< Proverbs 2 >
1 Ọmọ mi, bí ìwọ bá gba ọ̀rọ̀ mi, tí ìwọ sì pa òfin mi mọ́ sí inú rẹ,
Mon fils, si tu reçois la parole de mon commandement, si tu la tiens cachée en toi-même,
2 tí ìwọ dẹtí rẹ sílẹ̀ sí ọgbọ́n tí ìwọ sì fi ọkàn rẹ sí òye,
ton oreille écoutera la Sagesse, et tu inclineras ton cœur à la prudence, et tu l'appliqueras à l'enseignement de ton fils.
3 àní, bí ìwọ bá ké tọ ìmọ̀ lẹ́yìn, tí ìwọ sì gbé ohùn rẹ sókè fún òye
Car si tu invoques la Sagesse, et si tu appelles à haute voix la prudence, et si tu demandes à grands cris la doctrine,
4 bí ìwọ bá ṣàfẹ́rí rẹ̀ bí i fàdákà tí ìwọ sì wa kiri bí ìṣúra tí a fi pamọ́.
et si tu la recherches comme de l'argent, et si tu la creuses comme un trésor,
5 Nígbà náà ni ìwọ yóò bẹ̀rù Olúwa, ìwọ yóò sì rí ìmọ̀ Ọlọ́run.
alors tu comprendras la crainte du Seigneur, et tu trouveras la connaissance de Dieu.
6 Nítorí Olúwa ni ó ń fún ni ní ọgbọ́n, láti ẹnu rẹ̀ sì ni ìmọ̀ àti òye ti ń wá.
Car c'est le Seigneur qui donne la sagesse, et de Sa face viennent l'intelligence et le savoir.
7 Ó to ìgbàlà fún àwọn olódodo, Òun ni asà fún àwọn tí ń rìn déédé,
Et Il thésaurise le salut pour ceux qui font le bien; Il protège leurs voies,
8 Ó pa ipa ọ̀nà ìdájọ́ mọ́ Ó sì ń pa ọ̀nà àwọn àyànfẹ́ rẹ̀ mọ́.
pour qu'ils marchent dans la justice, et Lui-même veille sur la voie de ceux qui Le révèrent.
9 Nígbà náà ni ìwọ yóò mọ òdodo àti ìdájọ́, àti àìṣègbè—gbogbo ipa ọ̀nà rere.
Alors tu comprendras la justice et le jugement, et tu garderas droits tes sentiers.
10 Nítorí ọgbọ́n yóò wọ inú ọkàn rẹ ìmọ̀ yóò sì jẹ́ ìtura fún ọkàn rẹ.
Car si la sagesse entre dans ta pensée, et si la doctrine semble bonne à ton âme,
11 Ìmòye yóò pa ọ mọ́ òye yóò sì máa ṣọ́ ọ.
le bon conseil te gardera, et l'intelligence sainte te conservera;
12 Ọgbọ́n yóò gbà ọ́ là kúrò ní ọ̀nà àwọn ènìyàn búburú, lọ́dọ̀ àwọn ènìyàn tí ọrọ̀ ọ wọn jẹ́ àyídáyidà,
pour te délivrer de la voie mauvaise et de l'homme dont la parole est infidèle.
13 ẹni tí ó kúrò ní ọ̀nà ìdúró ṣinṣin láti rìn ní ọ̀nà tí ó ṣókùnkùn,
Ô vous qui avez abandonné le droit chemin pour marcher dans la voie des ténèbres,
14 ẹni tí ó yọ̀ nínú ṣíṣe búburú, tí ó ṣe inú dídùn sí àyídáyidà àwọn ènìyàn ibi,
qui vous complaisez dans le mal, et vous réjouissez de la perversité,
15 ọ̀nà ẹni tí ó wọ́ tí wọ́n sì jẹ́ alárékérekè ní ọ̀nà wọn.
dont les sentiers sont obliques, et les ornières tortueuses,
16 Yóò gba ìwọ pẹ̀lú là kúrò lọ́wọ́ àwọn àjèjì obìnrin, àní, lọ́wọ́ obìnrin àjèjì tí ń fi ọ̀rọ̀ ẹnu rẹ̀ tannijẹ,
vous chercherez à éloigner mon fils du droit chemin, et à le rendre étranger à la justice. Ô mon fils, ne te laisse pas surprendre par leur mauvais conseil!
17 ẹni tí ó ti kọ ọkọ àkọ́fẹ́ ìgbà èwe rẹ̀ sílẹ̀ tí ó sì gbàgbé májẹ̀mú tí ó ti dá níwájú Ọlọ́run rẹ̀.
Celle qui délaisse le compagnon de sa virginité,
18 Nítorí ilé rẹ̀ jẹ́ ọ̀nà sí ikú ipa ọ̀nà rẹ̀ sọ́dọ̀ àwọn òkú.
et qui oublie l'alliance divine, a mis sa maison près de la mort, et ses voies près de l'enfer avec les fils de la terre. ()
19 Kò sẹ́ni tó lọ sọ́dọ̀ rẹ̀ tí ó padà bẹ́ẹ̀ ni wọn kì í dé ọ̀nà ìyè.
Aucun de ceux qui vont avec elle ne reviendra, et ils ne reprendront pas les droits sentiers; car ils ne se maintiendront pas dans les longues années de la vie.
20 Bẹ́ẹ̀ ni ìwọ yóò rìn ní ọ̀nà àwọn ènìyàn rere kí ìwọ kí ó sì pa ọ̀nà àwọn olódodo mọ́.
Et s'ils avaient marché dans les bons sentiers, ils auraient sûrement trouvé faciles les sentiers de la justice.
21 Nítorí ẹni dídúró ṣinṣin yóò gbé ní ilé náà àwọn aláìlẹ́gàn sì ni yóò máa wà nínú rẹ̀.
[Les débonnaires auront leur demeure sur la terre et les innocents y seront laissés] Les cœurs droits habiteront la terre, et les saints y seront établis.
22 Ṣùgbọ́n a ó ké ènìyàn búburú kúrò lórí ilẹ̀ náà a ó sì fa àwọn aláìṣòótọ́ tu kúrò lórí rẹ̀.
Les voies des impies seront effacées sur la terre, et les pervers en seront expulsés.