< Proverbs 20 >

1 Ẹlẹ́yà ni ọtí wáìnì, aláriwo sì ní ọtí líle; ẹnikẹ́ni tí ó bá fi tànjẹ kò gbọ́n.
Wine [is] a mocker, strong drink [is] raging: and whosoever is deceived thereby is not wise.
2 Ìbẹ̀rù ọba dàbí kíké e kìnnìún; ẹnikẹ́ni tí ó bá mú un bínú ba ayé ara rẹ̀ jẹ́.
The fear of a king [is] as the roaring of a lion: [whoso] provoketh him to anger sinneth [against] his own soul.
3 Iyì ni ó jẹ́ fún ènìyàn láti sá fún ìjà, ṣùgbọ́n gbogbo aláìgbọ́n a máa tètè wá ìjà.
[It is] an honour for a man to cease from strife: but every fool will be meddling.
4 Ọ̀lẹ kì í ṣiṣẹ́ oko nígbà tí ó yẹ, nítorí náà ní àsìkò ìkórè, yóò wá kò sì ní rì nǹkan.
The sluggard will not plow by reason of the cold; [therefore] shall he beg in harvest, and [have] nothing.
5 Ète ọkàn ènìyàn dàbí omi jíjìn; ṣùgbọ́n ènìyàn olóye á wá wọn jáde.
Counsel in the heart of man [is like] deep water; but a man of understanding will draw it out.
6 Ọ̀pọ̀lọpọ̀ ènìyàn ni wọ́n máa ń sọ pe àwọn ní ìfẹ́ àìṣẹ̀tàn, ṣùgbọ́n kò rọrùn láti rí ènìyàn olóòtítọ́.
Most men will proclaim every one his own goodness: but a faithful man who can find?
7 Olódodo ènìyàn a máa gbé ìgbé ayé àìlábùkù ìbùkún ni fún àwọn ọmọ rẹ̀ lẹ́yìn rẹ̀.
The just [man] walketh in his integrity: his children [are] blessed after him.
8 Nígbà tí ọba bá jókòó sórí ìtẹ́ rẹ̀ láti ṣe ìdájọ́ yóò fẹ́ gbogbo ibi dànù pẹ̀lú ojú rẹ̀.
A king that sitteth in the throne of judgment scattereth away all evil with his eyes.
9 Ta ni ó le è wí pé, “Mo ti ṣe ọkàn mi ní mímọ́, mo mọ́, n kò sì lẹ́ṣẹ̀”?
Who can say, I have made my heart clean, I am pure from my sin?
10 Ìwọ̀n èké àti òsùwọ̀n ìrẹ́jẹ Olúwa kórìíra méjèèjì.
Divers weights, [and] divers measures, both of them [are] alike abomination to the LORD.
11 Kódà a mọ ọmọdé nípa iṣẹ́ rẹ̀ nípa pe bóyá iṣẹ́ rẹ mọ́ tàbí pé ó tọ̀nà.
Even a child is known by his doings, whether his work [be] pure, and whether [it be] right.
12 Etí tí ó ń gbọ́ àti ojú tí ó ń ríran Olúwa ni ó dá méjèèjì.
The hearing ear, and the seeing eye, the LORD hath made even both of them.
13 Má ṣe fẹ́ràn oorun, àìṣe bẹ́ẹ̀ ìwọ yóò di tálákà. Ma ṣe sùn ìwọ yóò sì ní oúnjẹ láti tún fi tọrọ.
Love not sleep, lest thou come to poverty; open thine eyes, [and] thou shalt be satisfied with bread.
14 “Kò dára, kò dára!” ní ẹni tó ra ọjà máa ń wí; nígbà tí ó bá kúrò níbẹ̀ tán, yóò máa yangàn bí òun tí ṣe rí rà sí.
[It is] naught, [it is] naught, saith the buyer: but when he is gone his way, then he boasteth.
15 Wúrà wà, iyùn sì wà rẹpẹtẹ, ṣùgbọ́n, ahọ́n tí ń sọ ìmọ̀ gan an ni ọ̀ṣọ́ iyebíye.
There is gold, and a multitude of rubies: but the lips of knowledge [are] a precious jewel.
