< Proverbs 20 >

1 Ẹlẹ́yà ni ọtí wáìnì, aláriwo sì ní ọtí líle; ẹnikẹ́ni tí ó bá fi tànjẹ kò gbọ́n.
Csúfoló a bor, zajongó a részegítő ital; és bárki megmámorodik benne, nem lesz bölcs.
2 Ìbẹ̀rù ọba dàbí kíké e kìnnìún; ẹnikẹ́ni tí ó bá mú un bínú ba ayé ara rẹ̀ jẹ́.
Mint fiatal oroszlán ordítása, olyan a király ijesztése, a ki magára haragítja, lelke ellen vét.
3 Iyì ni ó jẹ́ fún ènìyàn láti sá fún ìjà, ṣùgbọ́n gbogbo aláìgbọ́n a máa tètè wá ìjà.
Dicsősége a férfiúnak elállni a pörtől, de minden oktalan kitör.
4 Ọ̀lẹ kì í ṣiṣẹ́ oko nígbà tí ó yẹ, nítorí náà ní àsìkò ìkórè, yóò wá kò sì ní rì nǹkan.
Ősztől kezdve nem szánt a rest, majd kér aratáskor, de nincs.
5 Ète ọkàn ènìyàn dàbí omi jíjìn; ṣùgbọ́n ènìyàn olóye á wá wọn jáde.
Mélységes víz a tanács az ember szívében, de az értelem embere merít belőle.
6 Ọ̀pọ̀lọpọ̀ ènìyàn ni wọ́n máa ń sọ pe àwọn ní ìfẹ́ àìṣẹ̀tàn, ṣùgbọ́n kò rọrùn láti rí ènìyàn olóòtítọ́.
A legtöbb ember – kiki hirdeti szeretetét, de hűséges embert ki talál?
7 Olódodo ènìyàn a máa gbé ìgbé ayé àìlábùkù ìbùkún ni fún àwọn ọmọ rẹ̀ lẹ́yìn rẹ̀.
Gáncstalanságában jár az igaz, boldogok a fiai ő utána.
8 Nígbà tí ọba bá jókòó sórí ìtẹ́ rẹ̀ láti ṣe ìdájọ́ yóò fẹ́ gbogbo ibi dànù pẹ̀lú ojú rẹ̀.
A király, ki az ítélet trónján ül, szemeivel szór szét minden rosszat.
9 Ta ni ó le è wí pé, “Mo ti ṣe ọkàn mi ní mímọ́, mo mọ́, n kò sì lẹ́ṣẹ̀”?
Ki mondhatja: megtisztítottam szívemet, tiszta lettem vétkemtől;
10 Ìwọ̀n èké àti òsùwọ̀n ìrẹ́jẹ Olúwa kórìíra méjèèjì.
Kétféle súlykő, kétféle mérő; az Örökkévaló utálata mindakettő.
11 Kódà a mọ ọmọdé nípa iṣẹ́ rẹ̀ nípa pe bóyá iṣẹ́ rẹ mọ́ tàbí pé ó tọ̀nà.
Cselekedeteiben megismerszik a fiú is, vajon tiszta s vajon egyenes-e a míve.
12 Etí tí ó ń gbọ́ àti ojú tí ó ń ríran Olúwa ni ó dá méjèèjì.
Halló fül és látó szem, az Örökkévaló teremtette mind a kettőt.
13 Má ṣe fẹ́ràn oorun, àìṣe bẹ́ẹ̀ ìwọ yóò di tálákà. Ma ṣe sùn ìwọ yóò sì ní oúnjẹ láti tún fi tọrọ.
Ne szeresd az alvást, nehogy elszegényedjél, nyisd ki szemeidet, lakjál jól kenyérrel.
14 “Kò dára, kò dára!” ní ẹni tó ra ọjà máa ń wí; nígbà tí ó bá kúrò níbẹ̀ tán, yóò máa yangàn bí òun tí ṣe rí rà sí.
Rossz, rossz! mondja a vevő, s midőn elmegy, akkor dicsekszik.
15 Wúrà wà, iyùn sì wà rẹpẹtẹ, ṣùgbọ́n, ahọ́n tí ń sọ ìmọ̀ gan an ni ọ̀ṣọ́ iyebíye.
Van arany és korál bőven, de drága ékszer a tudás ajkai.
