< Proverbs 2 >
1 Ọmọ mi, bí ìwọ bá gba ọ̀rọ̀ mi, tí ìwọ sì pa òfin mi mọ́ sí inú rẹ,
Filho meu, se aceitares as minhas palavras, e esconderes contigo os meus mandamentos,
2 tí ìwọ dẹtí rẹ sílẹ̀ sí ọgbọ́n tí ìwọ sì fi ọkàn rẹ sí òye,
Para fazeres atento à sabedoria o teu ouvido, e inclinares o teu coração ao entendimento,
3 àní, bí ìwọ bá ké tọ ìmọ̀ lẹ́yìn, tí ìwọ sì gbé ohùn rẹ sókè fún òye
E se clamares por entendimento, e por inteligência alçares a tua voz,
4 bí ìwọ bá ṣàfẹ́rí rẹ̀ bí i fàdákà tí ìwọ sì wa kiri bí ìṣúra tí a fi pamọ́.
Se como a prata a buscares e como a tesouros escondidos a esquadrinhares,
5 Nígbà náà ni ìwọ yóò bẹ̀rù Olúwa, ìwọ yóò sì rí ìmọ̀ Ọlọ́run.
Então entenderás o temor do Senhor, e acharás o conhecimento de Deus.
6 Nítorí Olúwa ni ó ń fún ni ní ọgbọ́n, láti ẹnu rẹ̀ sì ni ìmọ̀ àti òye ti ń wá.
Porque o Senhor é o que dá a sabedoria: da sua boca é que sai o conhecimento e o entendimento.
7 Ó to ìgbàlà fún àwọn olódodo, Òun ni asà fún àwọn tí ń rìn déédé,
Ele reserva a verdadeira sabedoria para os retos: escudo é para os que caminham na sinceridade.
8 Ó pa ipa ọ̀nà ìdájọ́ mọ́ Ó sì ń pa ọ̀nà àwọn àyànfẹ́ rẹ̀ mọ́.
Para que guardem as veredas do juízo: e ele o caminho dos seus santos conservará.
9 Nígbà náà ni ìwọ yóò mọ òdodo àti ìdájọ́, àti àìṣègbè—gbogbo ipa ọ̀nà rere.
Então entenderás justiça, e juízo, e equidades, e todas as boas veredas,
10 Nítorí ọgbọ́n yóò wọ inú ọkàn rẹ ìmọ̀ yóò sì jẹ́ ìtura fún ọkàn rẹ.
Quando a sabedoria entrar no teu coração, e o conhecimento for suave à tua alma.
11 Ìmòye yóò pa ọ mọ́ òye yóò sì máa ṣọ́ ọ.
O bom siso te guardará e a inteligência te conservará;
12 Ọgbọ́n yóò gbà ọ́ là kúrò ní ọ̀nà àwọn ènìyàn búburú, lọ́dọ̀ àwọn ènìyàn tí ọrọ̀ ọ wọn jẹ́ àyídáyidà,
Para te fazer escapar do mau caminho, e do homem que fala coisas perversas.
13 ẹni tí ó kúrò ní ọ̀nà ìdúró ṣinṣin láti rìn ní ọ̀nà tí ó ṣókùnkùn,
Dos que deixam as veredas da retidão, para andarem pelos caminhos das trevas.
14 ẹni tí ó yọ̀ nínú ṣíṣe búburú, tí ó ṣe inú dídùn sí àyídáyidà àwọn ènìyàn ibi,
Que se alegram de mal fazer, e folgam com as perversidades dos maus.
15 ọ̀nà ẹni tí ó wọ́ tí wọ́n sì jẹ́ alárékérekè ní ọ̀nà wọn.
Cujas veredas são tortuosas e que se desviam nas suas carreiras,
16 Yóò gba ìwọ pẹ̀lú là kúrò lọ́wọ́ àwọn àjèjì obìnrin, àní, lọ́wọ́ obìnrin àjèjì tí ń fi ọ̀rọ̀ ẹnu rẹ̀ tannijẹ,
Para te fazer escapar da mulher estranha, e da estrangeira que lisongeia com suas palavras.
17 ẹni tí ó ti kọ ọkọ àkọ́fẹ́ ìgbà èwe rẹ̀ sílẹ̀ tí ó sì gbàgbé májẹ̀mú tí ó ti dá níwájú Ọlọ́run rẹ̀.
Que deixa o guia da sua mocidade e se esquece do concerto do seu Deus.
18 Nítorí ilé rẹ̀ jẹ́ ọ̀nà sí ikú ipa ọ̀nà rẹ̀ sọ́dọ̀ àwọn òkú.
Porque a sua casa se inclina para a morte, e as suas veredas para os defuntos.
19 Kò sẹ́ni tó lọ sọ́dọ̀ rẹ̀ tí ó padà bẹ́ẹ̀ ni wọn kì í dé ọ̀nà ìyè.
Todos os que entrarem a ela não tornarão a sair, e não atinarão com as veredas da vida.
20 Bẹ́ẹ̀ ni ìwọ yóò rìn ní ọ̀nà àwọn ènìyàn rere kí ìwọ kí ó sì pa ọ̀nà àwọn olódodo mọ́.
Para andares pelo caminho dos bons, e guardares as veredas dos justos.
21 Nítorí ẹni dídúró ṣinṣin yóò gbé ní ilé náà àwọn aláìlẹ́gàn sì ni yóò máa wà nínú rẹ̀.
Porque os retos habitarão a terra, e os sinceros permanecerão nela.
22 Ṣùgbọ́n a ó ké ènìyàn búburú kúrò lórí ilẹ̀ náà a ó sì fa àwọn aláìṣòótọ́ tu kúrò lórí rẹ̀.
Mas os ímpios serão arrancados da terra, e os aleivosos serão dela exterminados.