16 Gba abọ́ ẹni tí ó ṣe onídùúró fún àlejò; mú un lọ́wọ́ bí ìbúra bí ó bá ṣe é fún obìnrin onírìnkurìn.
Take his garment that is surety [for] a stranger: and take a pledge of him for a strange woman.
17 Oúnjẹ tí a fi ọ̀nà èrú rí máa ń dùn lẹ́nu ènìyàn, ṣùgbọ́n, a yọrí sí ibi ẹnu tí ó kún fún erùpẹ̀.
Bread of deceit [is] sweet to a man; but afterwards his mouth shall be filled with gravel.
18 Pa ètè rẹ mọ́ nípa wíwá ìmọ̀ràn bí o bá ń jagun, gba ìtọ́sọ́nà.
[Every] purpose is established by counsel: and with good advice make war.
19 Olófòófó a máa tú àṣírí nítorí náà yẹra fún ènìyàn tí ń rojọ́ púpọ̀.
He that goeth about [as] a talebearer revealeth secrets: therefore meddle not with him that flattereth with his lips.
20 Bí ènìyàn kan bá ṣépè fún baba tàbí ìyá rẹ̀, ìmọ́lẹ̀ rẹ̀ ni a ó pa kú nínú òkùnkùn biribiri.
Whoso curseth his father or his mother, his lamp shall be put out in obscure darkness.
21 Ogún tí a kójọ kíákíá ní ìbẹ̀rẹ̀ kì yóò ní ìbùkún ní ìgbẹ̀yìn gbẹ́yín.
An inheritance [may be] gotten hastily at the beginning; but the end thereof shall not be blessed.
22 Má ṣe wí pé, “N ó sẹ̀san àṣìṣe rẹ yìí fún ọ.” Dúró de Olúwa yóò sì gbà ọ́ là.
Say not thou, I will recompense evil; [but] wait on the LORD, and he shall save thee.
23 Olúwa kórìíra òdínwọ̀n èké. Òsùwọ̀n ìrẹ́jẹ kò sì tẹ́ ẹ lọ́rùn.
Divers weights [are] an abomination unto the LORD; and a false balance [is] not good.
24 Olúwa ni ó ń ṣe olùdarí ìgbésẹ̀ ènìyàn. Báwo wá ni òye gbogbo ọ̀nà ènìyàn ṣe le yé ni?
Man’s goings [are] of the LORD; how can a man then understand his own way?
25 Ìdẹ̀kùn ni fún ènìyàn láti ṣe ìlérí kíákíá nígbà tí ó bá sì yá kí ó máa ro ẹ̀jẹ̀ rẹ̀ wò.
[It is] a snare to the man [who] devoureth [that which is] holy, and after vows to make enquiry.
26 Ọlọ́gbọ́n ọba tú ènìyàn búburú ká; Ó sì fi òòlọ ìpakà lọ̀ wọ́n.
A wise king scattereth the wicked, and bringeth the wheel over them.
27 Àtùpà Olúwa ń ṣe àwárí ẹ̀mí ènìyàn a máa ṣàwárí ibi ìkọ̀kọ̀ inú.
The spirit of man [is] the candle of the LORD, searching all the inward parts of the belly.
28 Ìfẹ́ àti òdodo pa ọba mọ́, nípa ìfẹ́, ìtẹ́ rẹ̀ wà láìléwu.
Mercy and truth preserve the king: and his throne is upholden by mercy.
29 Ògo àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin ni agbára wọn, ewú orí ni iyì arúgbó.
The glory of young men [is] their strength: and the beauty of old men [is] the gray head.
30 Ìgbájú ìgbámú àti ìfarapa máa ń mú ibi lọ, pàṣán sì máa ń ṣe àfọ̀mọ́ ibi ìkọ̀kọ̀ inú.
The blueness of a wound cleanseth away evil: so [do] stripes the inward parts of the belly.

< Proverbs 20 >