaka miara, to oboje obrzydliwością jest Panu.
11 Kódà a mọ ọmọdé nípa iṣẹ́ rẹ̀ nípa pe bóyá iṣẹ́ rẹ mọ́ tàbí pé ó tọ̀nà.
Po zabawach swych poznane bywa i dziecię, jeźli czysty i prawy uczynek jego.
12 Etí tí ó ń gbọ́ àti ojú tí ó ń ríran Olúwa ni ó dá méjèèjì.
Ucho, które słyszy, i oko, które widzi, Pan to oboje uczynił.
13 Má ṣe fẹ́ràn oorun, àìṣe bẹ́ẹ̀ ìwọ yóò di tálákà. Ma ṣe sùn ìwọ yóò sì ní oúnjẹ láti tún fi tọrọ.
Nie kochaj się w spaniu, byś snać nie zubożał, otwórz oczy swoje, a nasycisz się chlebem.
14 “Kò dára, kò dára!” ní ẹni tó ra ọjà máa ń wí; nígbà tí ó bá kúrò níbẹ̀ tán, yóò máa yangàn bí òun tí ṣe rí rà sí.
Złe to, złe to, mówi ten, co kupuje, a odszedłszy, ali się chlubi.
15 Wúrà wà, iyùn sì wà rẹpẹtẹ, ṣùgbọ́n, ahọ́n tí ń sọ ìmọ̀ gan an ni ọ̀ṣọ́ iyebíye.
Wargi umiejętne są jako złoto i obfitość pereł, i kosztowne klejnoty.
16 Gba abọ́ ẹni tí ó ṣe onídùúró fún àlejò; mú un lọ́wọ́ bí ìbúra bí ó bá ṣe é fún obìnrin onírìnkurìn.
Weźmij szatę tego, któryć ręczył za obcego; a od tego, który ręczył za cudzoziemkę, weźmij zastaw jego.
17 Oúnjẹ tí a fi ọ̀nà èrú rí máa ń dùn lẹ́nu ènìyàn, ṣùgbọ́n, a yọrí sí ibi ẹnu tí ó kún fún erùpẹ̀.
Smaczny jest drugiemu chleb kłamstwa; ale potem piaskiem napełnione będą usta jego.
18 Pa ètè rẹ mọ́ nípa wíwá ìmọ̀ràn bí o bá ń jagun, gba ìtọ́sọ́nà.
Myśli radami utwierdzaj, a wojnę prowadź opatrznie.
19 Olófòófó a máa tú àṣírí nítorí náà yẹra fún ènìyàn tí ń rojọ́ púpọ̀.
Kto objawia tajemnicę, zdradliwie się obchodzi; przetoż z tymy, którzy pochlebiają wargami swemi, nie miej towarzystwa.
20 Bí ènìyàn kan bá ṣépè fún baba tàbí ìyá rẹ̀, ìmọ́lẹ̀ rẹ̀ ni a ó pa kú nínú òkùnkùn biribiri.
Kto złorzeczy ojcu swemu albo matce swojej, zgaśnie pochodnia jego w gęstych ciemnościach.
21 Ogún tí a kójọ kíákíá ní ìbẹ̀rẹ̀ kì yóò ní ìbùkún ní ìgbẹ̀yìn gbẹ́yín.
Dziedzictwu prędko z początku nabytemu naostatek błogosławić nie będą.
22 Má ṣe wí pé, “N ó sẹ̀san àṣìṣe rẹ yìí fún ọ.” Dúró de Olúwa yóò sì gbà ọ́ là.
Nie mów: Oddam złem. Oczekuj na Pana, a wybawi cię.
23 Olúwa kórìíra òdínwọ̀n èké. Òsùwọ̀n ìrẹ́jẹ kò sì tẹ́ ẹ lọ́rùn.
Obrzydliwością Panu dwojaki gwicht, a szale fałszywe nie podobają mu się.
24 Olúwa ni ó ń ṣe olùdarí ìgbésẹ̀ ènìyàn. Báwo wá ni òye gbogbo ọ̀nà ènìyàn ṣe le yé ni?
Od Pana bywają sprawowane drogi męża; ale człowiek jakoż zrozumie drogę jego?
25 Ìdẹ̀kùn ni fún ènìyàn láti ṣe ìlérí kíákíá nígbà tí ó bá sì yá kí ó máa ro ẹ̀jẹ̀ rẹ̀ wò.
Pożreć rzecz poświęconą, jest człowiekowi sidłem; a poślubiwszy co, tego zaś szukać, jakoby tego ujść.
26 Ọlọ́gbọ́n ọba tú ènìyàn búburú ká; Ó sì fi òòlọ ìpakà lọ̀ wọ́n.
Król mądry rozprasza niezbożnych, i przywodzi na nich pomstę.
27 Àtùpà Olúwa ń ṣe àwárí ẹ̀mí ènìyàn a máa ṣàwárí ibi ìkọ̀kọ̀ inú.
Dusza ludzka jest pochodnią Pańską, która doświadcza wszystkich skrytości wnętrznych.
28 Ìfẹ́ àti òdodo pa ọba mọ́, nípa ìfẹ́, ìtẹ́ rẹ̀ wà láìléwu.
Miłosierdzie i prawda króla strzegą, a stolica jego miłosierdziem wsparta bywa.
29 Ògo àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin ni agbára wọn, ewú orí ni iyì arúgbó.
Ozdoba młodzieńców jest siła ich, a sędziwość poczciwością starców.
30 Ìgbájú ìgbámú àti ìfarapa máa ń mú ibi lọ, pàṣán sì máa ń ṣe àfọ̀mọ́ ibi ìkọ̀kọ̀ inú.
Złemu są lekarstwem siności ran, i razy przenikające do wnętrzności żywota jego.

< Proverbs 20 >