16 Gba abọ́ ẹni tí ó ṣe onídùúró fún àlejò; mú un lọ́wọ́ bí ìbúra bí ó bá ṣe é fún obìnrin onírìnkurìn.
Vedd el ruháját, mert másért kezeskedett, és idegen nő miatt zálogold őt meg.
17 Oúnjẹ tí a fi ọ̀nà èrú rí máa ń dùn lẹ́nu ènìyàn, ṣùgbọ́n, a yọrí sí ibi ẹnu tí ó kún fún erùpẹ̀.
Kellemes az embernek a hazugság kenyere, de azután kaviccsal telik meg a szája.
18 Pa ètè rẹ mọ́ nípa wíwá ìmọ̀ràn bí o bá ń jagun, gba ìtọ́sọ́nà.
Gondolatok tanács által szilárdulnak meg, és útmutatásokkal viselj háborút.
19 Olófòófó a máa tú àṣírí nítorí náà yẹra fún ènìyàn tí ń rojọ́ púpọ̀.
Feltárja a titkot, ki mint rágalmazó jár, és csacskaajkúval ne állj össze.
20 Bí ènìyàn kan bá ṣépè fún baba tàbí ìyá rẹ̀, ìmọ́lẹ̀ rẹ̀ ni a ó pa kú nínú òkùnkùn biribiri.
A ki átkozza atyját és anyját, annak mécsese kialszik sötétség homályában.
21 Ogún tí a kójọ kíákíá ní ìbẹ̀rẹ̀ kì yóò ní ìbùkún ní ìgbẹ̀yìn gbẹ́yín.
Kezdetben hamarkodva szerzett birtok – annak vége nem lesz áldott.
22 Má ṣe wí pé, “N ó sẹ̀san àṣìṣe rẹ yìí fún ọ.” Dúró de Olúwa yóò sì gbà ọ́ là.
Ne mondd: Hadd fizetek rosszal; remélj az Örökkévalóhoz, s majd megsegít téged.
23 Olúwa kórìíra òdínwọ̀n èké. Òsùwọ̀n ìrẹ́jẹ kò sì tẹ́ ẹ lọ́rùn.
Utálata az Örökkévalónak kétféle súlykő, és csalárd mérleg nem jó.
24 Olúwa ni ó ń ṣe olùdarí ìgbésẹ̀ ènìyàn. Báwo wá ni òye gbogbo ọ̀nà ènìyàn ṣe le yé ni?
Az Örökkévalótól valók a férfi léptei, s az ember – miképp értheti az utját?
25 Ìdẹ̀kùn ni fún ènìyàn láti ṣe ìlérí kíákíá nígbà tí ó bá sì yá kí ó máa ro ẹ̀jẹ̀ rẹ̀ wò.
Tőr az embernek hirtelen kiejteni: szentség! és azután fontolgatni a fogadalmakat.
26 Ọlọ́gbọ́n ọba tú ènìyàn búburú ká; Ó sì fi òòlọ ìpakà lọ̀ wọ́n.
A gonoszokat szétszórja a bölcs király, és rájuk fordította a kereket.
27 Àtùpà Olúwa ń ṣe àwárí ẹ̀mí ènìyàn a máa ṣàwárí ibi ìkọ̀kọ̀ inú.
Mécsese az Örökkévalónak az ember lelke, átkutatja mind a testnek kamaráit.
28 Ìfẹ́ àti òdodo pa ọba mọ́, nípa ìfẹ́, ìtẹ́ rẹ̀ wà láìléwu.
Szeretet és hűség megóvják a királyt, és szeretettel támasztja trónját.
29 Ògo àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin ni agbára wọn, ewú orí ni iyì arúgbó.
Az ifjak ékessége erejök, s az öregek dísze az ősz haj.
30 Ìgbájú ìgbámú àti ìfarapa máa ń mú ibi lọ, pàṣán sì máa ń ṣe àfọ̀mọ́ ibi ìkọ̀kọ̀ inú.
Ütésnek kelevénye kenőcs a rosszra s a verések a test kamaráiba hatolnak.

< Proverbs 20 >