< Proverbs 2 >

1 Ọmọ mi, bí ìwọ bá gba ọ̀rọ̀ mi, tí ìwọ sì pa òfin mi mọ́ sí inú rẹ,
Fiam! ha beveszed az én beszédimet, és az én parancsolatimat elrejted magadnál,
2 tí ìwọ dẹtí rẹ sílẹ̀ sí ọgbọ́n tí ìwọ sì fi ọkàn rẹ sí òye,
Ha figyelmeztetvén a bölcsességre a te füleidet, hajtod a te elmédet az értelemre,
3 àní, bí ìwọ bá ké tọ ìmọ̀ lẹ́yìn, tí ìwọ sì gbé ohùn rẹ sókè fún òye
Igen, ha a bölcseségért kiáltasz, és az értelemért a te szódat felemeled,
4 bí ìwọ bá ṣàfẹ́rí rẹ̀ bí i fàdákà tí ìwọ sì wa kiri bí ìṣúra tí a fi pamọ́.
Ha keresed azt, mint az ezüstöt, és mint a kincseket kutatod azt:
5 Nígbà náà ni ìwọ yóò bẹ̀rù Olúwa, ìwọ yóò sì rí ìmọ̀ Ọlọ́run.
Akkor megérted az Úrnak félelmét, és az Istennek ismeretére jutsz.
6 Nítorí Olúwa ni ó ń fún ni ní ọgbọ́n, láti ẹnu rẹ̀ sì ni ìmọ̀ àti òye ti ń wá.
Mert az Úr ád bölcseséget, az ő szájából tudomány és értelem származik.
7 Ó to ìgbàlà fún àwọn olódodo, Òun ni asà fún àwọn tí ń rìn déédé,
Az igazaknak valóságos jót rejteget, paizst a tökéletesen járóknak,
8 Ó pa ipa ọ̀nà ìdájọ́ mọ́ Ó sì ń pa ọ̀nà àwọn àyànfẹ́ rẹ̀ mọ́.
Hogy megőrizze az igazságnak útait, és kegyeseinek útját megtartja.
9 Nígbà náà ni ìwọ yóò mọ òdodo àti ìdájọ́, àti àìṣègbè—gbogbo ipa ọ̀nà rere.
Akkor megérted az igazságot, és törvényt és becsületességet, és minden jó útat.
10 Nítorí ọgbọ́n yóò wọ inú ọkàn rẹ ìmọ̀ yóò sì jẹ́ ìtura fún ọkàn rẹ.
Mert bölcseség megy a te elmédbe, és a tudomány a te lelkedben gyönyörűséges lesz.
11 Ìmòye yóò pa ọ mọ́ òye yóò sì máa ṣọ́ ọ.
Meggondolás őrködik feletted, értelem őriz téged,
12 Ọgbọ́n yóò gbà ọ́ là kúrò ní ọ̀nà àwọn ènìyàn búburú, lọ́dọ̀ àwọn ènìyàn tí ọrọ̀ ọ wọn jẹ́ àyídáyidà,
Hogy megszabadítson téged a gonosznak útától, és a gonoszságszóló férfiútól;
13 ẹni tí ó kúrò ní ọ̀nà ìdúró ṣinṣin láti rìn ní ọ̀nà tí ó ṣókùnkùn,
A kik elhagyják az igazságnak útát, hogy járjanak a setétségnek útain.
14 ẹni tí ó yọ̀ nínú ṣíṣe búburú, tí ó ṣe inú dídùn sí àyídáyidà àwọn ènìyàn ibi,
A kik örülnek gonoszt cselekedvén, vígadnak a gonosz álnokságokon.
15 ọ̀nà ẹni tí ó wọ́ tí wọ́n sì jẹ́ alárékérekè ní ọ̀nà wọn.
A kiknek ösvényeik görbék, és a kik az ő útaikban gonoszok.
16 Yóò gba ìwọ pẹ̀lú là kúrò lọ́wọ́ àwọn àjèjì obìnrin, àní, lọ́wọ́ obìnrin àjèjì tí ń fi ọ̀rọ̀ ẹnu rẹ̀ tannijẹ,
Hogy megszabadítson téged a nem hozzád tartozó asszonytól, az idegentől, a ki az ő beszédével hizelkedik,
17 ẹni tí ó ti kọ ọkọ àkọ́fẹ́ ìgbà èwe rẹ̀ sílẹ̀ tí ó sì gbàgbé májẹ̀mú tí ó ti dá níwájú Ọlọ́run rẹ̀.
A ki elhagyja az ő ifjúságának férjét, és az ő Istenének szövetségéről elfelejtkezik;
18 Nítorí ilé rẹ̀ jẹ́ ọ̀nà sí ikú ipa ọ̀nà rẹ̀ sọ́dọ̀ àwọn òkú.
Mert a halálra hanyatlik az ő háza, és az ő ösvényei az élet nélkül valókhoz.
19 Kò sẹ́ni tó lọ sọ́dọ̀ rẹ̀ tí ó padà bẹ́ẹ̀ ni wọn kì í dé ọ̀nà ìyè.
Valakik mennek ahhoz, nem térnek meg, sem meg nem nyerhetik az életnek útait.
20 Bẹ́ẹ̀ ni ìwọ yóò rìn ní ọ̀nà àwọn ènìyàn rere kí ìwọ kí ó sì pa ọ̀nà àwọn olódodo mọ́.
Hogy járj a jóknak útjokon, és az igazaknak ösvényeit kövessed.
21 Nítorí ẹni dídúró ṣinṣin yóò gbé ní ilé náà àwọn aláìlẹ́gàn sì ni yóò máa wà nínú rẹ̀.
Mert az igazak lakják a földet, és a tökéletesek maradnak meg rajta.
22 Ṣùgbọ́n a ó ké ènìyàn búburú kúrò lórí ilẹ̀ náà a ó sì fa àwọn aláìṣòótọ́ tu kúrò lórí rẹ̀.
A gonoszok pedig a földről kivágattatnak, és a hitetlenül cselekedők kiszaggattatnak abból.

< Proverbs 2 >