< Proverbs 2 >
1 Ọmọ mi, bí ìwọ bá gba ọ̀rọ̀ mi, tí ìwọ sì pa òfin mi mọ́ sí inú rẹ,
Mein Sohn, wenn du meine Reden annimmst und meine Gebote bei dir verwahrst,
2 tí ìwọ dẹtí rẹ sílẹ̀ sí ọgbọ́n tí ìwọ sì fi ọkàn rẹ sí òye,
so daß du dein Ohr auf Weisheit merken läßt, dein Herz neigst zum Verständnis;
3 àní, bí ìwọ bá ké tọ ìmọ̀ lẹ́yìn, tí ìwọ sì gbé ohùn rẹ sókè fún òye
ja, wenn du dem Verstande rufst, deine Stimme erhebst zum Verständnis;
4 bí ìwọ bá ṣàfẹ́rí rẹ̀ bí i fàdákà tí ìwọ sì wa kiri bí ìṣúra tí a fi pamọ́.
wenn du ihn suchst wie Silber, und wie nach verborgenen Schätzen ihm nachspürst:
5 Nígbà náà ni ìwọ yóò bẹ̀rù Olúwa, ìwọ yóò sì rí ìmọ̀ Ọlọ́run.
dann wirst du die Furcht Jehovas verstehen und die Erkenntnis Gottes finden.
6 Nítorí Olúwa ni ó ń fún ni ní ọgbọ́n, láti ẹnu rẹ̀ sì ni ìmọ̀ àti òye ti ń wá.
Denn Jehova gibt Weisheit; aus seinem Munde kommen Erkenntnis und Verständnis.
7 Ó to ìgbàlà fún àwọn olódodo, Òun ni asà fún àwọn tí ń rìn déédé,
Er bewahrt klugen Rat [O. Heil; eig. das, was fördert, frommt] auf für die Aufrichtigen, er ist ein Schild denen, die in Vollkommenheit [O. Lauterkeit] wandeln;
8 Ó pa ipa ọ̀nà ìdájọ́ mọ́ Ó sì ń pa ọ̀nà àwọn àyànfẹ́ rẹ̀ mọ́.
indem er die Pfade des Rechts behütet und den Weg seiner Frommen bewahrt.
9 Nígbà náà ni ìwọ yóò mọ òdodo àti ìdájọ́, àti àìṣègbè—gbogbo ipa ọ̀nà rere.
Dann wirst du Gerechtigkeit verstehen und Recht und Geradheit, jede Bahn [Eig. Geleise, Spur; so auch später] des Guten.
10 Nítorí ọgbọ́n yóò wọ inú ọkàn rẹ ìmọ̀ yóò sì jẹ́ ìtura fún ọkàn rẹ.
Denn Weisheit wird in dein Herz kommen, und Erkenntnis wird deiner Seele lieblich sein;
11 Ìmòye yóò pa ọ mọ́ òye yóò sì máa ṣọ́ ọ.
Besonnenheit wird über dich wachen, Verständnis dich behüten:
12 Ọgbọ́n yóò gbà ọ́ là kúrò ní ọ̀nà àwọn ènìyàn búburú, lọ́dọ̀ àwọn ènìyàn tí ọrọ̀ ọ wọn jẹ́ àyídáyidà,
um dich zu erretten von dem bösen Wege, von dem Manne, der Verkehrtes redet;
13 ẹni tí ó kúrò ní ọ̀nà ìdúró ṣinṣin láti rìn ní ọ̀nà tí ó ṣókùnkùn,
die da verlassen die Pfade der Geradheit, um auf den Wegen der Finsternis zu wandeln;
14 ẹni tí ó yọ̀ nínú ṣíṣe búburú, tí ó ṣe inú dídùn sí àyídáyidà àwọn ènìyàn ibi,
die sich freuen, Böses zu tun, über boshafte Verkehrtheit frohlocken;
15 ọ̀nà ẹni tí ó wọ́ tí wọ́n sì jẹ́ alárékérekè ní ọ̀nà wọn.
deren Pfade krumm sind, und die abbiegen in ihren Bahnen:
16 Yóò gba ìwọ pẹ̀lú là kúrò lọ́wọ́ àwọn àjèjì obìnrin, àní, lọ́wọ́ obìnrin àjèjì tí ń fi ọ̀rọ̀ ẹnu rẹ̀ tannijẹ,
um dich zu erretten von dem fremden Weibe, [d. h. dem Eheweibe eines anderen] von der Fremden, [Eig. Ausländerin] die ihre Worte glättet;
17 ẹni tí ó ti kọ ọkọ àkọ́fẹ́ ìgbà èwe rẹ̀ sílẹ̀ tí ó sì gbàgbé májẹ̀mú tí ó ti dá níwájú Ọlọ́run rẹ̀.
welche den Vertrauten ihrer Jugend verläßt und den Bund ihres Gottes vergißt.
18 Nítorí ilé rẹ̀ jẹ́ ọ̀nà sí ikú ipa ọ̀nà rẹ̀ sọ́dọ̀ àwọn òkú.
Denn zum Tode sinkt ihr Haus hinab, und ihre Bahnen zu den Schatten; [S. die Anm. zu Ps. 88,10]
19 Kò sẹ́ni tó lọ sọ́dọ̀ rẹ̀ tí ó padà bẹ́ẹ̀ ni wọn kì í dé ọ̀nà ìyè.
alle, die zu ihr eingehen, kehren nicht wieder und erreichen nicht die Pfade des Lebens:
20 Bẹ́ẹ̀ ni ìwọ yóò rìn ní ọ̀nà àwọn ènìyàn rere kí ìwọ kí ó sì pa ọ̀nà àwọn olódodo mọ́.
Damit du wandelst auf dem Wege der Guten und die Pfade der Gerechten einhältst.
21 Nítorí ẹni dídúró ṣinṣin yóò gbé ní ilé náà àwọn aláìlẹ́gàn sì ni yóò máa wà nínú rẹ̀.
Denn die Aufrichtigen werden das Land bewohnen, und die Vollkommenen darin übrigbleiben;
22 Ṣùgbọ́n a ó ké ènìyàn búburú kúrò lórí ilẹ̀ náà a ó sì fa àwọn aláìṣòótọ́ tu kúrò lórí rẹ̀.
aber die Gesetzlosen werden aus dem Lande ausgerottet, und die Treulosen daraus weggerissen werden.